< Wyjścia 13 >

1 I rzekł Pan do Mojżesza mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Poświęć mi wszelkie pierworodne; cokolwiek otwiera każdy żywot między syny Izraelskimi, tak z ludzi, jako z bydła; bo moje jest.
“Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin sọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ tèmi, ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”
3 Tedy rzekł Mojżesz do ludu: Pamiętajcież na ten dzień, któregoście wyszli z Egiptu, z domu niewoli; bo w możnej ręce wywiódł was Pan stamtąd; a tak nie będziecie jedli kwaszonego.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má ṣe jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.
4 Dziś wy wychodzicie, w miesiącu Abib.
Òní, ní oṣù Abibu (oṣù kẹta ọdún tiwa) lónìí ẹ̀yin ń jáde kúrò ní Ejibiti.
5 A gdy się wprowadzi Pan do ziemi Chananejczyka, i Hetejczyka, i Amorejczyka, i Hewejczyka, i Jebuzejczyka, o którą przysiągł ojcom twoim, abyć ją dał, ziemię opływającą mlekiem i miodem, tedy będziesz obchodził tę służbę w tymże miesiącu.
Ní ìgbà tí Olúwa mú un yín jáde wá sí ilẹ̀ Kenaani, Hiti, Amori, Hifi àti ilẹ̀ àwọn Jebusi; ilẹ̀ tí ó ti ṣe búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ẹ ni láti pa ìsìn yìí mọ́ ní oṣù yìí.
6 Przez siedem dni jeść będziesz przaśniki, a dnia siódmego będzie święto Panu.
Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà nínú àti pé ní ọjọ́ keje ni àjọ yóò wà fún Olúwa.
7 Przaśniki jeść będziecie przez siedem dni, i nie ukaże się u ciebie nic kwaszonego, ani widziano będzie kwas we wszystkich granicach twoich.
Kí ẹ̀yin ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje yìí; kó má ṣe sí ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe ní sàkání yín.
8 I opowiesz synowi twemu onegoż dnia, mówiąc: Dla tego, co mi uczynił Pan, gdym wychodził z Egiptu, obchodzę to.
Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, ‘Mo ń ṣe èyí nítorí ohun tí Olúwa ṣe fún mi nígbà tí èmi jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.’
9 I będziesz to miał za znak na ręce twojej, i na pamiętne przed oczyma twemi, aby Zakon Pański był w uściech twoich, ponieważ ręką możną wywiódł cię Pan z Egiptu.
Ṣíṣe èyí yóò wà fún àmì ní ọwọ́ rẹ, àti bí àmì ìrántí ni iwájú orí rẹ, tí yóò máa rán ọ létí òfin Olúwa ní ẹnu rẹ. Nítorí Olúwa mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá rẹ̀.
10 I będziesz strzegł ustawy tej na pewny czas, od roku do roku.
Ìwọ gbọdọ̀ pa òfin náà mọ́ ní àkókò tí a yàn bí ọdún tí ń gorí ọdún.
11 A gdy cię Pan wprowadzi do ziemi Chananejczyka, jako przysiągł tobie i ojcom twoim, i da ją tobie:
“Lẹ́yìn tí Olúwa tí mú ọ wá sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani tí ó sì fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí pẹ̀lú ìbúra fún ọ àti fún àwọn baba ńlá rẹ̀,
12 Tedy odłączysz wszystko, co otwiera żywot, Panu: i każdy płód otwierający żywot z bydła twego, każdy samiec będzie Panu.
ìwọ yóò fi àkọ́bí inú rẹ fún Olúwa. Gbogbo àkọ́bí ti ó jẹ́ akọ ti ẹran ọ̀sìn rẹ ní ó jẹ́ ti Olúwa.
13 Każde zaś pierworodne oślę odkupisz barankiem; a jeźlibyś nie odkupił, tedy złamiesz mu szyję; a każde pierworodne człowieka między synami twoimi odkupisz.
Ìwọ yóò fi ọ̀dọ́-àgùntàn ra àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, ǹjẹ́ kí ìwọ ṣẹ́ ẹ ní ọrùn, gbogbo àkọ́bí ọkùnrin ni kí ìwọ kí ó rà padà.
