< Powtórzonego 5 >

1 Tedy zawoławszy Mojżesz wszystkiego Izraela; mówił do nich: Słuchaj Izraelu, ustaw i sądów, które ja dziś mówię w uszy wasze; nauczcie się ich, a przestrzegajcie tego, abyście je czynili.
Mose sì pe gbogbo Israẹli jọ, ó sì wí pé, Gbọ́ ìwọ Israẹli, gbọ́ ìlànà àti òfin tí mo mú wá sí etí ìgbọ́ ọ yín lónìí. Ẹ kọ wọ́n, kí ẹ sì ri dájú pé ẹ̀ ń ṣe wọ́n.
2 Pan, Bóg nasz, uczynił z nami przymierze na górze Horeb.
Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Horebu.
3 Nie z ojcy naszymi uczynił Pan to przymierze, ale z nami, którzyśmy tu dziś wszyscy żywi.
Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láààyè níbí lónìí.
4 Twarzą w twarz mówił Pan z wami na górze, z pośrodku ognia,
Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrín iná lórí òkè.
5 (A jam stał między Panem, i między wami na on czas, abym wam odnosił słowo Pańskie; boście się bali ognia, a nie wstąpiliście na górę) i rzekł:
(Ní ìgbà yìí, mo wà láàrín ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè.) Ó sì wí pé,
6 Jam jest Pan, Bóg twój, którym cię wywiódł z ziemi Egipskiej, z domu niewoli.
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
7 Nie będziesz miał bogów innych przede mną.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
8 Nie czyń sobie obrazu rytego, ani żadnego podobieństwa tych rzeczy, które są na niebie wzgórę, i które na ziemi nisko, i które w wodach pod ziemią;
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
9 Nie będziesz się im kłaniał, ani ich chwalił: bom Ja Pan, Bóg twój, Bóg zawisny w miłości, nawiedzający nieprawość ojców nad syny do trzeciego i do czwartego pokolenia tych, którzy mię nienawidzą;
Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
10 A czyniący miłosierdzie nad tysiącami tych, którzy mię miłują, i strzegą przykazań moich.
Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
11 Nie bierz imienia Pana, Boga twego, na daremno: bo się będzie mścił Pan nad tym, który imię jego na daremno bierze.
Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
12 Przestrzegaj dnia sobotniego, abyś go święcił, jakoć rozkazał Pan, Bóg twój.
Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín.
13 Przez sześć dni będziesz robił, i wykonasz wszelaką robotę twoję;
Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ.
14 Ale dnia siódmego jest odpocznienie Pana, Boga twego; nie czyń żadnej roboty, ty i syn twój, i córka twoja, i sługa twój, i służebnica twoja, i wół twój, i osieł twój, i każde bydlę twoje, i gość twój, który jest w bramach twoich, aby odpoczynął sługa twój, i służebnica twoja, jako i ty.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti akọ màlúù rẹ, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, àti ohun ọ̀sìn rẹ kan, àti àlejò tí ń bẹ nínú ibodè rẹ; kí ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin kí ó lè sinmi gẹ́gẹ́ bí ìwọ.
15 A pamiętaj, żeś był niewolnikiem w ziemi Egipskiej, i wywiódł cię Pan, Bóg twój, stamtąd ręką możną, i ramieniem wyciągnionem; przetoż ci przykazał Pan, Bóg twój, abyś obchodził dzień sobotni.
Sì rántí pé, ìwọ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yọ ọ́ kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe pàṣẹ fún ọ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.
16 Czcij ojca twego i matkę twoję, jakoć przykazał Pan, Bóg twój, aby przedłużone były dni twoje, i żebyć się dobrze działo na ziemi, którą Pan, Bóg twój, da tobie.
Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún ọ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́, àti kí ó lè dára fún ọ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
17 Nie będziesz zabijał.
Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
18 Nie będziesz cudzołożył.
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
19 Nie będziesz kradł.
Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
20 Nie będziesz mówił przeciw bliźniemu twemu świadectwa fałszywego.
Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
21 Nie będziesz pożądał żony bliźniego twego, ani będziesz pożądał domu bliźniego twego, roli jego, i sługi jego, i służebnicy jego, wołu jego, i osła jego, i wszystkich rzeczy, które są bliźniego twego.
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéji rẹ, oko rẹ̀, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéji rẹ.”
22 Teć słowa mówił Pan do wszystkiego zgromadzenia waszego na górze z pośrodku ognia, obłoku, i mgły, głosem wielkim, a nic więcej nie przydał, i napisał je na dwóch tablicach kamiennych, które mnie oddał.
Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ Olúwa tí a kéde rẹ̀ sí gbogbo ìpéjọpọ̀ ọ yín, níbẹ̀ ní orí òkè, láàrín iná, ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri, kò sì fi ohunkóhun kún un mọ́. Ó sì kọ wọ́n sínú wàláà méjì, Ó sì fi wọ́n lé mi lọ́wọ́.
