< Wyjścia 8 >

1 I rzekł Pan do Mojżesza: Wnijdź do Faraona, a mów do niego: Tak mówi Pan: Wypuść lud mój, aby mi służył.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Padà tọ Farao lọ kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni Olúwa wí: Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn ó bá à lè sìn mi.
2 Ale jeźli ty nie będziesz chciał puścić, oto, Ja zarażę wszystkie granice twoje żabami.
Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, èmi yóò fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀pọ̀lọ́ kọlu gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ.
3 I wyda rzeka żaby, które wylezą i wnijdą do domu twego, i do komory łoża twego, i na pościel twoję, i do domu sług twoich, i między lud twój, i do pieców twoich, i w dzieże twoje.
Odò Naili yóò kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀pọ̀lọ́. Wọn yóò gòkè wá sí ààfin rẹ, àti yàrá rẹ ni orí ibùsùn rẹ. Wọn yóò gòkè wá sí ilé àwọn ìjòyè rẹ àti sí ara àwọn ènìyàn rẹ, àti sí ibi ìdáná rẹ, àti sí inú ìkòkò ìyẹ̀fun rẹ.
4 Tak na cię, jako na lud twój, i na wszystkie sługi twoje polezą żaby.
Àwọn ọ̀pọ̀lọ́ yóò gun ara rẹ àti ara àwọn ìjòyè rẹ, àti ara gbogbo àwọn ènìyàn rẹ.’”
5 Tedy rzekł Pan do Mojżesza: Rzecz do Aarona: Wyciągnij rękę twoję z laską twą na rzeki, na strugi, i na jeziora, a wywiedź żaby na ziemię Egipską.
Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Sọ fún Aaroni, ‘Kí ó na ọwọ́ rẹ̀ jáde pẹ̀lú ọ̀pá sí orí àwọn odò kéékèèké àti odò ńlá, àti sí orí àwọn àbàtà kí ó sì mú àwọn ọ̀pọ̀lọ́ gòkè wá sí ilẹ̀ Ejibiti.’”
6 Tedy wyciągnął Aaron rękę swą na wody Egipskie, i wylazły żaby, które okryły ziemię Egipską.
Ní ìgbà náà ni Aaroni sì na ọwọ́ rẹ̀ jáde sí orí àwọn omi Ejibiti, àwọn ọ̀pọ̀lọ́ sì wá, wọ́n sì bo gbogbo ilẹ̀.
7 I uczynili także czarownicy czarami swemi, i wywiedli żaby na ziemię Egipską.
Ṣùgbọ́n àwọn onídán ilẹ̀ Ejibiti ṣe bákan náà pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn. Àwọn náà mú kí ọ̀pọ̀lọ́ gún wá sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
8 Zatem Farao wezwał Mojżesza i Aarona, mówiąc: Módlcie się Panu, aby oddalił żaby ode mnie, i od ludu mego; a wypuszczę lud, aby ofiarowali Panu.
Farao ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì sọ fún wọn pé, “Gbàdúrà sí Olúwa kí ó mú àwọn ọ̀pọ̀lọ́ wọ̀nyí kúrò lọ́dọ̀ mi àti lára àwọn ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ kí àwọn ènìyàn rẹ kí ó lọ láti rú ẹbọ sí Olúwa.”
9 I rzekł Mojżesz do Faraona: Poczczę cię tem, a powiedz, kiedy się modlić mam za cię, i za sługi twoje, i za lud twój, aby wytracone były żaby od ciebie, i z domów twoich, a tylko w rzece zostały.
Mose sọ fún Farao pé, “Jọ̀wọ́ sọ fún mi ìgbà ti èmi yóò gbàdúrà fún ọ àti àwọn ìjòyè rẹ àti fún àwọn ènìyàn rẹ, kí àwọn ọ̀pọ̀lọ́ wọ̀nyí bá lè lọ lọ́dọ̀ rẹ àti ní àwọn ilé yín tí wọn yóò sì wà nínú odò Naili nìkan.”
10 A on rzekł: Jutro. Tedy rzekł Mojżesz: Uczynię według słowa twego, abyś wiedział, że nie masz, jako Pan Bóg nasz.
Farao wí pé, “Ni ọ̀la.” Mose sì dáhùn pé, “Yóò sì rí bí ìwọ ti sọ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé kò sí ẹni bí Olúwa Ọlọ́run wa.
