< Wyjścia 23 >

1 Nie przyjmuj powieści kłamliwej; nie miej spółki z niepobożnym, abyś miał być świadkiem fałszywym.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ tan ìròyìn èké kalẹ̀. Ìwọ kò gbọdọ̀ ran ènìyàn búburú lọ́wọ́ láti jẹ́rìí èké.
2 Nie udawaj się za wielkością do złego, i nie mów tak za sprawą, cobyś się nakłonił za wielą ich ku podwróceniu sądu.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀pọ̀ ènìyàn láti ṣe aburú. Nígbà tí ìwọ bá jẹ́rìí sí ẹjọ́, ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po nípa gbígbé lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ènìyàn.
3 I nie szanuj ubogiego przy sprawie jego.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú sí tálákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.
4 Gdybyś natrafił wołu nieprzyjaciela twego, albo osła jego błądzącego, zwrócisz, a dowiedziesz go do niego.
“Bí ìwọ bá ṣe alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀tá rẹ tí ó ṣìnà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.
5 Jeźlibyś ujrzał, że osieł tego, który cię ma w nienawiści, leży pod brzemieniem swojem, azali zaniechasz, abyś mu pomóc nie miał? owszem poratujesz go pospołu z nim.
Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó kórìíra rẹ tí ẹrù ṣubú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.
6 Nie będziesz podwracał sądu ubogiemu twemu w sprawie jego.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.
7 Od rzeczy kłamliwej oddalisz się, a niewinnego i sprawiedliwego nie zabijesz; bo nie usprawiedliwię niezbożnego.
Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbí olódodo ènìyàn, nítorí Èmi kò ní dá ẹlẹ́bi láre.
8 Darów też brać nie będziesz, ponieważ dar zaślepia mądre, i wywraca słowa sprawiedliwych.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
9 Przychodnia też nie uciskaj: bo sami wiecie, jaki jest żywot przychodnia, boście byli przychodniami w ziemi Egipskiej.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ pọ́n àjèjì kan lójú, ẹ̀yin sa ti mọ inú àjèjì, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àjèjì ní ilẹ̀ Ejibiti.
10 Przez sześć lat obsiewać będziesz ziemię twoję, a będziesz zgromadzał urodzaj jej;
“Ní ọdún mẹ́fà ni ìwọ yóò gbin oko rẹ, ìwọ yóò sì kóre èso rẹ̀.
11 Ale siódmego roku zaniechasz jej; że odpocznie, aby jedli ubodzy ludu twego, a co zostanie po nich, zje zwierz polny. Także uczynisz winnicy twojej, i oliwnicy twojej.
Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, jẹ́ kí ilẹ̀ náà wà ní àìkọ àti ní àìlò, jẹ́ kí ilẹ̀ náà kí ó sinmi. Nígbà náà ni tálákà láàrín yín yóò rí oúnjẹ láti ibẹ̀. Ẹranko igbó yóò sì jẹ èyí tí wọ́n fi sílẹ̀. Ìwọ ṣe bákan náà pẹ̀lú ọgbà àjàrà rẹ àti ọgbà olifi rẹ.
12 Przez sześć dni będziesz odprawował roboty twoje; ale dnia siódmego odpoczniesz, aby sobie wytchnął wół twój, osieł twój, i żeby wytchnął syn niewolnicy twojej, i przychodzień.
“Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò ṣe iṣẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì sinmi ní ọjọ́ keje, kí akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ bá à lè ní ìsinmi, kí a sì tú ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àlejò ti ń gbé ni ilé rẹ lára.
13 A we wszystkiem, com wam powiedział, ostrożnymi bądźcie. Imienia też cudzych bogów nie wspominajcie, nie będzie słyszane z ust twoich.
“Ẹ máa ṣọ́ra, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo wí fún un yín. Ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà, kí a má ṣe gbọ́ orúkọ wọn ní ẹnu yín.
14 Trzy kroć święto obchodzić mi będziecie na każdy rok.
“Ní ìgbà mẹ́ta ni ìwọ yóò ṣe àjọ fún mi nínú ọdún.
