< Wyjścia 35 >

1 Potem zebrał Mojżesz wszystko zgromadzenie synów Izraelskich, i mówił do nich: Te są rzeczy, które rozkazał Pan, abyście je czynili.
Mose pe gbogbo ìjọ Israẹli ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ohun ti Olúwa ti pàṣẹ fún un yín láti ṣe.
2 Przez sześć dni odprawowana będzie robota; ale dzień siódmy będzie wam święty, sabbat odpocznienia Pańskiego; kto by weń robił robotę, umrze.
Fún ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje yóò jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún yín, ọjọ́ ìsinmi ni sí Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ni ọjọ́ náà ní a ó pa.
3 Nie rozniecicie ognia we wszystkich mieszkaniach waszych w dzień sabbatu.
Ẹ má ṣe dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”
4 Rzekł też Mojżesz do wszystkiego zgromadzenia synów Izraelskich, mówiąc: Tać jest rzecz, którą przykazał Pan mówiąc:
Mose sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ.
5 Złóżcie od siebie podarek Panu: każdy, kto jest ochotnego serca, przyniesie ten podarek Panu, złoto, i srebro, i miedź.
Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti: “wúrà, fàdákà àti idẹ;
6 I hijacynt, i szarłat, i karmazyn dwa kroć farbowany, i biały jedwab, i sierść kozią;
aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára; àti irun ewúrẹ́;
7 Skóry też baranie czerwono farbowane i skóry borsukowe, i drzewo sytym;
awọ àgbò tí a kùn ní pupa àti awọ màlúù; odò igi kasia;
8 I oliwę do świecenia, i rzeczy wonne na olejek pomazywania, i dla kadzenia wonnego;
òróró olifi fún títan iná; olóòórùn fún òróró ìtasórí, àti fún tùràrí dídùn;
9 Kamienie też onychiny, i kamienie do osadzania naramiennika i napierśnika.
òkúta óníkìsì àti òkúta tí a tò sí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
10 A wszyscy dowcipnego serca między wami przyjdą, i robić będą, cokolwiek rozkazał Pan:
“Gbogbo ẹni tí ó ní ọgbọ́n láàrín yín, kí ó wa, kí ó sì wá ṣe gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ:
11 Przybytek, namiot jego, i przykrycie jego, haczyki jego, i deski jego, drągi jego, słupy jego, i podstawki jego;
“àgọ́ náà pẹ̀lú àgọ́ rẹ àti ìbòrí rẹ̀, kọ́kọ́rọ́ rẹ̀, pákó rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, ọ̀wọ́n rẹ̀ àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀;
12 Skrzynie i drążki jej, ubłagalnią, i oponę do zasłony,
Àpótí náà pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀, ìbò àánú àti aṣọ títa náà tí ó síji bò ó.
13 Stół i drążki jego, ze wszystkiem naczyniem jego, i chleby pokładne;
Tábìlì náà pẹ̀lú òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀ àti àkàrà ìfihàn náà.
14 I świecznik do świecenia z naczyniem jego, i lampy jego, i oliwę do świecenia.
Ọ̀pá fìtílà tí ó wà fún títanná pẹ̀lú ohun èlò rẹ̀, fìtílà àti òróró fún títanná.
15 Ołtarz także do kadzenia z drążkami jego, i olejek pomazywania, i kadzenia wonne, i zasłonę do drzwi przybytku;
Pẹpẹ tùràrí náà pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀, òróró ìtasórí àti tùràrí dídùn; aṣọ títa fún ọ̀nà ìlẹ̀kùn ní ẹnu-ọ̀nà sí àgọ́ náà.
16 Ołtarz do całopalenia, i kratę jego miedzianą, drążki jego, i wszystkie naczynia jego, wannę z stolcem jej.
Pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú ojú ààrò idẹ rẹ̀, òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀; agbada idẹ pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
17 Opony do sieni, słupy jej, i podstawki jej, i zasłony do drzwi u sieni.
Aṣọ títa ti àgbàlá pẹ̀lú, ọ̀wọ́n àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀ àti aṣọ títa fún ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà.
18 Kołki do przybytku i kołki do sieni z sznurami jej.
Èèkàn àgọ́ náà fún àgọ́ náà àti fún àgbàlá àti okùn wọn.
19 Szaty służebne do usługiwania w świątnicy, szaty święte Aaronowi kapłanowi, i szaty synom jego, dla sprawowania urzędu kapłańskiego
Aṣọ híhun láti ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́ aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n sìn bí àlùfáà.”
20 Wyszło tedy wszystko zgromadzenie synów Izraelskich od obliczności Mojżeszowej.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì kúrò níwájú Mose,
21 I przyszedł każdy mąż, którego pobudziło serce jego, i każdy, w którym dobrowolny był duch jego, przynieśli podarek Panu do robienia namiotu zgromadzenia, i do wszelkiej potrzeby jego, i na szaty święte.
olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ àti ẹni tí ọkàn rẹ̀ gbé sókè wá, wọ́n sì mú ọrẹ fún Olúwa, fún iṣẹ́ àgọ́ àjọ, fún gbogbo ìsìn rẹ̀ àti fún aṣọ mímọ́ náà.