14 A gdyby cię spytał syn twój potem mówiąc: Cóż to jest? Tedy mu odpowiesz: Możną ręką wywiódł nas Pan z Egiptu, z domu niewoli.
“Yóò sí ṣe ní àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín yóò béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni èyí túmọ̀ sí?’ Kí ìwọ kí ó sọ fún wọn pé, ‘Pẹ̀lú ọwọ́ agbára ní Olúwa fi mú wa jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní oko ẹrú.
15 Bo gdy się był zatwardził Farao, nie chcąc nas wypuścić, tedy zabił Pan wszelkie pierworodne w ziemi Egipskiej, od pierworodnego z ludzi aż do pierworodnego z bydła. Dla tegoż ja ofiaruję Panu każdego samca, otwierającego żywot, ale każde pierworodne synów moich odkupuję.
Ní ìgbà ti Farao ṣe orí kunkun, ti ó kọ̀ láti jẹ́ kí a lọ, Olúwa pa gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, àti ènìyàn àti ẹranko. Ìdí èyí ni àwa fi ń fi gbogbo àkọ́bí tí í ṣe akọ rú ẹbọ sí Olúwa láti fi ṣe ìràpadà fún àwọn àkọ́bí wa ọkùnrin.’
16 I będzie to za znak na ręce twojej, i za naczelniki między oczyma twemi, iż w możnej ręce wywiódł nas Pan z Egiptu.
Èyí yóò sì jẹ́ àmì ni ọwọ́ yín àti àmì ní iwájú orí yín pé Olúwa mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá.”
17 I stało się, gdy wypuścił Farao lud, że nie prowadził ich Bóg drogą ziemi Filistyńskiej, chociaż bliższa była; bo mówił Bóg: By snać nie żałował lud, gdyby ujrzał przeciw sobie wojnę i nie wrócił się do Egiptu.
Ní ìgbà tí Farao jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ, Ọlọ́run kò mú wọn tọ ojú ọ̀nà ti ó la orílẹ̀-èdè àwọn Filistini kọjá, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀nà náà kúrú. Nítorí Ọlọ́run sọ pé, “Bí wọ́n bá dojúkọ ogun, wọ́n lè yí ọkàn wọn padà kí wọ́n padà sí ilẹ̀ Ejibiti.”
18 Ale obwodził Bóg lud drogą pustyni nad morzem czerwonem; i uszykowani wyszli synowie Izraelscy z ziemi Egipskiej.
Nítorí náà Ọlọ́run darí àwọn ènìyàn rọkọ gba ọ̀nà aginjù ní apá Òkun Pupa. Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ìmúra fún ogun.
19 Wziął też Mojżesz kości Józefowe z sobą dla tego, że był Józef przysięgą obowiązał syny Izraelskie, mówiąc: Zapewne nawiedzi was Bóg; przetoż wynieście kości moje stąd z sobą.
Mose kó egungun Josẹfu pẹ̀lú rẹ̀ nítorí Josẹfu tí mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra. Ó ti wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò dìde fún ìrànlọ́wọ́ yín ẹ sì gbọdọ̀ kó egungun mi lọ pẹ̀lú yín kúrò níhìn-ín yìí.”
20 I wyciągnąwszy z Suchotu położyli się obozem w Etam, na końcu puszczy.
Wọ́n sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n láti Sukkoti lọ, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu ní etí aginjù.
21 A Pan szedł przed nimi we dnie w słupie obłoku, aby je prowadził drogą, a w nocy w słupie ognia, aby im świecił, żeby szli we dnie i w nocy.
Olúwa sì ń lọ níwájú wọn, nínú ọ̀wọ̀n ìkùùkuu ní ọ̀sán láti máa ṣe amọ̀nà wọn àti ní òru nínú ọ̀wọ̀n iná láti máa tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn, kí wọn lè máa lọ nínú ìrìnàjò wọn ní tọ̀sán tòru.
22 Nie odejmował słupa obłokowego we dnie, ani słupa ognistego w nocy od ludu.
Ìkùùkuu náà kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ní ọ̀sán, bẹ́ẹ̀ ni, ọ̀wọ̀n iná kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ni òru, ní iwájú àwọn ènìyàn náà.

< Wyjścia 13 >