11 I odejdą żaby od ciebie, i od domów twoich, i od sług twoich, i od ludu twego, tylko w rzece zostaną.
Àwọn ọ̀pọ̀lọ́ yóò fi ìwọ àti àwọn ilé yín àti ìjòyè rẹ, àti àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, wọn yóò sì wà nínú Naili nìkan.”
12 Wyszedł tedy Mojżesz i Aaron od Faraona. I zawołał Mojżesz do Pana, aby odjął żaby, które był przepuścił na Faraona.
Lẹ́yìn tí Mose àti Aaroni tí kúrò ní iwájú Farao, Mose gbé ohùn ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ sókè sí Olúwa nípa àwọn ọ̀pọ̀lọ́ tí ó ti rán sí Farao.
13 I uczynił Pan według słowa Mojżeszowego, że wyzdychały żaby z domów, ze wsi, i z pól.
Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose tí béèrè. Àwọn ọ̀pọ̀lọ́ sì kú nínú ilé àti ní ìta, gbangba àti nínú oko.
14 I zgromadzali je na kupy, i zśmierdła się ziemia.
Wọ́n sì kó wọn jọ ni òkìtì òkìtì gbogbo ilẹ̀ sì ń rùn.
15 A widząc Farao, że miał wytchnienie, obciążył serce swoje, i nie usłuchał ich, jako był powiedział Pan.
Ṣùgbọ́n ni ìgbà tí Farao rí pé ìtura dé, ó sé ọkàn rẹ̀ le kò sì fetí sí Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí.
16 I rzekł Pan do Mojżesza: Mów do Aarona: Wyciągnij laskę twoję, a uderz w proch ziemi, aby się obrócił we wszy po wszystkiej ziemi Egipskiej.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Sọ fún Aaroni, ‘Na ọ̀pá rẹ jáde kí ó sì lu eruku ilẹ̀,’ jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni erùpẹ̀ ilẹ̀ yóò ti di kòkòrò-kantíkantí.” (Kòkòrò kan tí ó ní ìyẹ́ méjì tí ó ṣì ń ta ni.)
17 I uczynili tak; bo wyciągnął Aaron rękę swoję z laską swoją, i uderzył w proch ziemi; i były wszy na ludziach, i na bydle; wszystek proch ziemi obrócił się we wszy po wszystkiej ziemi Egipskiej.
Wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, nígbà tí Aaroni na ọwọ́ rẹ́ jáde pẹ̀lú ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, tí ó sì lu eruku ilẹ̀, kòkòrò-kantíkantí sì wà lára àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko wọn. Gbogbo eruku jákèjádò ilẹ̀ Ejibiti ni ó di kòkòrò-kantíkantí.
18 Czynili też także czarownicy, przez czary swoje, aby wywiedli wszy, ale nie mogli; i były wszy na ludziach i na bydle.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn onídán gbìdánwò láti da kòkòrò-kantíkantí pẹ̀lú agbára òkùnkùn wọn, wọn kò le è ṣé. Nígbà tí kòkòrò-kantíkantí sì wà lára àwọn ẹranko wọn,
19 Tedy rzekli czarownicy do Faraona: Palec to Boży jest. I zatwardziało serce Faraonowe, i nie usłuchał ich, jako powiedział Pan.
àwọn onídán sì sọ fún Farao pé, “Ìka Ọlọ́run ni èyí.” Ṣùgbọ́n àyà Farao sì yigbì, kò sì fetísílẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
20 I rzekł Pan do Mojżesza: Wstań rano, a stań przed Faraonem, (oto, wynijdzie do wody, ) i rzeczesz do niego: Tak mówi Pan: Wypuść lud mój, aby mi służył;
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù kí o sì ko Farao lójú bí ó ṣe ń lọ sí odò, kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó bá à lè sìn Mi.
21 Bo jeźli ty nie wypuścisz ludu mego, oto, Ja posyłam na cię, i na sługi twe, i na lud twój, i na domy twoje rozmaite robactwo; a będą napełnione domy Egipskie rozmaitem robactwem, nadto i ziemia, na której oni są.
Bí ìwọ kò bá jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, èmi yóò rán ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣinṣin sí ara rẹ àti sí ara àwọn ìjòyè rẹ, àti sí ara àwọn ènìyàn rẹ̀, sí àwọn ilẹ̀ rẹ̀. Gbogbo ilé àwọn ará Ejibiti ni yóò kún fún eṣinṣin àti orí ilẹ̀ tí wọ́n wà pẹ̀lú.