15 Święta przaśników przestrzegać będziesz; siedem dni jeść będziesz przaśniki, jakom ci rozkazał, czasu miesiąca Abiba; boś weń wyszedł z Egiptu, a nie ukażecie się przed twarz moję próżnymi.
“Ṣe àjọ àkàrà àìwú; jẹ àkàrà ti kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje, bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ. Ṣe èyí ní àkókò tí a ti yàn ní oṣù Abibu, nítorí ni oṣù yìí ni ìwọ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú mi ní ọwọ́ òfo.
16 Także święto żniwa pierwiastek pracy twojej, cośkolwiek siał na polu; święto też zbierania na schodzie roku, gdy zbierzesz prace twoje z pola.
“Ṣe àjọ ìkórè pẹ̀lú èso àkọ́so ọ̀gbìn oko rẹ. “Ṣe àjọ àkójọ oko rẹ ní òpin ọdún, nígbà tí ìwọ bá kó ìre oko rẹ jọ tan.
17 Trzykroć do roku ukaże się każdy mężczyzna twój przed obliczem Panującego Pana.
“Ní ìgbà mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni àwọn ọkùnrin yín yóò máa wá fi ara hàn ní iwájú Olúwa Olódùmarè.
18 Nie będziesz ofiarował przy kwasie krwi ofiary mojej, ani zostanie przez noc tłustość ofiary mojej aż do poranku.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ rú ẹbọ ẹ̀jẹ̀ sí mi ti òun ti àkàrà tó ní ìwúkàrà. “Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rá ẹbọ àjọ mi ni kò gbọdọ̀ kù títí di òwúrọ̀.
19 Pierwiastki pierwszych urodzajów ziemi twej przyniesiesz w dom Pana Boga twego; nie będziesz warzył koźlęcia w mleku matki jego.
“Mú àkọ́ká èso ilẹ̀ rẹ tí ó dára jùlọ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ. “Ìwọ kò gbọdọ̀ bọ ọmọ ewúrẹ́ nínú omi ọmú ìyá rẹ̀.
20 Oto ja posyłam Anioła przed tobą, aby cię strzegł w drodze, i wprowadził cię na miejsce, którem ci zgotował.
“Kíyèsi èmi rán angẹli kan lọ ní iwájú rẹ, láti ṣọ́ ọ ni ọ̀nà àti láti mú ọ dé ibi ti mo ti pèsè sílẹ̀ fún.
21 Ostrożnym bądź przed oblicznością jego; a słuchaj głosu jego; nie drażnij go, boć nie przepuści przestępstwu waszemu, gdyż imię moje w nim jest.
Fi ara balẹ̀, kí o sì fetísílẹ̀ sí i, kí o sì gba ohùn rẹ̀ gbọ́; má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí i, nítorí kò ní fi àìṣedéédéé yín jì yín, orúkọ mi wà lára rẹ̀.
22 Bo jeźli pilnie słuchać będziesz głosu jego, i uczynisz, cokolwiek rzekę, nieprzyjacielem będę nieprzyjaciół twych, i trapić będę tych, którzy cię trapili.
Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí ohùn rẹ̀ tí ẹ sì ṣe ohun gbogbo ti mo ní kí ẹ ṣe, èmi yóò jẹ́ ọ̀tá àwọn ọ̀tá yín. Èmi yóò sì fóòro àwọn tí ń fóòro yín.
23 Pójdzie bowiem Anioł mój przed tobą, i wprowadzi cię do Amorejczyka, i Hetejczyka, i Ferezejczyka, i Chananejczyka, Hewejczyka, i Jebuzejczyka, i wytracę je.
Angẹli mi yóò lọ níwájú rẹ, yóò sì mú ọ dé ọ̀dọ̀ àwọn ará: Amori, Hiti, Peresi, Kenaani, Hifi àti Jebusi, èmi a sì gé wọn kúrò.