22 Przychodzili tedy mężowie z niewiastami, każdy, kto był ochotnego serca, przynosili zapony, i nausznice, i pierścienie, i manele, i wszelakie naczynia złote, i ktokolwiek przynosił ofiarę złotą Panu.
Gbogbo àwọn tí ó fẹ́, ọkùnrin àti obìnrin, wọ́n wá wọ́n sì mú onírúurú ìlẹ̀kẹ̀ wúrà: òrùka etí, òrùka àti ọ̀ṣọ́. Gbogbo wọn mú wúrà gẹ́gẹ́ bí ọrẹ wá fún Olúwa.
23 Każdy też co miał hijacynt, i szarłat, i karmazyn dwa kroć farbowany, i biały jedwab, i sierść kozią, i skóry baranie czerwono farbowane, i skóry borsukowe, przynosili.
Olúkúlùkù ẹni tí ó ni aṣọ aláró elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára, tàbí irun ewúrẹ́, awọ àgbò tí a rì ní pupa tàbí awọ màlúù odò, kí ó mú wọn wá.
24 Ktokolwiek ofiarował podarek srebra i miedzi, przynosili na ofiarę Panu, każdy też, co miał drzewo sytym, na wszelaką potrzebę ku usłudze przynosili.
Àwọn tí ó mú ọrẹ fàdákà tàbí idẹ wá, mú ọrẹ wá fún Olúwa, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ní igi ṣittimu fún ipa kankan nínú iṣẹ́ mú un wá.
25 I wszystkie niewiasty dowcipnego serca rękami swemi przędły, a przynosiły co naprzędły, hijacynt, i szarłat, karmazyn dwa kroć farbowany, i biały jedwab.
Gbogbo àwọn obìnrin tí ó ní ọgbọ́n ríran owú pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀, kí ó mú èyí ti ó ti ran wá ti aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó tàbí ti ọ̀gbọ̀ dáradára.
26 A wszystkie niewiasty których pobudziło serce ich umiejętne, przędły sierść kozią.
Gbogbo àwọn obìnrin tí ó fẹ́, tí ó sì ní ọgbọ́n ń ran òwú irun ewúrẹ́.
27 Przełożeni zasię przynosili kamienie onychiny, i kamienie do osadzania naramiennika i napierśnika.
Àwọn olórí mú òkúta óníkìsì wá láti tò ó lórí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
28 Także rzeczy wonne i oliwę do świecenia, i na olejek pomazywania i na wonne kadzenia.
Wọ́n sì tún mú olóòórùn àti òróró olifi wá fún títanná àti fún òróró ìtasórí àti fún tùràrí dídùn.
29 Każdy mąż i niewiasta, w których ochotne serce było do ofiarowania, na każdą robotę, którą rozkazał Pan czynić przez Mojżesza, przynosili synowie Izraelscy ofiarę dobrowolną Panu.
Gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli ọkùnrin àti obìnrin ẹni tí ó fẹ́ mú ọrẹ àtinúwá fún Olúwa fún gbogbo iṣẹ́ tí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn láti ṣe nípasẹ̀ Mose.
30 Zatem rzekł Mojżesz do synów Izraelskich: Oto, wezwał Pan z imienia Besaleela, syna Urowego, syna Churowego, z pokolenia Judy,
Nígbà náà ni Mose wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Wò ó, Olúwa ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
31 I napełnił go Duchem Bożym, mądrością, i umiejętnością wszelkiego rzemiosła;
Ó sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un, pẹ̀lú ọgbọ́n, òye, ìmọ̀ àti gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
32 I ku dowcipnemu wymyślaniu, cokolwiek może być urobione ze złota, i z srebra, i z miedzi;
Láti máa ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ,
33 Do rzezania kamienia ku osadzeniu, i na wyrobienie drzewa, do czynienia wszelakiej roboty zmyślnej.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò ó, láti fún igi àti láti ṣiṣẹ́ ni gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
34 Dał nadto do serca jego, aby uczyć mógł inszych, on, i Acholijab, syn Achysamechów z pokolenia Dan.
Ó sì fún òun àti Oholiabu ọmọ Ahisamaki ti ẹ̀yà Dani, ni agbára láti kọ́ àwọn tókù.
35 Napełnił je mądrością serca, aby robili wszelakie rzemiosło ciesielskie, i haftarskie, i tkackie z hijacyntu, i z szarłatu, z karmazynu dwa kroć farbowanego, i z białego jedwabiu tkacką robotą, aby robili każdą robotę dowcipnie wymyślając.
Ó sì fi ọgbọ́n kún wọn láti ṣe gbogbo onírúurú iṣẹ́, ti oníṣọ̀nà, ti ayàwòrán, ti aránsọ, ti aláṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ní ọ̀gbọ̀ dáradára àti ti ahunṣọ, gbogbo èyí tí ọ̀gá oníṣẹ́-ọnà àti ayàwòrán ń ṣe.

< Wyjścia 35 >