< Powtórzonego 32 >

1 Słuchajcie niebiosa, a mówić będę; niech słucha i ziemia wymowy ust moich.
Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
2 Kropić będzie jako deszcz nauka moja, popłynie jako rosa wymowa moja, jako drobny deszcz na zioła, a jako krople na trawę.
Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
3 Albowiem imienia Pańskiego będę wzywał; dajcież wielmożność Bogu naszemu,
Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
4 Skale, której sprawy są doskonałe; bo wszystkie drogi jego są sprawiedliwe. Boć jest Bóg prawdziwy, a nie masz w nim nieprawości, sprawiedliwy i prawy jest.
Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
5 Pokazili mu się, jakoby nie byli synami jego, sprosnością swoją, naród zły, a przewrotny.
Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
6 I także to oddawacie Panu, ludu głupi i szalony? izali nie on jest ojcem twoim, który cię sobie nabył? on cię uczynił, i stworzył cię.
Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
7 Wspomnij na dni dawne, uważajcie lata każdego wieku; spytaj ojca twego, a oznajmi tobie; starszych twoich, a powiedząć.
Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
8 Gdy rozdzielił dziedzictwa Najwyższy narodom, a rozsadził syny Adamowe, położył granice narodom według liczby synów Izraelskich;
Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
9 Albowiem działem Pańskim jest lud jego, Jakób sznurem dziedzictwa jego.
Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
10 Znalazł go w ziemi pustej, i na puszczy wielkiej i strasznej; obwodził go, uczył go, strzegł go, jako źrenicy oka swego.
Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
11 Jako orzeł wybawia orlęta swoje, nad orlętami swojemi latając, rozszerza skrzydła swoje, bierze je i nosi je na skrzydłach swoich;
Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
12 Tak Pan sam prowadził go, a żaden obcy bóg nie był z nim.
Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
13 Wyniósł go na wysokie miejsca ziemi, aby używał urodzajów polnych, i uczynił, aby ssał miód z skały i oliwę z opoki twardej;
Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
14 Aby jadł masło od krów, i mleko od owiec, z tłustością jagniąt, i barany odchowane w Basan, i kozły z tłustością ziarn pszenicznych, a pił czerwone wino wyborne.
Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
15 I roztył Izrael, i wierzgał (otyłeś, stłuściałeś, zgrubiałeś, i opuściłeś Boga, który cię uczynił, ) i lekce poważył Boga, opokę zbawienia swego.
Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
16 Ku zapalczywości pobudzili go przez cudze bogi, i przez obrzydliwości rozdraźnili go.
Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
17 Ofiarowali dyjabłom, nie Bogu, bogom, których nie znali, nowym, którzy z bliska przyszli, których się nie bali ojcowie wasi.
Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
18 Opoki, która cię spłodziła, zapomniałeś, zapomniałeś Boga, Stworzyciela twego.
Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
19 Co widząc Pan poruszył się gniewem na syny swoje, i na córki swoje.
Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
20 I rzekł: Skryję oblicze moje przed nimi, obaczę, jaki będzie koniec ich; albowiem są narodem przewrotnym, synami, w których wiary nie masz.
Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
21 Oni mię wzruszyli ku zapalczywości przez to, co nie jest Bogiem; pobudzili mię próżnościami swemi. Ja też do zazdrości pobudzę je przez te, którzy nie są ludem, przez naród głupi rozdraźnię je.
Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
22 Albowiem ogień rozpalił się w popędliwości mojej, i będzie gorzał aż do najgłębszego piekła, i pożre ziemię, i urodzaj jej, i wypali grunty gór. (Sheol h7585)
Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol h7585)
23 Zgromadzę na nie złe rzeczy, strzały moje na nie wystrzelam.
“Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
24 Zniszczeją od głodu, i będą strawieni gorączką, i śmiercią gorzką; zęby też bestyi poślę na nie, z jadem gadzin ziemskich.
Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
25 Zewnątrz osieroci je miecz, a w pokojach będzie strach, tak na młodzieńca, jako na pannę, na ssącego piersi, i na męża sędziwego.
Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
26 Rzekłem: Rozproszę je po kątach, i wygubię między ludźmi pamiątkę ich.
Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
27 Gdybym się na pychę nieprzyjaciół nie oglądał, by się snać nie podnieśli nieprzyjaciele ich, a nie rzekli: Ręka nasza wyniosła, a nie Pan, sprawiła to wszystko.
nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
28 Albowiem ten naród ginie przez rady swe, i nie ma rozumu.
Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
29 O by mądrymi byli! wyrozumieliby to, i oglądaliby się na ostatnie rzeczy swoje.
Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
30 Jakoby uganiał jeden z nich tysiąc, a dwaj goniliby dziesięć tysięcy! gdyby ich Bóg, opoka ich, nie zaprzedał, i Pan ich nie wydał:
Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
31 Albowiem nie jako skała nasza skała ich, co nieprzyjaciele nasi sami osądzą.
Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
32 Albowiem z macicy Sodomskiej macica ich, i z latorośli Gomorskich jagody ich, jagody jadowite, grona ich gorzkie.
Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
33 Jad smoczy wino ich, i trucizną żmij okrutną.
Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
34 Izali to nie jest skryto u mnie; zapieczętowano w skarbie moim?
“Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
35 Mojać jest pomsta i nagroda; czasu swego powinie się noga ich, ponieważ bliski jest dzień zginienia ich, a spieszą się przyszłe rzeczy do nich.
Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
36 Albowiem sądzić będzie Pan lud swój, a sług swoich użali się, gdy ujrzy, że ustała siła, a iż tak pojmany, jako zostawiony, nic nie mogą.
Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
37 I rzecze: Gdzież bogowie ich? Ona opoka, w której ufali?
Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
38 Którzy tłustość ofiar ich jadali, i pijali wino ofiar ich mokrych? Niechże wstaną, i ratują was, i niechaj będą ucieczką waszą.
ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
39 Obaczcież teraz, żem Ja, Jam jest sam, a że nie masz bogów oprócz Mnie; Ja zabijam i ożywiam, zranię, i Ja uleczę, a nie masz kto by z ręki mojej wyrwał.
“Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
40 Albowiem podniosę ku niebu rękę moję, i rzekę: Żyję Ja na wieki.
Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
41 Jeźli zaostrzę błyszczący się miecz swój, i porwie sąd ręka moja, oddam pomstę nieprzyjaciołom moim, i tym, którzy mię nienawidzą, nagrodzę.
nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
42 Opoję strzały moje krwią, a miecz mój naje się mięsa ze krwi pobitych i pojmanych, skoro zacznę mścić się nad nieprzyjacioły.
Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
43 Weselcie się narodowie z ludem jego; albowiem krwi sług swoich pomści się, i pomstę odda nieprzyjaciołom swoim, a miłościw będzie ziemi swojej, i ludowi swemu.
Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
44 Tedy przyszedł Mojżesz, i mówił wszystkie słowa pieśni tej w uszach ludu tego, on i Jozue, syn Nunów.
Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
45 A gdy dokonał Mojżesz mówić tych wszystkich słów do wszystkiego Izraela,
Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
46 Rzekł do nich: Przyłóżcie serca wasze do wszystkich słów, któremi się ja oświadczam przeciwko wam dziś, abyście je przykazywali synom waszym, żeby strzegli i pełnili wszystkie słowa zakonu tego;
Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
47 Albowiem to słowo nie ma być próżne u was, gdyż jest żywotem waszym; i w tem słowie przedłużycie dni na ziemi, do której się przeprawiacie przez Jordan, abyście ją osiedli.
Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
48 I rzekł Pan do Mojżesza tegoż dnia, mówiąc:
Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
49 Wstąp na tę górę Abarym, na górę Nebo, która jest w ziemi Moabskiej przeciw Jerychu, a oglądaj ziemię Chananejską, którą Ja dawam synom Izraelskim w osiadłość.
“Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
50 I umrzesz na tej górze, na którą wstąpisz, i będziesz przyłączony do ludu twego, jako umarł Aaron, brat twój, na górze Hor, i przyłączon jest do ludu swego;
Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
51 Dla tego żeście wystąpili przeciwko mnie w pośród synów Izraelskich przy wodach w poswarku w Kades na puszczy Syn, i żeście mię nie poświęcili w pośród synów Izraelskich.
Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
52 Bo przed sobą oglądasz ziemię; ale tam nie wnijdziesz, do tej ziemi, którą ja daję synom Izraelskim.
Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”

< Powtórzonego 32 >