< Powtórzonego 29 >

1 Teć są słowa przymierza, które przykazał Pan Mojżeszowi postanowić z synami Izraelskimi w ziemi Moabskiej nad ono przymierze, które postanowił z nimi na Horeb.
Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
2 Zwołał tedy Mojżesz wszystkiego Izraela, i mówił do nich: Wyście widzieli wszystko, co czynił Pan przed oczyma waszemi w ziemi Egipskiej Faraonowi, i wszystkim sługom jego, i całej ziemi jego;
Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
3 Pokusy wielkie, które widziały oczy twoje, znaki, i cuda one wielkie.
Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
4 Ale nie dał wam Pan serca ku zrozumieniu, i oczu ku widzeniu, ani uszu ku słyszeniu, aż do dnia dzisiejszego.
Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
5 I prowadziłem was przez czterdzieści lat po puszczy; nie wiotszały szaty wasze na was, i obuwie wasze nie wiotszało na nogach waszych.
Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
6 Chlebaście nie jedli, i wina, i mocnego napoju nie piliście, abyście wiedzieli żem Ja Pan, Bóg wasz.
O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
7 A gdyście przyszli na to miejsce, wyciągnął Sehon, król Heseboński, i Og, król Basański, przeciwko nam ku bitwie, i poraziliśmy je.
Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
8 A wziąwszy ziemię ich, podaliśmy ją w dziedzictwo Rubenitom, i Gadytom, i połowie pokolenia Manasesowego.
A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
9 A tak przestrzegajcież słów przymierza tego, i czyńcie je, aby się wam szczęśliwie powodziło, wszystko, co czynić będziecie.
Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
10 Wy stoicie dziś wszyscy przed Panem, Bogiem waszym, książęta wasze w pokoleniach waszych, starsi wasi, i przełożeni wasi, wszyscy mężowie Izraelscy;
Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
11 Dziatki wasze, żony wasze, i przychodzień twój, który mieszka w pośrodku obozu twego, od tego, który drwa rąbie, aż do tego, co wodę czerpie;
pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
12 Abyś wszedł w przymierze Pana, Boga twego, i w przysięgę jego, którą Pan, Bóg twój, stanowi z tobą dziś;
O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
13 Aby cię sobie dziś wystawił za lud, a sam żeby tobie był za Boga, jakoć powiedział, i jako przysiągł ojcom twoim Abrahamowi, Izaakowi i Jakóbowi.
láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
14 A nie tylko z wami samymi ja stanowię to przymierze, i tę przysięgę;
Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
15 Ale z każdym, który tu stoi dziś z nami przed Panem, Bogiem naszym, i z każdym, którego tu nie masz z nami dziś.
tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
16 Wy bowiem wiecie, jakośmy mieszkali w ziemi Egipskiej, i jakośmy przeszli przez pośrodek narodów, któreście przeszli;
Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
17 I widzieliście obrzydliwości ich, i bałwany ich, drewno i kamień, srebro i złoto, które są przy nich.
Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
18 Niechże nie będzie między wami mąż, albo niewiasta, albo dom, albo pokolenie, którego by się dziś serce odwróciło od Pana, Boga naszego, żeby szedł, a służył bogom narodów onych, by snać nie był między wami jaki korzeń, wydawający żółć i piołun;
Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
19 Bo kto by słuchał słów przeklęstwa tego, a błogosławiłby sobie w sercu swem, mówiąc: Pokój mi będzie, chociaż według zdania serca mego chodzić będę, przydawając pijaną do upragnionej.
Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
20 Ale Pan nie chce odpuścić takowemu; lecz zaraz zapali się gniew Pański, a zapalczywość jego przeciwko mężowi temu, i przypadnie nań wszystko przeklęstwo, które jest napisane w tych księgach, i wygładzi Pan imię jego pod niebem;
Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
21 I wyłączy go Pan na złe jego ze wszystkich pokoleń Izraelskich, według każdego przeklęstwa przymierza napisanego w księgach zakonu tego,
Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
22 Tak, że rzecze naród potomny, synowie wasi, którzy powstaną po was, i cudzoziemiec, który przyjdzie z ziemi dalekiej ( gdy obaczą plagi ziemi tej, i niemoce jej, któremi ją zarazi Pan;
Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
23 Bo siarka i sól wypali tę wszystkę ziemię, że nie będzie osiewana, ani też rodzić będzie, i nie zrośnie na niej żadna trawa, na kształt podwrócenia Sodomy i Gomorry, Adamy i Seboim, które podwrócił Pan w gniewie swym, i w popędliwości swej.)
Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
24 Tak rzeką wszyscy narodowie: Przeczże tak Pan uczynił tej ziemi? cóż to za gniew tej wielkiej zapalczywości?
Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
25 I odpowiedzą: Przeto, że opuścili przymierze Pana, Boga ojców swych, które postanowił z nimi, gdy je wywiódł z ziemi Egipskiej.
Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
26 Albowiem poszli, a służyli bogom cudzym, i kłaniali się im; bogom, których oni nie znali, i którzy im nic nie udzielili.
Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
27 Przetoż zapalił się Pan gniewem przeciwko tej ziemi, aby przywiódł na nie wszelkie przeklęstwo napisane w tych księgach.
Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
28 I wykorzenił je Pan z ziemi ich w gniewie i w zapalczywości, a w popędliwości wielkiej, i wyrzucił je do ziemi obcej, jako dziś widzicie.
Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
29 Rzeczy tajemne należą Panu, Bogu naszemu, a jawne nam i synom naszym aż na wieki, abyśmy czynili wszystkie słowa zakonu tego.
Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.

< Powtórzonego 29 >