< Powtórzonego 15 >

1 Na początku każdego siódmego roku czynić będziesz odpuszczenie.
Ní òpin ọdún méje méje, ẹ̀yin gbọdọ̀ máa yọ̀ǹda àwọn gbèsè.
2 A toć jest sposób odpuszczania, żeby odpuścił każdy, który pożyczył z ręki swej, to, czego pożyczył bliźniemu swemu; nie będzie wyciągał długu od bliźniego swego, i od brata swego, ponieważ obwołane jest odpuszczenie Pańskie.
Báyìí ni kí ẹ máa ṣe é. Gbogbo ẹni tí wọ́n jẹ ní gbèsè gbọdọ̀ fojú fo gbèsè tí ó ti yá ará Israẹli ènìyàn rẹ̀. Kò gbọdọ̀ béèrè ohun náà, lọ́dọ̀ ará Israẹli ènìyàn rẹ̀ tàbí lọ́dọ̀ arákùnrin rẹ̀: nítorí pé a ti kéde àkókò Olúwa láti fojú fo gbèsè.
3 Od obcego wyciągać dług możesz: ale cobyś miał u brata twego, odpuści mu ręka twoja:
Ẹ lè béèrè ìsanpadà lọ́dọ̀ àjèjì. Ṣùgbọ́n ẹ fa igi lé gbèsè yówù kó jẹ́ tí arákùnrin yín jẹ yín.
4 Dla tego, żeby się nie stał między wami kto przez cię ubogim, ponieważ hojnie błogosławić tobie będzie Pan w ziemi, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie w dziedzictwo, abyś ją posiadł.
Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò tọ́ sí nínú yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín lọ́pọ̀lọ́pọ̀ nínú ilẹ̀ náà tí ó ń mú un yín lọ láti gbà bí ìní yín.
5 Tylko żebyś słuchając posłuszny był głosowi Pana, Boga twego, abyś strzegł, i czynił każde przykazanie to, które ja przykazuję tobie dzisiaj,
Kìkì bí ẹ bá gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín tí ẹ sì kíyèsára láti máa rìn nínú gbogbo àṣẹ wọ̀nyí, tí èmi ń pa fún un yín lónìí.
6 Albowiem Pan, Bóg twój, błogosławić cię będzie, jakoć obiecał; i będziesz pożyczał wielu narodom, a sam u nikogo nie będziesz pożyczał; i będziesz panował nad wielą narodów, a one nad tobą panować nie będą.
Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín bí ó ti ṣèlérí, ẹ̀yin yóò sì máa yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ẹ kì yóò sì tọrọ. Ẹ ó ṣàkóso ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò sí orílẹ̀-èdè tí yóò lè jẹ ọba lé e yín lórí.
7 Gdyby był u ciebie ubogi ktokolwiek z braci twojej w któremkolwiek mieście twojem, w ziemi twojej, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie, nie zatwardzaj serca swego, ani zawieraj ręki twej przed bratem twoim ubogim;
Bí tálákà kan bá wà láàrín àwọn arákùnrin yín ní èyíkéyìí àwọn ìlú, ilẹ̀ náà tí Olúwa yín yóò fún un yín. Ẹ má ṣe ṣe àìláàánú, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe háwọ́ sí arákùnrin yín tí ó jẹ́ tálákà.
8 Ale szczodrze otworzysz mu rękę twoję, i ochotnie pożyczysz mu, ile będzie potrzebował i czego by mu niedostawało.
Ṣùgbọ́n ẹ lawọ́ kí ẹ sì fi tọkàntọkàn yá wọn ní ohun tí wọ́n nílò.
9 Strzeż się, aby nie była jaka niepobożność w sercu twojem, żebyś miał rzec: Nadchodzi rok on siódmy, rok odpuszczenia, i surowo byś się stawił bratu twemu ubogiemu, tak, żebyś mu nie użyczył, a on by wołał przeciwko tobie do Pana, i miałbyś grzech;
Ẹ ṣọ́ra kí èrò búburú kan má ṣe sí nínú àyà rẹ wí pé, “Ọdún keje tí í ṣe ọdún ìyọ̀ǹda gbèsè ti súnmọ́,” nípa bẹ́ẹ̀, ojú rẹ a sì burú sí arákùnrin rẹ tálákà, tí ìwọ kò sì fun ní nǹkan, o kò sì fun ní nǹkan kan. Òun a si kígbe pe Olúwa nítorí rẹ, a si di ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ.
10 Ale ochotnie dawać mu będziesz, i nie będzie niechętne serce twoje, gdy mu dawać będziesz, albowiem dla tegoć pobłogosławi Pan, Bóg twój, we wszystkich sprawach twoich, i do czegokolwiek ściągniesz rękę twoję.
Fún un tọkàntọkàn, láìsí ìkùnsínú, nítorí èyí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún fún ọ nínú iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, àti gbogbo ìdáwọ́lé rẹ.
11 Boć się nie przebierze ubogich w ziemi waszej; dla tegoć rozkazuję, mówiąc: abyś szczodrze otwierał rękę twą bratu twemu, i nędznemu twemu, i ubogiemu twemu w ziemi twojej.
