< Wyjścia 4 >

1 Potem odpowiadając Mojżesz, rzekł: Ale oto, nie uwierzą mi, i nie usłuchają głosu mego, bo rzeką: Nie ukazał się tobie Pan.
Mose dáhùn ó sì wí pé, “Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gbà mí gbọ́ ń kọ́? Tàbí tí wọn kò fi etí sílẹ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi, tí wọn sì wí pé, ‘Olúwa kò farahàn ọ́’?”
2 I rzekł mu Pan: Cóż jest w ręce twojej? i odpowiedział: Laska.
Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún un pé, “Kí ni ó wà ní ọwọ́ rẹ n nì?” Ó sì dáhùn pé, “Ọ̀pá ni.”
3 I rzekł: Porzuć ją na ziemię; i porzucił ją na ziemię, a obróciła się w węża, i uciekał Mojżesz przed nim.
Olúwa sì sọ pé, “Sọ ọ̀pá náà sílẹ̀.” Mose sì sọ ọ̀pá náà sílẹ̀, lọ́gán ni ọ̀pá náà di ejò, ó sì sá fún un.
4 I rzekł Pan do Mojżesza: Wyciągnij rękę twoję, a ujmij go za ogon; i wyciągnął rękę swoję, i ujął go, i obrócił się w laskę w ręce jego.
Nígbà náà ni Olúwa wá sọ fún un pé, “Na ọwọ́ rẹ, kí o sì mú un ni ìrù.” Mose sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì mu ejò náà, ejò náà sì padà di ọ̀pá tí ó wà ni ọwọ́ rẹ̀.
5 Abyć uwierzyli, iż ci się ukazał Pan, Bóg ojców ich, Bóg Abrahamów, Bóg Izaaków, i Bóg Jakóbów.
Olúwa sì wí pé, “Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí wọn bá à le è gbàgbọ́ pé, Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu; tí farahàn ọ́.”
6 I rzekł mu Pan jeszcze: Włóż teraz rękę twoję w zanadrza twoje; i włożył rękę swoję w zanadrza swoje; i wyjął ją, a oto, ręka jego była trędowata jako śnieg.
Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Ti ọwọ́ rẹ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀.” Mose sì ti ọwọ́ rẹ̀ bọ inú aṣọ ní igbá àyà rẹ̀, ní ìgbà ti ó sì yọ ọ́ jáde, ọwọ́ rẹ̀ ti dẹ́tẹ̀, ó sì ti funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
7 I rzekł: Włóż znowu rękę twoję w zanadrza twe; i włożył znowu rękę swoję w zanadrza swe; a gdy ją wyjął z zanadrza swego, a oto, stała się znowu jako inne ciało jego.
Ó sì wí pé, “Nísinsin yìí, fi ọwọ́ náà padà sí abẹ́ aṣọ ní igbá àyà rẹ.” Mose sì ṣe bẹ́ẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ́ sípò bí àwọn ẹ̀yà ara rẹ̀ tókù.
8 I stanie się, jeźlić nie uwierzą i nie usłuchają głosu znaku pierwszego, tedy uwierzą głosowi znaku pośledniego.
Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, “Bí wọn kò bá gbà ọ́ gbọ́ tàbí kọ ibi ara sí iṣẹ́ ìyanu àkọ́kọ́, wọ́n le è ti ipasẹ̀ iṣẹ́ ìyanu kejì gbàgbọ́.
9 I stanie się, jeźli nie uwierzą ani tym dwom znakom, i nie usłuchają głosu twego, weźmiesz wody rzecznej, i wylejesz ją na ziemię; tedy się przemieni woda ona, którą weźmiesz z rzeki, a obróci się w krew na ziemi.
Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá gba àmì méjèèjì wọ̀nyí gbọ́, tí wọn kò sì fetí sí ọ̀rọ̀ rẹ, bu omi díẹ̀ láti inú odò Naili kí o si dà á sí orí ìyàngbẹ ilẹ̀, omi tí ìwọ bù láti inú odò yìí yóò sì di ẹ̀jẹ̀.”
10 I rzekł Mojżesz do Pana. Proszę Panie, nie jestem ja mężem wymownym ani przedtem ani odtąd, jakoś mówił do sługi twego: bom ciężkich ust i ciężkiego języka.
Mose sì sọ fún Olúwa pé, “Èmi jẹ́ akólòlò, èmi kì í ṣe ẹni tó lè sọ̀rọ̀ já gaara láti ìgbà àtijọ́ wá tàbí láti ìgbà ti o ti ń bá ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀, mo jẹ́ ẹni ti ahọ́n rẹ̀ lọ́, tí ó sì ń lọ́ra àti sọ̀rọ̀.”