22 A oddzielę dnia onego ziemię Gosen, w której lud mój mieszka, aby tam nie było rozmaitego robactwa, abyś poznał, żem Ja Pan w pośrodku ziemi.
“‘Ṣùgbọ́n ni ọjọ́ náà, Èmi yóò ya ilẹ̀ Goṣeni sọ́tọ̀, níbi tí àwọn ènìyàn mi ń gbé, ọ̀wọ́ eṣinṣin kankan ki yóò dé ibẹ̀. Kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, mo wà ni ilẹ̀ yìí.
23 I położę znak odkupienia między ludem moim i między ludem twoim; jutro będzie znak ten.
Èmi yóò pààlà sáàárín àwọn ènìyàn mi àti àwọn ènìyàn rẹ. Àwọn iṣẹ́ ìyanu yìí yóò ṣẹlẹ̀ ni ọ̀la.’”
24 Tedy uczynił tak Pan. I przyszło rozmaite robactwo ciężkie na dom Faraonów, i na dom sług jego, i na wszystkę ziemię Egipską; i psowała się ziemia od rozmaitego robactwa.
Olúwa sì ṣe èyí. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ eṣinṣin sì ya wọ ààfin Farao àti sí ilé àwọn ìjòyè rẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ Ejibiti bàjẹ́ pẹ̀lú ọ̀wọ́ eṣinṣin wọ̀n-ọn-nì.
25 Zatem wezwał Farao Mojżesza i Aarona, i rzekł: Idźcie, ofiarujcie Bogu waszemu w tej ziemi.
Nígbà náà ni Farao ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa lọ kí ẹ sì rú ẹbọ sí Ọlọ́run yín ní ilẹ̀ yìí.”
26 I odpowiedział Mojżesz: Nie godzi się tak czynić; bo byśmy obrzydliwość Egipską ofiarowali Panu Bogu naszemu; a gdybyśmy ofiarowali obrzydliwość Egipską przed oczyma ich, zażby nas nie ukamionowali?
Ṣùgbọ́n Mose sọ pé, “Èyí ló tọ́, ẹbọ tí a ó rú sí Olúwa Ọlọ́run wa yóò jẹ́ ohun ìríra sí àwọn ará ilẹ̀ Ejibiti. Bí a bá ṣe ìrúbọ ti yóò jẹ́ ìríra ni ojú wọn ṣé wọn, ó ní sọ òkúta lù wá?
27 Drogę trzech dni pójdziemy na puszczą, i ofiarować będziemy Panu Bogu naszemu, jako nam rozkaże.
A gbọdọ̀ lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ fún wa.”
28 I rzekł Farao: Jać wypuszczę was, abyście ofiarowali Panu Bogu waszemu na puszczy, wszakże daleko nie odchodźcie, i módlcie się za mną.
Nígbà náà ni Farao wí pé, “Èmi yóò jẹ́ ki ẹ lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín nínú aginjù, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ rìn jìnnà jù. Ẹ gbàdúrà fún mi.”
29 I odpowiedział Mojżesz: Ja wychodzę od ciebie, i będę się modlił Panu, a odejdzie rozmaite robactwo od Faraona, od sług jego, i od ludu jego jutro; tylko niech więcej Farao nie kłamie, aby nie miał wypuścić ludu dla ofiarowania Panu.
Mose dáhùn ó wí pé, “Bí èmi bá ti kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa, àwọn ọ̀wọ́ eṣinṣin yóò fi Farao, àwọn ìjòyè rẹ, àti àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀ ní ọ̀la ṣùgbọ́n ǹjẹ́ ìdánilójú wa pé Farao kò tún ni lo ẹ̀tàn láti má jẹ́ kí àwọn ènìyàn kí ó lọ rú ẹbọ sí Olúwa.”
30 Wyszedłszy tedy Mojżesz od Faraona, modlił się Panu.
Nígbà náà ni Mose kúrò ni ọ̀dọ̀ Farao, ó sì gbàdúrà sí Olúwa;
31 I uczynił Pan według słowa Mojżeszowego, i oddalił ono rozmaite robactwo od Faraona, i od sług jego, i od ludu jego, a nie zostało i jednego.
Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti béèrè. Àwọn ọ̀wọ́ eṣinṣin kúrò lára Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti lára àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú, eṣinṣin kan kò sì ṣẹ́kù.
32 Jednak Farao obciążył serce swe i tym razem, a nie wypuścił ludu.
Ṣùgbọ́n ni àkókò yìí náà, Farao sé ọkàn rẹ le, kò sì jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.

< Wyjścia 8 >