24 Nie kłaniajże się bogom ich, ani im służ, ani czyń według spraw ich; ale do gruntu popsujesz je, i wszcząt pokruszysz obrazy ich.
Ìwọ kò gbọdọ̀ foríbalẹ̀ fún òrìṣà wọn, bẹ́ẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n, tàbí kí ẹ tẹ̀lé ìṣe wọn. Kí ìwọ kí ó si wó wọn lulẹ̀, kí ìwọ kí ó sì fọ́ ère òkúta wọ́n túútúú.
25 Lecz służyć będziecie Panu Bogu waszemu, a on błogosławić będzie chlebowi twemu, i wodom twoim; i odejmę niemoc z pośrodku ciebie.
Ẹ̀yin yóò sí máa sin Olúwa Ọlọ́run yin, òun yóò si bùsi oúnjẹ rẹ. Èmi yóò mú àìsàn kúrò láàrín rẹ.
26 Nie będzie poroniająca ani niepłodna w ziemi twojej; liczbę dni twoich dopełnię.
Oyún kò ní bàjẹ́ lára obìnrin kan, bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan kì yóò yàgàn ni ilẹ̀ rẹ. Èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.
27 Strach mój puszczę przed tobą, i strwożę wszelki lud, przeciw któremu pójdziesz, i uczynię, że wszyscy nieprzyjaciele twoi podadzą tył przed tobą.
“Èmi yóò rán ẹ̀rù mi lọ ṣáájú rẹ, ìdàrúdàpọ̀ yóò sì wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ bá da ojú kọ. Èmi yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ yí ẹ̀yìn padà sí ọ, kí wọn sì sá ní iwájú rẹ.
28 Poślę też szerszenie przed tobą, które wypędzą Hewejczyka, Chananejczyka, i Hetejczyka przed oblicznością twoją.
Èmi yóò rán oyin ṣáájú rẹ láti lé àwọn ará: Hifi, Kenaani àti Hiti kúrò ni ọ̀nà rẹ.
29 Nie wyrzucę go przed obliczem twojem za jeden rok, by się snać ziemia w pustynią nie obróciła, a nie namnożyło się przeciwko tobie zwierza dzikiego.
Ṣùgbọ́n, Èmi kò ni lé gbogbo wọn jáde ni ọdún kan ṣoṣo, ki ilẹ̀ náà má ba à di ahoro, àwọn ẹranko búburú yóò sì ti pọ̀jù fún ọ.
30 Pomaluczku będę je wyrzucał od oblicza twego, aż się rozmnożysz i osiądziesz ziemię.
Díẹ̀díẹ̀ ni èmi yóò máa lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ, títí ìwọ yóò fi pọ̀ tó láti gba gbogbo ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ìní.
31 A położę granice twoje od morza czerwonego aż do morza Filistyńskiego, a od puszczy aż do rzeki; bo podam w ręce wasze obywatele ziemi, i wypędzisz je od oblicza twego.
“Èmi yóò fi ìdí òpin ààlà ilẹ̀ rẹ lélẹ̀ láti etí Òkun Pupa títí dé òkun àwọn ara Filistini, láti aṣálẹ̀ títí dé etí odò Eufurate, Èmi yóò fa àwọn ènìyàn ti ń gbé ilẹ̀ náà lé ọ lọ́wọ́, ìwọ yóò sì lé wọn jáde kúrò ní iwájú rẹ.
32 Nie postanowisz z nimi, ani z bogami ich przymierza.
Ìwọ kò gbọdọ̀ dá májẹ̀mú kankan pẹ̀lú wọn tàbí pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn.
33 Niech nie mieszkają w ziemi twej, by cię snać nie przywiedli do grzechu przeciwko mnie, gdybyś służył bogom ich, co by tobie było sidłem.
Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn gbé ni ilẹ̀ rẹ, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn yóò mú ọ dẹ́ṣẹ̀ sí mi: nítorí bí ìwọ bá sin òrìṣà wọn, èyí yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fun ọ nítòótọ́.”

< Wyjścia 23 >