< Powtórzonego 24 >

1 Gdyby pojął kto żonę, a stałby się jej małżonkiem, a przydałoby się, żeby nie znalazła łaski w oczach jego, przeto, że znalazł przy niej co sprośnego, tedy jej napisze list rozwodny i da w rękę jej, a puści ją z domu swego.
Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
2 A gdyby wyszła z domu jego, a odszedłszy szłaby za drugiego męża;
tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
3 A mając ją w nienawiści on mąż drugi, napisałby jej list rozwodny, i dałby w rękę jej i puściłby ją z domu swego; albo jeźliby też umarł on mąż drugi, który ją był pojął sobie za żonę:
àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
4 Nie będzie mógł mąż jej pierwszy, który ją był opuścił, znowu jej pojąć, aby mu była żoną, gdyż jest splugawiona; albowiem obrzydliwością to jest przed obliczem Pańskiem. Przetoż nie dopuszczaj grzeszyć ziemi, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie w dziedzictwo.
nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
5 Gdyby się kto świeżo ożenił, nie wynijdzie na wojnę, ani nań włożona będzie jaka praca; wolen będzie w domu swym przez cały rok weseląc się z żoną swoją, którą pojął.
Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
6 Nikt nie weźmie w zastawie zwierzchniego i spodniego kamienia młyńskiego; bo takowy jakoby duszę brał w zastawie.
Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
7 Jeźliby kto był znalezion, coby ukradł człowieka z braci swej, synów Izraelskich, a handlowałby nim, i sprzedał go, tedy umrze on złodziej, i odejmiesz złe z pośrodku siebie.
Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
8 Strzeż się zarazy trądu, a przestrzegaj pilnie, żebyś czynił wszystko, czego was nauczą kapłani Lewitowie; jakom im rozkazał, przestrzegać tego, i czynić to będziecie.
Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
9 Pamiętaj co uczynił Pan, Bóg twój, Maryi w drodze, gdyście wyszli z Egiptu.
Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
10 Gdy pożyczysz czego bliźniemu twemu, nie wchodźże do domu jego, abyś wziął co w zastawie od niego.
Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
11 Ale na dworze zostaniesz, a człowiek, któremuś pożyczył, wyniesie do ciebie zastaw przed dom.
Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
12 A jeźliby on człowiek był ubogi, nie układziesz się z zastawem jego.
Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
13 Bez omieszkania wrócisz mu on zastaw, gdy słońce zajdzie, żeby leżał na odzieniu swem, i błogosławił ci; a będzieć to sprawiedliwością przed Panem, Bogiem twoim.
Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
14 Nie uczynisz krzywdy najemnikowi ubogiemu, i potrzebnemu z braci twojej, albo z cudzoziemców twoich, którzy są w ziemi twej, w bramach twoich.
Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
15 Tegoż dnia dasz mu zapłatę jego przed zajściem słońca, albowiem ubogi jest, a z tego żywi duszę swoję; żeby nie wołał przeciwko tobie do Pana, a zostałby na tobie grzech.
San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
16 Nie umrą ojcowie za syny, a synowie nie umrą za ojce; każdy za grzech swój umrze.
Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
17 Nie wywrócisz sądu przychodniowi, ani sierocie, ani weźmiesz w zastawie szaty wdowy;
Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
18 Ale pamiętaj, żeś niewolnikiem był w Egipcie, a iż cię wybawił Pan, Bóg twój, stamtąd; dla tegoż ja przykazuję tobie, abyś to czynił.
Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
19 Gdybyś żął zboże twoje na roli twojej, a zapamiętałbyś snopa na polu, nie wracaj się, abyś go wziął; przychodniowi, sieroci, i wdowie to będzie, abyć błogosławił Pan, Bóg twój, w każdej sprawie rąk twoich.
Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
20 Gdy będziesz obierał oliwki twoje, nie oglądajże się na każdą gałązkę za sobą; przychodniowi, sierocie, i wdowie to będzie.
Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
21 Gdy będziesz obierał winnicę twoję, nie zbierajże gron pozostałych za tobą; przychodniowi, sierocie, i wdowie to będzie.
Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
22 A pamiętaj, iżeś był niewolnikiem w ziemi Egipskiej; przetoż ja tobie przykazuję, abyś to czynił.
Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.

< Powtórzonego 24 >