< Wyjścia 33 >

1 Potem mówił Pan do Mojżesza: Idź, rusz się stąd, ty i lud, któryś wywiódł z ziemi Egipskiej, do ziemi, o którąm przysiągł Abrahamowi, Izaakowi i Jakóbowi, mówiąc: Nasieniu twemu dam ją.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Fi ìhín yìí sílẹ̀, ìwọ àti àwọn ènìyàn tí o mú gòkè láti Ejibiti wá, kí ẹ sì gòkè lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ti pinnu ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu wí pé, ‘Èmi yóò fi fún irú-ọmọ rẹ.’
2 I poślę przed tobą Anioła, i wyrzucę Chananejczyka, Amorejczyka, i Hetejczyka, i Ferezejczyka, Hewejczyka, i Jebuzejczyka.
Èmi yóò rán angẹli ṣáájú yín, Èmi yóò sì lé àwọn Kenaani, àwọn ará Amori, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi jáde.
3 Do ziemi opływającej mlekiem i miodem; lecz sam nie pójdę z tobą, gdyżeś jest lud karku twardego, bym cię snać nie wytracił w drodze.
Ẹ gòkè lọ sí ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin. Ṣùgbọ́n èmi kò ní lọ pẹ̀lú yín, nítorí ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ̀yin, kí èmi má ba à run yín ní ọ̀nà.”
4 A usłyszawszy lud tę rzecz złą, zasmucił się, i nie włożył żaden ochędóstwa swego na się.
Nígbà tí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ọ̀rọ̀ ìparun wọ̀nyí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì ní kùn, ẹnìkankan kò sì le è wọ ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀.
5 Albowiem rzekł Pan do Mojżesza: Powiedz synom Izraelskim: Wyście ludem twardego karku; przyjdę kiedy z nagła w pośród ciebie, i wygładzę cię. Przetoż teraz złóż ochędóstwo twoje z siebie, a będę wiedział, coć bym uczynić miał.
Nítorí Olúwa ti wí fún Mose pé, “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ènìyàn Ọlọ́rùn líle ní ẹ̀yin, bí Èmi bá lè wá sí àárín yín ni ìṣẹ́jú kan, Èmi lè pa yín run. Nísìnsinyìí, bọ́ ohun ọ̀ṣọ́ rẹ kúrò, Èmi yóò sì gbèrò ohun tí Èmi yóò ṣe pẹ̀lú rẹ.’”
6 I złożyli synowie Izraelscy ochędóstwo swoje przy górze Horeb.
Bẹ́ẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bọ́ ohun ọ̀ṣọ́ wọn kúrò lára wọn ní òkè Horebu.
7 A Mojżesz wziąwszy namiot, rozbił go sobie za obozem, opodal od obozu, i nazwał go namiotem zgromadzenia. Tedy każdy, który chciał o co pytać Pana, wychodził do namiotu zgromadzenia, który był za obozem.
Mose máa ń gbé àgọ́ náà, ó sì pa á sí ìta ibùdó, ó jìnnà díẹ̀ sí ibùdó, ó pè é ni “Àgọ́ àjọ.” Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń béèrè Olúwa yóò lọ sí ibi àgọ́ àjọ náà ní ìta ibùdó.
8 A gdy wychodził Mojżesz do namiotu, powstawał wszystek lud, i stał każdy we drzwiach namiotu swego; i patrzali za Mojżeszem, aż wszedł do namiotu.
Nígbàkígbà tí Mose bá jáde lọ sí ibi àgọ́, gbogbo ènìyàn á dìde, wọ́n á sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn, wọn yóò máa wo Mose títí yóò fi wọ inú àgọ́ náà.
9 I bywało to, że gdy wchadzał Mojżesz do namiotu, zstępował słup obłokowy, a stawał u drzwi namiotu, i mawiał Bóg z Mojżeszem.
Bí Mose ṣe wọ inú àgọ́ náà, ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀ yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì dúró sí ẹnu ọnà, nígbà tí Olúwa ń sọ̀rọ̀ pẹ̀lú Mose.
10 A widząc wszystek lud słup obłokowy, stojący u drzwi namiotu, powstawał wszystek lud i kłaniał się każdy u drzwi namiotu swego.
Nígbàkígbà tí àwọn ènìyàn bá rí i ti ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀ bá dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, gbogbo wọn yóò dìde wọn yóò sì sìn, olúkúlùkù ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀.
11 I mawiał Pan do Mojżesza twarzą w twarz, jako mawia człowiek do przyjaciela swego; potem wracał się do obozu, a sługa jego Jozue, syn Nunów, młodzieniec, nie odchodził z pośrodku namiotu.
Olúwa máa ń bá Mose sọ̀rọ̀ lójúkojú, gẹ́gẹ́ bí i pé ènìyàn ń bá ọ̀rẹ́ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nígbà náà ni Mose yóò tún padà lọ sí ibùdó, ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọkùnrin Joṣua ìránṣẹ́ rẹ̀ ọmọ Nuni kò fi àgọ́ sílẹ̀.
