< Ezechiela 12 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Synu człowieczy! ty w pośrodku domu odpornego mieszkasz, którzy mają oczy, aby widzieli, a nie widzą, uszy mają, aby słyszeli, a nie słyszą; przeto, że domem odpornym są.
“Ọmọ ènìyàn, ìwọ ń gbé ní àárín ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn. Wọ́n lójú láti fi ríran, ṣùgbọ́n wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n létí láti fi gbọ́rọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́rọ̀, torí pé ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn ni wọ́n.
3 Ty tedy, synu człowieczy! spraw sobie sprzęt przeprowadzenia, a przeprowadzaj się we dnie przed oczyma ich, a przeprowadzaj się z miejsca swego na miejsce inne przed oczyma ich, aza wżdy obaczą, acz domem odpornym są.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, palẹ̀ ẹrù rẹ mọ́ láti lọ sí ìgbèkùn, ní ọ̀sán gangan ní ojú wọn, kúrò láti ibi tí ìwọ wà lọ sí ibòmíràn. Bóyá bí wọ́n bá rí ọ, wọn yóò sì ronú bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
4 I wyniesiesz sprzęt swój, jako sprzęt przeprowadzenia, we dnie przed oczyma ich; a sam wynijdź w wieczór przed oczyma ich, jako wychodzą, którzy się przeprowadzają.
Di ẹrù ìgbèkùn rẹ lójú wọn ní ọ̀sán án gangan, nígbà tí ó bá sì di alẹ́, ní ojú wọn, máa lọ sí ìgbèkùn gẹ́gẹ́ bí àwọn tí ó lọ ìgbèkùn ṣe máa ń ṣe.
5 Przed oczyma ich przekop sobie mur, a wynieś przezeń sprzęt twój.
Dá ògiri lu ní ojú wọn, kí ìwọ sì gba ibẹ̀ kó ẹrù rẹ jáde.
6 Przed oczyma ich na ramionach nieś, z zmierzkiem wynieś, twarz swoję zakryj, a nie patrz na ziemię; bom cię dał za dziw domowi Izraelskiemu.
Gbé ẹrù rẹ lé èjìká ní ojú wọn, bo ojú rẹ, kí ìwọ má ba à rí ilẹ̀, sì ru ẹrù rẹ lọ ní alẹ́ nítorí pé mo fi ọ́ ṣe àmì fún ilé Israẹli.”
7 I uczyniłem tak, jako mi rozkazano; sprzęt mój wyniosłem jako sprzęt prowadzącego się we dnie, a w wieczór przekopałem sobie mur ręką; z zmierzkiem wyniosłem go na ramieniu niosąc przed oczyma ich.
Mo ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi. Mo kó ẹrù mi jáde ní ọ̀sán án láti lọ fun ìgbèkùn. Nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, mo dá ògiri lu pẹ̀lú ọwọ́ mi. Mo sì gbe ẹrù mi lé èjìká nínú òkùnkùn ní ojú wọn.
8 Znowu stało się słowo Pańskie do mnie rano, mówiąc:
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
9 Synu człowieczy! Izali nie rzekł do ciebie dom Izraelski, dom ten odporny: Cóż to czynisz?
“Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli tilẹ̀ bi ọ́ pé, ‘Kí ni ohun tí o ń ṣe túmọ̀ sí?’
10 Rzeczże im, tak mówi panujący Pan: Na księcia, który jest w Jeruzalemie, ściąga się to brzemię, i na wszystek dom Izraelski, którzy są w pośród jego.
“Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ yìí kan àwọn ọmọ-aládé Jerusalẹmu àti gbogbo ilé Israẹli tí ó wà ní àárín rẹ.
11 Rzeczże do nich: Jam jest dziwem waszym; jakom uczynił, tak się im stanie; przeprowadzą się, i w niewolę pójdą.
Sọ fún wọn pé, Èmi jẹ́ àmì fún yín’. “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí wọn. Wọn ó kó lọ sí ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí ẹni ti a dè ní ìgbèkùn.
12 A książę, który jest w pośrodku nich, na ramieniu poniesie sprzęt swój z zmierzkiem, i wynijdzie; mur przekopią, aby go wywiedli przezeń; twarz swoję zakryje, tak, że nie będzie widział ziemi okiem swojem.
“Ọmọ-aládé tí ó wà ní àárín wọn yóò di ẹrù rẹ̀ lé èjìká ní alẹ́ yóò sì jáde lọ, òun náà yóò da ògiri lu kí ó le gba ibẹ̀ jáde. Yóò sì bo ojú rẹ̀ kí ó má ba à rí ilẹ̀.
13 Bo rozciągnę nań sieć swoję, i pojmany będzie niewodem moim, i przywiodę go do Babilonu, do ziemi Chaldejskiej, a tej nie ogląda, i tam umrze.