11 A Pan mu rzekł: Któż uczynił usta człowiekowi? albo kto uczynił niemego, albo głuchego, albo widzącego, albo ślepego, izaż nie Ja Pan?
Olúwa sì sọ fún un pé, “Ta ni ó fún ènìyàn ni ẹnu? Ta ni ó mú un ya odi tàbí adití? Ta ni ó mú un ríran, tàbí mú un fọ́jú? Ǹjẹ́ kì í ṣe èmi Olúwa?
12 Idźże teraz, a Ja będę z usty twojemi, i nauczę cię, co byś miał mówić.
Lọ nísinsin yìí, Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò sì kọ́ ọ ni ohun ti ìwọ yóò sọ.”
13 I rzekł Mojżesz: Słuchaj Panie, poślij proszę tego, kogo posłać masz.
Mose dáhùn ó wí pé, “Olúwa jọ̀wọ́ rán ẹlòmíràn láti lọ ṣe iṣẹ́ yìí.”
14 I zapalił się gniew Pański na Mojżesza, i rzekł: Azaż nie wiem, iż Aaron, brat twój Lewita wymownym jest? a oto i ten wynijdzie przeciwko tobie, i ujrzawszy cię, uraduje się w sercu swojem.
Ìbínú Olúwa ru sókè sí Mose, ó sì sọ pé, “Aaroni ará Lefi arákùnrin rẹ ń kọ́? Mo mọ̀ pé ó lè sọ̀rọ̀ já gaara, ó ti wà ní ọ̀nà rẹ̀ báyìí láti pàdé e rẹ. Inú rẹ̀ yóò sì dùn ti ó bá rí ọ.
15 I będziesz mówił do niego, i włożysz słowa w usta jego, a Ja będę z usty twemi, i z usty jego, i nauczę was, co byście mieli czynić.
Ìwọ yóò sọ̀rọ̀ fún un, ìwọ yóò sì fi ọ̀rọ̀ sí i lẹ́nu, èmi yóò ràn yín lọ́wọ́ láti sọ̀rọ̀. Èmi yóò kọ́ ọ yín ni ohun ti ẹ ó ṣe.
16 On będzie mówił za cię do ludu, i stanie się, że on będzie tobie za usta, a ty mu będziesz za Boga;
Òun yóò bá ọ sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn, yóò sì dàbí i pé ẹnu un rẹ ni a gbà sọ ọ̀rọ̀ náà, ìwọ yóò sì dàbí Ọlọ́run ní iwájú rẹ̀.
17 Laskę też tę weźmij w rękę twoję, którą będziesz czynił znaki.
Ṣùgbọ́n mú ọ̀pá yìí ni ọwọ́ rẹ kí ìwọ bá à lè fi ṣe àwọn iṣẹ́ àmì ìyanu pẹ̀lú rẹ̀.”
18 Odszedł tedy Mojżesz, i wrócił się do Jetra, świekra swego, i mówił do niego: Pójdę teraz, a wrócę się do braci mojej, którzy są w Egipcie, a obaczę, sąli jeszcze żywi. A Jetro rzekł do Mojżesza: Idź w pokoju.
Mose padà sí ọ̀dọ̀ Jetro baba ìyàwó rẹ̀, ó sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ jẹ́ kí n padà tọ àwọn ènìyàn mi lọ ni ilẹ̀ Ejibiti láti wò bóyá wọ́n ṣì wà láààyè síbẹ̀.” Jetro sì dáhùn, ó wí pé, “Máa lọ ni àlàáfíà.”
19 I rzekł Pan do Mojżesza w ziemi Madyjańskiej: Idź, wróć się do Egiptu; pomarli bowiem wszyscy mężowie, którzy szukali duszy twojej.
Nísinsin yìí, Olúwa ti sọ fún Mose ni ilẹ̀ Midiani pé, “Máa padà lọ sí Ejibiti, nítorí àwọn ti ó fẹ́ pa ọ ti kú.”
20 Wziąwszy tedy Mojżesz żonę swą, i syny swe, wsadził je na osła, i wrócił się do ziemi Egipskiej; wziął też Mojżesz laskę Bożą w rękę swą.
Mose mú ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, ó kó wọn lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ padà sí Ejibiti. Ó sì mú ọ̀pá Ọlọ́run sí ọwọ́ rẹ̀.
