< Wyjścia 2 >

1 I wyszedł mąż niektóry z domu Lewiego; który pojął córkę z pokolenia Lewiego.
Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
2 I poczęła ona niewiasta, a porodziła syna; a widząc go, że był nadobny, kryła go przez trzy miesiące.
Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
3 Ale gdy go nie mogła dłużej zataić, wzięła plecionkę z sitowia i obmazała ją klejem i smołą; a włożywszy w nię ono dziecię, położyła je między rogóż na brzegu rzeki.
Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
4 A stała siostra jego z daleka, aby wiedziała, co się z nim dziać będzie.
Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
5 Wtem wyszła córka Faraonowa, aby się kąpała w rzece, a panny jej przechadzały się po brzegu rzeki; i ujrzała plecionkę w rogoży, i posłała służebnicę swą, aby ją wzięła.
Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
6 A otworzywszy ujrzała dziecię, a ono chłopiątko płakało; a użaliwszy się go, rzekła: Z dziatek Hebrejskich jest ten.
ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
7 I rzekła siostra jego do córki Faraonowej: Chceszże, pójdę, i zawołam ci niewiasty, mamki Hebrejskiej, która być odchowała to dziecię?
Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
8 I rzekła jej córka Faraonowa: Idź. Tedy poszła ona dzieweczka, i zawołała matki onegoż dziecięcia.
Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
9 Do której rzekła córka Faraonowa: Weźmij to dziecię, i chowaj mi je, a ja tobie dam zapłatę twoję; i wziąwszy niewiasta dziecię, chowała je.
Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
10 A gdy podrosło ono dziecię, przywiodła je do córki Faraonowej, i było jej za syna; a nazwała imię jego Mojżesz, bo mówiła: Żem z wody wyciągnęła go.
Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
11 I stało się za onych dni, gdy urósł Mojżesz, że wyszedł do braci swej, i widział ciężary ich; obaczył też męża Egipczanina, który bił jednego Hebrajczyka z braci jego.
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
12 A obejrzawszy się tam i sam, gdy widział, że nikogo nie masz, zabił Egipczanina, i zagrzebł go w piasek.
Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
13 A wyszedłszy zaś dnia wtórego, ujrzał, a oto, dwaj mężowie Hebrejscy wadzili się; i rzekł onemu, który krzywdę czynił:
Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
14 Czemuż bijesz bliźniego swego? Ale mu odpowiedział: Któż cię postanowił książęciem i sędzią nad nami? albo mię ty myślisz zabić, jakoś zabił Egipczanina? i zląkł się Mojżesz i rzekł:
Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
15 Pewnie się ta rzecz wyjawiła. Usłyszał tedy Farao tę rzecz, i szukał zabić Mojżesza. Lecz Mojżesz uciekł od twarzy Faraonowej, i mieszkał w ziemi Madyjańskiej; a przyszedłszy tam siedział u studni.
Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
16 A kapłan Madyjański miał siedem córek, które wyszedłszy czerpały wodę, i nalewały do koryt, aby napoiły trzodę ojca swego;
Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
17 A przyszedłszy pasterze odganiali je. Tedy wstawszy Mojżesz obronił ich, i napoił bydło ich.
Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
18 A gdy się wróciły do Raguela, ojca swego, rzekł: Czemuście dziś tak prędko przyszły?
Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
19 I odpowiedziały: Mąż Egipski obronił nas od ręki pasterzów; nadto czerpając naczerpał nam i wody i napoił trzody.
Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
20 Zatem rzekł do córek swych: A gdzież ten jest? Czemuście opuściły człowieka tego? Zawołajcie go, aby jadł chleb.
Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
21 I przyzwolił Mojżesz mieszkać z onym mężem, który dał Zeforę, córkę swoję, Mojżeszowi.
Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
22 I urodziła syna, a nazwał imię jego Gerson, bo mówił: Byłem przychodniem w ziemi cudzej.
Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
23 I stało się po niemałym czasie, że umarł król Egipski; i wzdychali, i wołali synowie Izraelscy dla niewoli; a wstąpiło wołanie ich do Boga przed niewolą.
Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
24 I usłyszał Bóg wołanie ich; i wspomniał Bóg na przymierze swoje z Abrahamem, z Izaakiem, i z Jakóbem.
Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
25 I wejrzał Bóg na syny Izraelskie, i poznał Bóg.
Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.

< Wyjścia 2 >