Èmi yóò ta àwọ̀n mi lé e lórí, yóò sì kó sínú okùn, Èmi yóò sì mú lọ sí Babeli, ní ilẹ̀ Kaldea, ṣùgbọ́n kò ní fojúrí ilẹ̀ náà ibẹ̀ ni yóò kú sí.
14 Także też wszystkich, którzy są około niego, pomoc jego, i wszystkie hufy jego rozproszę na wszystkie strony, i miecza dobędę za nimi;
Gbogbo àwọn tó yí i ká láti ràn án lọ́wọ́ ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ni Èmi yóò túká sí afẹ́fẹ́, èmi yóò sì tún fi idà lé wọn kiri.
15 I poznają, żem Ja Pan, gdy ich rozproszę między narody, i rozwieję ich po ziemiach.
“Wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà tí mo bá tú wọn ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì fọ́n wọn ká sí ilẹ̀ káàkiri.
16 Jednak zostawię z nich trochę mężów po mieczu, po głodzie i po morze, aby opowiadali wszystkie obrzydliwości swe między narodami, do których wnijdą, i poznają, żem Ja Pan.
Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ díẹ̀ kù lára wọn, ní ọwọ́ idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, kí wọn le jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe ìríra wọn ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè yìí. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
17 Znowu stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
18 Synu człowieczy! chleb swój z strachem jedz i wodę twoję ze drżeniem i z smutkiem pij,
“Ọmọ ènìyàn, jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ìwárìrì, sì mu omi rẹ pẹ̀lú ìwárìrì àti àìbalẹ̀ àyà.
19 A rzecz do ludu tej ziemi: Tak mówi panujący Pan o tych, którzy mieszkają w Jeruzalemie, o ziemi Izraelskiej: Chleb swój z smutkiem jeść, a wodę swą z trwogą pić będą, aby była ziemia jego złupiona z dostatków swoich dla bezprawia wszystkich mieszkających w niej;
Sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti ilẹ̀ Israẹli pé, pẹ̀lú àìbalẹ̀ àyà ni wọn yóò máa jẹun wọn, wọn yóò sì mu omi pẹ̀lú àìnírètí, kí ilẹ̀ wọn lè di ahoro torí ìwà ipá àwọn tó ń gbé ibẹ̀.
20 Także miasta, w których mieszkają, spustoszone będą, i ziemia spustoszeje; i dowiecie się, żem Ja Pan.
Ìlú tó jẹ́ ibùgbé ènìyàn tẹ́lẹ̀ yóò di òfo, ilẹ̀ náà yóò sì di ahoro. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
21 Stało się zaś słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
22 Synu człowieczy! cóż to za przypowieść u was o ziemi Izraelskiej, iż mówicie: Przedłużąć się dni, a z tego widzenia nic nie będzie?
“Ọmọ ènìyàn, irú òwe wo ni ẹ pa nílẹ̀ Israẹli pé: ‘A fa ọjọ́ gùn, gbogbo ìran di asán’?
23 Przetoż mów do nich: Tak mówi panujący Pan: Sprawię Ja to, iż ustanie ta przypowieść, a nie będą używać tej przypowieści więcej w Izraelu; powiedz im: I owszem, przybliżyły się te dni, i spełnienie wszelkiego widzenia.
Nítorí náà wí fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò fi òpin sí òwe yìí, wọn kò ní ipa mọ́ ní Israẹli.’ Sọ fún wọn, ‘Ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí nígbà tí gbogbo ìran àti ìsọtẹ́lẹ̀ yóò sì wá sí ìmúṣẹ.
24 Bo nie będzie więcej żadnego marnego widzenia, ani wieszczby pochlebcy w pośrodku domu Izraelskiego.
Nítorí kò ní sí ìran asán tàbí àfọ̀ṣẹ tí ó ń pọ́n ni mọ́ ní àárín ilé Israẹli.
25 Przeto, że Ja Pan mówić będę, a którekolwiek słowo wyrzekę, stanie się; nie pójdzie w długą, ale za dni waszych, domie odporny! wyrzekę słowo, i wypełnię je, mówi panujący Pan.
Ṣùgbọ́n, Èmi Olúwa yóò sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò sì ṣẹ láì falẹ̀. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ní àsìkò yín, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀ ilé ni Èmi yóò mú ọ̀rọ̀ yówù tí mo bá sọ ṣẹ.’”
26 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
27 Synu człowieczy! oto dom Izraelski mówią: To widzenie, które ten widzi, odwlecze się na wiele dni, a o dalekich czasach ten prorokuje;
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ń wí pé, ‘Ìran ọjọ́ pípẹ́ ni ìwọ rí, ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ nípa àsìkò tó jìnnà réré.’
28 Przeto im rzecz: Tak mówi panujący Pan: Nie pójdzieć w długą żadne słowo moje; ale słowo, które wyrzekę, stanie się, mówi panujący Pan.
“Nítorí náà sọ fún wọn, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, kò sí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ mi tí yóò sún síwájú mọ́; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí mo bá sọ yóò ṣẹ.’”

< Ezechiela 12 >