21 I rzekł Pan do Mojżesza: Gdy pójdziesz i wrócisz się do Egiptu, patrzajże, abyś wszystkie cuda, którem Ja podał w rękę twoję, czynił przed Faraonem, a Ja zatwardzę serce jego, aby nie wypuścił lud.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ní ìgbà tí ìwọ bá padà sí Ejibiti rí i pé ìwọ ṣe iṣẹ́ ìyanu ni iwájú Farao. Èmi ti fún ọ lágbára láti ṣe é. Èmi yóò sì sé àyà rẹ̀ le, òun kì yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn náà kí ó lọ.
22 I rzeczesz do Faraona: Tak mówi Pan: Syn mój, pierworodny mój jest Izrael.
Lẹ́yìn náà, kí o sọ fún Farao pé, ‘Èyí ni Olúwa sọ: Israẹli ní àkọ́bí ọmọ mi ọkùnrin,
23 I rzekłem do ciebie: Wypuść syna mego, aby mi służył; a żeś go nie chciał wypuścić, oto, Ja zabiję syna twojego, pierworodnego twego.
mo sọ fún ọ, “Jẹ́ kí ọmọ mi lọ, ki òun kí ó lè máa sìn mí.” Ṣùgbọ́n ìwọ kọ̀ láti jẹ́ kí ó lọ; nítorí náà, èmi yóò pa àkọ́bí ọmọ rẹ ọkùnrin.’”
24 I stało się w drodze, w gospodzie, że zabieżał Pan Mojżeszowi, i chciał go zabić.
Ní ọ̀nà ìrìnàjò rẹ, ni ibi tí wọ́n gbé sùn ní ilé èrò ní alẹ́, Olúwa pàdé Mose, ó sì fẹ́ láti pa á.
25 Tedy wziąwszy Zefora krzemień ostry, obrzezała nieobrzezkę syna swego, i porzuciła przed nogi jego, i rzekła: Zaprawdę oblubieńcem krwi jesteś mi.
Ṣùgbọ́n Sippora mú ọ̀bẹ òkúta mímú, ó sì kọ ọmọ rẹ̀ ní ilà abẹ́, ó sì fi awọ rẹ̀ kan ẹsẹ̀ Mose. Sippora sì wí pé, “Ọkọ ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ jẹ́ sí mi.”
26 I odszedł od niego Pan. Tedy go nazwała oblubieńcem krwi, dla obrzezania.
Nítorí náà Olúwa yọ̀ǹda rẹ láti ìgbà tí ó ti wí pé, “Ẹlẹ́jẹ̀ ni ìwọ í ṣe.” Èyí tó túmọ̀ sí ìkọlà abẹ́.
27 I rzekł Pan do Aarona: Idź przeciwko Mojżeszowi na puszczą. I szedł i zaszedł mu na górze Bożej, i pocałował go.
Olúwa sì sọ fún Aaroni pé, “Lọ sínú aginjù láti lọ pàdé Mose.” Ní ìgbà náà ni ó lọ pàdé Mose ní orí òkè Ọlọ́run, ó sì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
28 Tedy powiedział Mojżesz Aaronowi wszystkie słowa Pana, który go posłał, i wszystkie znaki, które mu rozkazał.
Ní ìgbà náà ni Mose sì sọ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti rán fún Aaroni àti nípa gbogbo iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa ti pàṣẹ fún un láti ṣe ní iwájú Farao.
29 Szedłszy tedy Mojżesz z Aaronem, zgromadzili wszystkie starsze synów Izraelskich.
Mose àti Aaroni pe gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ.
30 I powiedział Aaron wszystkie słowa, które mówił Pan do Mojżesza, a Mojżesz czynił znaki przed oczyma ludu.
Aaroni sọ ohun gbogbo tí Olúwa sọ fún Mose fún wọn, ó sì ṣe iṣẹ́ àmì náà ní ojú àwọn ènìyàn náà.
31 I uwierzył lud, i zrozumieli, że nawiedził Pan syny Izraelskie, a iż wejżał na utrapienie ich; i schyliwszy się, pokłon uczynili.
Wọ́n sì gbàgbọ́. Nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Olúwa ti bẹ àwọn ọmọ Israẹli wò àti pé Olúwa ti gbọ́ nípa ìpọ́njú wọn, wọ́n tẹríba, wọ́n sì sìn ín. Ó sì ṣe àwọn iṣẹ́ àmì náà níwájú àwọn ènìyàn náà.

< Wyjścia 4 >