23 I stało się, gdyście usłyszeli głos z pośrodku ciemności; gdy góra ogniem pałała, żeście przystąpili do mnie, wszystkie książęta pokoleń waszych, i starsi wasi,
Nígbà tí ẹ gbóhùn láti inú òkùnkùn wá, nígbà tí iná náà ń yọ iná lala, àwọn aṣáájú ẹ̀yà a yín àti àwọn àgbàgbà yín tọ̀ mí wá.
24 I mówiliście: Oto nam ukazał Pan, Bóg nasz, chwałę swoję, i wielmożność swoję, a głos jego słyszeliśmy, z pośrodku ognia; dziś widzieliśmy, że Bóg mówił z człowiekiem, a człowiek żyw został.
Ẹ sì sọ pé, “Olúwa Ọlọ́run wa ti fi ògo rẹ̀ hàn wá, àti títóbi rẹ̀ a sì ti gbóhùn rẹ̀ láti àárín iná wá. A ti rí i lónìí pé, ènìyàn sì lè wà láààyè lẹ́yìn tí Ọlọ́run bá bá a sọ̀rọ̀.
25 A tak teraz przeczże mamy pomrzeć? albowiem nas ten ogień wielki pożre; jeźli jeszcze słyszeć będziemy głos Pana, Boga naszego, pomrzemy.
Ṣùgbọ́n èéṣe tí àwa yóò fi kú? Iná ńlá yìí yóò jó wa run, bí àwa bá sì tún gbọ́ ohun Olúwa Ọlọ́run wa, àwa ó kú.
26 Albowiem cóż jest wszelkie ciało, aby słyszało głos Boga żywiącego, mówiącego z pośrodku ognia, jako my, a żywo zostało?
Ta ni nínú ẹlẹ́ran ara tí ó ti gbọ́ ohun Ọlọ́run alààyè láti inú iná rí, bí àwa ti gbọ́ ọ, tí a sì wà láyé?
27 Idźże ty, a wysłuchaj wszystkiego, co będzie mówił Pan, Bóg nasz; ty zaś powiesz nam wszystko, co do ciebie mówić będzie Pan, Bóg nasz, a my słuchać i czynić to będziemy.
Súnmọ́ tòsí ibẹ̀ kí o sì gbọ́ gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò sọ, nígbà náà sọ ohunkóhun tí Olúwa Ọlọ́run wa sọ fún ọ fún wa. A ó sì fetísílẹ̀, a ó sì gbọ́rọ̀.”
28 A usłyszawszy Pan głos słów waszych, gdyście mówili do mnie, rzekł mi Pan: Słyszałem głos słów ludu tego, które mówili do ciebie; dobrze wszystko mówili, co mówili.
Olúwa ń gbọ́ nígbà tí ẹ̀yin ń bá mi sọ̀rọ̀, Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti gbọ́ ohun tí àwọn ènìyàn yí sọ fún ọ. Gbogbo ohun tí wọ́n sọ dára,
29 Kto by im to dał, żeby serce ich było takie, aby się mnie bali, i strzegli wszystkich przykazań moich po wszystkie dni, aby się im dobrze działo i synom ich na wieki.
ìbá ti dára tó, bí ọkàn wọn bá lè bẹ̀rù mi, tí ó sì ń pa gbogbo òfin mi mọ́ nígbà gbogbo, kí ó bá à lè dára fún wọn, àti àwọn ọmọ wọn láéláé.
30 Idźże, a rzecz im: Wróćcie się do namiotów waszych.
“Lọ sọ fún wọn kí wọn padà sínú àgọ́ wọn.
31 A ty tu zostań przy mnie, i opowiem tobie wszystkie przykazania, i ustawy, i sądy, których ich nauczać będziesz, aby je czynili w ziemi, którą Ja im dawam, aby ją posiedli.
Ṣùgbọ́n ìwọ túbọ̀ dúró síbí pẹ̀lú mi, kí n bá à lè fún ọ ní àwọn àṣẹ tí o gbọdọ̀ fi kọ́ wọn láti máa tẹ̀lé ní ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún wọn láti ní.”
32 Przetoż strzeżcie, abyście czynili, jako wam rozkazał Pan, Bóg wasz, nie uchylając się na prawo ani na lewo.
Torí èyí, ẹ ṣọ́ra láti máa ṣe ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín tí pa ní àṣẹ fún un yín; ẹ má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì.
33 Wszelką też drogą, którą wam przykazał Pan, Bóg wasz, chodzić będziecie, abyście żyli, i dobrze się wam działo, i żebyście przedłużyli dni swoje na ziemi, którą posiądziecie.
Ẹ rìn ní gbogbo ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín, kí ẹ bá à le yè, kí ó sì dára fún un yín, kí ọjọ́ ọ yín bá à lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin yóò gbà.

< Powtórzonego 5 >