< Powtórzonego 18 >

1 Nie będą mieli kapłani Lewitowie, i wszystko pokolenie Lewi, działu, ani dziedzictwa z innym Izraelem: ogniste ofiary Pańskie i dziedzictwo jego jeść będą.
Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, àní gbogbo ẹ̀yà Lefi, wọn kì yóò ní ìpín tàbí ogún láàrín Israẹli, wọn yóò máa jẹ nínú ọrẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa, nítorí òun ni ogún un tiwọn.
2 A dziedzictwa nie będą mieli między bracią swoją; Pan jest dziedzictwem ich, jako im powiedział.
Wọn kì yóò ní ìní láàrín àwọn arákùnrin wọn; Olúwa ni yóò jẹ́ ìní i tiwọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
3 A toć będzie prawo należące kapłanom od ludu, od ofiarujących ofiarę, bądź wołu, bądź owcę; tedy oddadzą kapłanowi łopatkę, i czeluści i kałdun.
Gbogbo èyí ni yóò jẹ́ ìpín àwọn àlùfáà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó fi akọ màlúù tàbí àgùntàn rú ẹbọ; wọn yóò fi èjìká àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ méjèèjì àti gbogbo inú fún àlùfáà.
4 Pierwociny zboża twego, wina twego, i oliwy twojej, także pierwociny wełny z owiec twoich oddasz mu.
Àkọ́so irúgbìn ọkà rẹ, ti wáìnì àti ti òróró rẹ, àti àkọ́rẹ́ irun àgùntàn rẹ ni ìwọ yóò fi fún wọn.
5 Albowiem obrał go Pan, Bóg twój, ze wszystkich pokoleń twoich, aby stał ku usłudze w imieniu Pańskiem, on i synowie jego, po wszystkie dni.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n àti àwọn ọmọ wọn láti inú gbogbo ẹ̀yà láti dúró àti láti ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa títí láé.
6 A gdyby przyszedł Lewita z któregokolwiek miasta twego, z całego Izraela, gdzie przemieszkiwa, a przyszedłby z całej chęci duszy swej na miejsce, które sobie obrał Pan:
Tí ọmọ Lefi kan bá sì wá láti ibikíbi nínú àwọn ìlú u yín ní Israẹli, níbi tí ó ń gbé ṣe àtìpó, tí ó sì wá gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
7 Tedy służyć będzie w imieniu Pana, Boga swego, jako wszyscy bracia jego Lewitowie, którzy tam stoją przed oblicznością Pańską.
Nígbà náà ni ó lè máa ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi arákùnrin rẹ̀ ti ń dúró ṣe iṣẹ́ ìsìn níwájú Olúwa níbẹ̀.
8 Część równą z drugimi jeść będą, oprócz tego, co im należało z dóbr ojców ich.
Wọn yóò ní ìpín kan láti jẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti gba owó nípa títa ogún baba rẹ̀.
9 Gdy tedy wnijdziesz do ziemi, którą dawa Pan, Bóg twój, tobie, nie ucz się czynić według obrzydliwości tych narodów.
Nígbà tí o bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ, ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ láti tẹ̀lé àwọn ọ̀nà ìríra àwọn orílẹ̀-èdè náà tí ó wà níbẹ̀.
10 Niech się między wami nie znajduje, któryby przewodził syna swego, albo córkę swoję przez ogień; także wieszczek, guślarz, i wróżek, i czarownik.
Má ṣe jẹ́ kí a rí ẹnikẹ́ni láàrín yín tí ó fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin la iná já (fi ọmọ rẹ rú ẹbọ) kí ẹnikẹ́ni má ṣe lọ fọ àfọ̀ṣẹ, tàbí ṣẹ́ oṣó, tàbí túmọ̀ àwọn àmì nǹkan tí ń bọ̀, tàbí àjẹ́,
11 I czarnoksiężnik, i ten, który ma sprawę z duchy złymi, i praktykarz, i wywiadujący się czego od umarłych.
tàbí afògèdè, tàbí jẹ́ a bá iwin gbìmọ̀ tàbí oṣó tàbí abókùúsọ̀rọ̀.