12 Tedy mówił Mojżesz do Pana: Wej, ty mi mówisz: Prowadź lud ten, a tyś mi nie oznajmił, kogo poślesz ze mną? Nad to powiedziałeś: Znam cię z imienia, znalazłeś też łaskę w oczach moich.
Mose sọ fún Olúwa pé, “Ìwọ ti ń sọ fún mi, ‘Darí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,’ ṣùgbọ́n ìwọ kò jẹ́ kí ń mọ ẹni tí ìwọ yóò rán pẹ̀lú mi. Ìwọ ti wí pé, ‘Èmi mọ̀ ọ́n nípa orúkọ, ìwọ sì ti rí ojúrere mi pẹ̀lú.’
13 Teraz tedy, jeźlim znalazł łaskę w oczach twoich, ukaż mi proszę drogę twoję, żebym cię poznał, i żebym znalazł łaskę w oczach twoich, a obacz, że ludem twoim jest naród ten.
Bí ìwọ bá ní inú dídùn pẹ̀lú mi, kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, kí èmi kí ó lè mọ̀ ọ́n, kí n sì le máa wá ojúrere rẹ pẹ̀lú. Rántí wí pé orílẹ̀-èdè yìí ènìyàn rẹ ni.”
14 I odpowiedział Pan: Oblicze moje pójdzie przed tobą, a dam ci odpocznienie.
Olúwa dáhùn wí pé, “Ojú mi yóò máa bá ọ lọ, Èmi yóò sì fún ọ ní ìsinmi.”
15 I rzekł Mojżesz do niego: Nie pójdzieli oblicze twoje z nami, nie wywódź nas stąd.
Nígbà náà ni, Mose wí fún un pé, “Bí ojú rẹ kò bá bá wa lọ, má ṣe rán wa gòkè láti ìhín lọ.
16 Albowiem po czemże tu znać będzie, żem znalazł łaskę w oczach twoich, ja i lud twój? izali nie po tem, gdy pójdziesz z nami? bo tak oddzieleni będziemy, ja i lud twój, od każdego ludu, który jest na ziemi.
Báwo ni ẹnikẹ́ni yóò ṣe mọ̀ pé inú rẹ dùn pẹ̀lú mi àti pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ àyàfi ti o bá bá wa lọ? Kí ni yóò lè yà mí àti àwọn ènìyàn rẹ kúrò lára gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé?”
17 I rzekł Pan do Mojżesza: I tę rzecz, o którąś mówił, uczynię; boś znalazł łaskę w oczach moich, i znam cię z imienia.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi yóò ṣe ohun gbogbo tí ìwọ ti béèrè, nítorí inú mi dún sí o, Èmi sì mọ̀ ọ́n nípa orúkọ rẹ̀.”
18 Nad to rzekł Mojżesz: Ukaż mi proszę, chwałę twoję.
Mose sì wí pé, “Nísinsin yìí fi ògo rẹ hàn mí.”
19 A on odpowiedział: Ja sprawię, że przejdzie wszystko dobre moje przed twarzą twoją, i zawołam z imienia: Pan przed twarzą twoją; zmiłuję się, nad kim się zmiłuję; a zlituję się, nad kim się zlituję.
Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò sì mú gbogbo ìre mí kọjá níwájú rẹ, Èmi yóò sì pòkìkí orúkọ Olúwa níwájú rẹ. Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí Èmi yóò ṣàánú fún, Èmi yóò sì ṣoore-ọ̀fẹ́ fún ẹni tí Èmi yóò ṣoore-ọ̀fẹ́ fún.
20 I rzekł: Nie będziesz mógł widzieć oblicza mego; bo nie ujrzy mię człowiek, aby żyw został.
Ṣùgbọ́n,” ó wí pé, “Ìwọ kò le è rí ojú mi, nítorí kò sí ènìyàn kan tí ń rí mi, tí ó lè yè.”
21 I rzekł Pan: Oto, miejsce u mnie, a staniesz na opoce.
Olúwa sì wí pé, “Ibìkan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀dọ̀ mi, níbi tí o ti lè dúró lórí àpáta.
22 A gdy przechodzić będzie chwała moja, tedy cię postawię w rozpadlinie opoki, i zakryję cię dłonią moją, póki nie przejdę.
Nígbà tí ògo mi bá kọjá, Èmi yóò gbé ọ sínú pàlàpálá àpáta, Èmi yóò sì bò ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ mi títí Èmi yóò fi rékọjá.
23 Potem odejmę dłoń moję, i ujrzysz tył mój; ale twarz moja nie będzie widziana.
Nígbà tí Èmi yóò mú ọwọ́ mi kúrò, ìwọ yóò sì rí ẹ̀yìn mi; ṣùgbọ́n ojú mi ni o kò ní rí.”

< Wyjścia 33 >