< Powtórzonego 2 >

1 Potem obróciwszy się, poszliśmy na puszczą, drogą ku morzu czerwonemu, jako mówił Pan do mnie, i krążyliśmy około około góry Seir przez wiele dni.
Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
2 Tedy rzekł Pan do mnie, mówiąc:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
3 Dosycieście już krążyli około tej góry, obróćcież się ku północy;
“Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
4 A ludowi rozkaż mówiąc: Wy wnet pójdziecie przez granice braci waszej, synów Ezawowych, którzy mieszkają w Seir, i będą się was bali; ale się i wy pilnie strzeżcie.
Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
5 Nie drażnijcież ich; albowiem nie dam wam ziemi ich, ani na stopę nogi, gdyżem w osiadłość dał Ezawowi górę Seir.
Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
6 Żywność będziecie kupowali u nich za pieniądze, i jeść będziecie; także i wodę od nich kupować będziecie za pieniądze, i pić będziecie.
Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
7 Albowiem ci Pan, Bóg twój, błogosławił we wszelkiej sprawie rąk twoich, i wiedział drogę twoję na tej puszczy wielkiej; już przez czterdzieści lat Pan, Bóg twój, był z tobą, nie schodziłoć na niczem.
Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
8 Poszliśmy tedy od braci naszej, synów Ezawowych, mieszkających w Seir, drogą równą od Elat, i od Asyjongaber, a nawróciwszy się udaliśmy się drogą ku puszczy Moabskiej.
Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
9 I rzekł Pan do mnie: Nie nacieraj na Moabczyki, ani podnoś wojny przeciwko nim; boć nie dam ziemi ich w osiadłość, gdyżem synom Lotowym dał Ar w dziedzictwo.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
10 (Emitowie pierwej mieszkali w niej, lud potężny i wielki, i wysokiego wzrostu, jako Enakimowie;
(Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
11 Które też za olbrzymy miano, jako Enakimy, a Moabczykowie zwali je Emim.
Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
12 Także w Seir mieszkali Horejczycy przedtem, które synowie Ezawowi wygnali, i wygładzili je przed sobą, a mieszkali na miejscu ich, jako uczynił Izrael w ziemi osiadłości swojej, którą im dał Pan.)
Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
13 Wstańcież tedy, a przeprawcie się przez potok Zared; i przeprawiliśmy się przez potok Zared.
Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
14 A czasu, któregośmy chodzili od Kades Barne, ażeśmy się przeprawili przez potok Zared, było trzydzieści i osiem lat, aż wyginął wszystek on naród mężów walecznych z obozu, jako im był przysiągł Pan.
Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
15 Albowiem ręka Pańska była przeciwko nim na wytracenie ich z obozu, aż ich wygubiła.
Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
16 I stało się, gdy wyginęli wszyscy mężowie waleczni, i pomarli z pośrodku ludu,
Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
17 Że rzekł Pan do mnie, mówiąc:
Olúwa sọ fún mi pé,
18 Ty dziś przejdziesz granicę Moabską Ar,
“Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
19 I przyjdziesz blisko ku synom Ammonowym; nie nacierajże na nie, ani podnoś wojny przeciwko nim; boć nie dam ziemi synów Ammonowych w osiadłość, ponieważ synom Lotowym dałem ją w dziedzictwo.
Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
20 (Tę też ziemię za ziemię olbrzymów miano; albowiem olbrzymowie mieszkali w niej przedtem, które Ammonitowie nazywali Zomzomim;
(A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
21 Lud potężny, i wielki, i wysokiego wzrostu, jako Enakimowie; ale wygubił je Pan przed nimi, a Ammonitowie opanowali je i mieszkali na miejscu ich;
Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
22 Jako uczynił synom Ezawowym mieszkającym w Seir, dla których wytracił Horejczyki przed obliczem ich; i wygnali je, i mieszkai na miejscach ich aż po dziś dzień.
Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
23 Hewejczyki także, którzy mieszkali w Aserym aż do Gazy, Kaftorytowie, którzy wyszli z Kaftor, wytracili je, i mieszkali na miejscu ich.)
Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
24 Wstawszy tedy idźcie, a przeprawcie się przez potok Arnon; oto, Ja dawam w ręce twoje Sehona, króla Hesebon Amorejczyka, i ziemię jego, pocznijże ją posiadać, a podnieś przeciwko niemu wojnę.
“Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
25 Dzisiaj pocznę puszczać strach i bojaźń twoję na ludzie, którzy są pod wszystkiem niebem, że gdy usłyszą wieść o tobie, drżeć i lękać się będą przed tobą.
Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
26 Tedym posłał posły z puszczy Kademot do Sehona, króla Hesebońskiego, z poselstwem spokojnem, mówiąc:
Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
27 Niech przejdę przez ziemię twoję; drogą pospolitą pójdę; nie uchylę się ani na prawo ani na lewo.
“Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
28 Żywności za pieniądze sprzedasz mi, abym jadł; wody także za pieniądze dasz mi, abym pił: tylko przejdę nogami memi;
Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
29 Jako mi uczynili synowie Ezawowi, którzy mieszkają w Seir, i Moabczycy, którzy mieszkają w Ar, ażbyśmy się przeprawili za Jordan, do ziemi, którą Pan, Bóg nasz, dawa nam.
gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
30 Ale nie chciał Sehon, król Heseboński, pozwolić nam przejścia przez ziemię swoję: bo był zatwardził Pan, Bóg twój, ducha jego, i stwierdził serce jego, aby go podał w ręce twoje, jako to dziś widzisz.
Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
31 Tedy rzekł Pan do mnie: Otom ci już począł podawać w moc Sehona, i ziemię jego: pocznijże ją posiadać, abyś odziedziczył ziemię jego.
Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
32 Ruszył się tedy Sehon przeciwko nam, sam i wszystek lud jego, chcąc z nami zwieść bitwę w Jaza;
Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
33 Ale go nam podał Pan, Bóg nasz, w moc, i poraziliśmy go, i syny jego i wszystek lud jego.
Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
34 I wzięliśmy wszystkie miasta jego na on czas, i wniwecześmy obrócili wszystkie miasta, mężczyzny i niewiasty, i dzieci, nie zostawiwszy z nich nikogo.
Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
35 Tylkośmy bydło pobrali sobie, i korzyści z miast, którycheśmy dobyli.
Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
36 Od Aroer, które leży nad brzegiem potoku Arnon, i od miasta, które jest w dolinie aż do Galaad, nie było miasta, które by się nam nie podało; wszystkie podał nam Pan, Bóg nasz.
Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
37 Tylkoś do ziemi synów Ammonowych nie dochodził ani do żadnego miejsca przyległego potokowi Jabok, ani do miast na górach, ani do żadnych miejsc, których zakazał Pan, Bóg nasz.
Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.

< Powtórzonego 2 >