12 Albowiem jest obrzydliwością Panu każdy, któryby to czynił; bo dla tych obrzydliwości Pan, Bóg twój, wyrzuca te narody przed tobą.
Ẹnikẹ́ni tó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìríra sí Olúwa, àti nítorí àwọn ìwà ìríra wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde kúrò níwájú rẹ.
13 Doskonałym będziesz przed Panem, Bogiem twoim.
O ní láti jẹ́ aláìlẹ́gàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
14 Albowiem narodowie ci, które ty opanujesz, wieszczków i guślarzy słuchają; ale tobie nie dopuszcza tego Pan, Bóg twój.
Àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ yóò gba ilẹ̀ tí wọ́n ń gbé, wọ́n fetí sí tí àwọn tí ó ń ṣe oṣó tàbí ṣe àfọ̀ṣẹ. Ṣùgbọ́n, ní ti ìwọ, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò fi ààyè gbà ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
15 Proroka z pośrodku ciebie, z braci twej, jakom ja jest, wzbudzi tobie Pan, Bóg twój; onego słuchać będziecie;
Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé wòlíì kan dìde gẹ́gẹ́ bí èmi láàrín àwọn arákùnrin rẹ. Tìrẹ ni kí o gbọ́.
16 Według tego wszystkiego, jakoś żądał od Pana, Boga twego, na górze Horeb, w dzień zgromadzenia, mówiąc: Niech więcej nie słucham głosu Pana, Boga mego, i na ogień ten wielki niech nie patrzę więcej, bym nie umarł.
Nítorí èyí ni ohun tí ìwọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Horebu ní ọjọ́ àjọ, nígbà tí ìwọ wí pé, “Kí àwa má ṣe gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run wa tàbí rí iná ńlá yìí mọ́. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ àwa yóò kú.”
17 Przetoż rzekł Pan do mnie: Dobrze mówili, co mówili.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ohun tí wọ́n sọ dára.
18 Proroka im wzbudzę z pośrodku braci ich, jakoś ty jest, i włożę słowa moje w usta jego, i opowiadać im będzie wszystko, cokolwiek mu rozkażę.
Èmi yóò gbé wòlíì kan dìde fún wọn láàrín àwọn arákùnrin wọn bí ìwọ, Èmi yóò fi ọ̀rọ̀ mi sí i ní ẹnu, yóò sì sọ fún wọn gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un.
19 I stanie się, że ktobykolwiek nie był posłuszny słowom moim, które on mówić będzie w imię moje, Ja tego szukać będę na nim.
Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi tí wòlíì náà yóò sọ ní orúkọ mi, èmi fúnra à mi yóò sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
20 Wszakże prorok, któryby sobie hardzie począł, mówiąc słowo w imieniu mojem, któregom mu mówić nie rozkazał i któryby mówił w imię bogów obcych, niech umrze prorok takowy.
Ṣùgbọ́n bí wòlíì kan bá kùgbù sọ ọ̀rọ̀ kan tí èmi kò paláṣẹ fún un láti sọ ní orúkọ mi tàbí wòlíì tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ ọlọ́run mìíràn, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ ní láti kú.”
21 A jeźlibyś rzekł w sercu swem: Jakoż rozeznamy to słowo, którego nie mówił Pan?
Ṣùgbọ́n ìwọ lè wí ní ọkàn rẹ pé, “Báwo ni àwa yóò ṣe mọ ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ?”
22 Jeźliby co mówił on prorok w imię Pańskie, a nie stałoby się to, ani wypełniło, onoć to jest słowo, którego nie mówił Pan; z hardości to mówił prorok on, nie bójże się go.
Nígbà tí ohun tí wòlíì bá sọ ní orúkọ Olúwa kò bá wá sí ìmúṣẹ tàbí jẹ́ òtítọ́, ìyẹn ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ tí sọ láìwádìí. Kí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.

< Powtórzonego 18 >