A kò lè fẹ́ tálákà kù ní ilẹ̀ náà ní ìgbà gbogbo, mo pàṣẹ fún un yín láti lawọ́ sí àwọn arákùnrin yín, sí àwọn tálákà àti sí àwọn aláìní, ní ilẹ̀ ẹ yín.
12 Jeźliby się zaprzedał tobie brat twój, Żydowin albo Żydówka, a służyłciby przez sześć lat, tedy siódmego roku wypuścisz go wolno od siebie;
Bí Heberu ara yín kan, yálà ọkùnrin tàbí obìnrin bá ta ara rẹ̀ fún ọ, tí ó sì sìn ọ́ fún ọdún mẹ́fà. Ní ọdún keje, jẹ́ kí ó di òmìnira.
13 A gdy go wolno puścisz od siebie, nie puścisz go próżnego.
Nígbà tí ó bá dá a sílẹ̀ má ṣe jẹ́ kí ó lọ lọ́wọ́ òfo.
14 Szczodrze go udarujesz z bydła twego, i z gumna twego, i z prasy twojej; z tego, w czem ci pobłogosławił Pan, Bóg twój, dasz mu.
Fi tọkàntọkàn fún un láti inú agbo ewúrẹ́ rẹ, ilẹ̀ ìpakà rẹ, àti ibi ìfúntí rẹ. Fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti bùkún fún ọ tó.
15 I wspomnisz sobie, żeś był niewolnikiem w ziemi Egipskiej, skąd cię wykupił Pan, Bóg twój; dla tego ja to dziś tobie przykazuję.
Ẹ rántí pé ẹ ti fi ìgbà kan jẹ́ ẹrú ní Ejibiti, Olúwa Ọlọ́run yín sì rà yín padà, ìdí nìyí tí mo fi pa àṣẹ yìí fún un yín lónìí.
16 Jeźliby też rzekł do ciebie: Nie pójdę od ciebie, przeto iż cię umiłował, i dom twój, a iż się ma dobrze u ciebie:
Ṣùgbọ́n bí ìránṣẹ́ rẹ bá sọ fún ọ pé, “Èmi kò fẹ́ fi ọ́ sílẹ̀,” nítorí pé ó fẹ́ràn ìwọ àti ìdílé rẹ, tí ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn,
17 Tedy wziąwszy szydło, przekolesz ucho jego na drzwiach, i będzie sługą twoim na wieki; toż i służebnicy swej uczynisz.
kí ìwọ kí ó mú ìlu kan lu etí rẹ̀ mọ́ ara ìlẹ̀kùn, yóò sì di ẹrú rẹ láéláé. Bẹ́ẹ̀ náà ni kí o ṣe sí ìránṣẹ́ ẹrúbìnrin rẹ.
18 Niech to nie będzie przykro w oczach twoich, że go puścisz wolno od siebie; bo dwojaką zapłatę najemnika zasłużył u ciebie przez sześć lat; i błogosławić będzie tobie Pan, Bóg twój, we wszystkiem, co będziesz czynił.
Má ṣe kà á sí ohun ìnira láti dá ẹrú rẹ sílẹ̀, nítorí ìsìnrú rẹ̀ fún ọ, ní ọdún mẹ́fà náà tó ìlọ́po méjì iṣẹ́ alágbàṣe, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún fún ọ nínú gbogbo ìdáwọ́lé rẹ.
19 Wszystkiego pierworodztwa, które się urodzi z bydła twego, albo z trzody twojej, samce, poświęcisz Panu, Bogu twemu; nie będziesz robił pierworodnym krowy twojej, ani będziesz strzygł pierworodnych owiec twoich.
Gbogbo àkọ́bí tí o jẹ́ akọ nínú agbo màlúù rẹ ni kí o yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, àti nínú agbo ewúrẹ́ bákan náà. Ẹ má ṣe fi àkọ́bí màlúù yín ṣiṣẹ́ rárá. Má ṣe rẹ́ irun àkọ́bí àgùntàn rẹ pẹ̀lú.
20 Przed Panem, Bogiem twoim, będziesz je jadł każdego roku, na miejscu, które obierze Pan, ty i dom twój,
Ní ọdọọdún ni kí ìwọ àti ìdílé rẹ máa jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbi tí Òun yóò yàn.
21 A jeźliby na niem była wada, żeby chrome, albo ślepe, albo z jakąkolwiek wadą złą było, nie będziesz go ofiarował Panu, Bogu twemu.
Bí ẹran ọ̀sìn kan bá ní àbùkù: bóyá ó yarọ, tàbí fọ́jú, tàbí tí ó ní èyíkéyìí àbùkù tó burú. Ẹ kò gbọdọ̀ fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín.
22 W bramach twych jeść je będziesz, nieczysty i czysty zarówno, jako sarnę i jako jelenia;
Ẹ jẹ ẹ́ ní ìlú u yín. Àti ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́ bí ìgbà tí a ń jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín.
23 Tylko krwi jego nie będziesz jadł; na ziemię wylejesz ją, jako wodę.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á síta bí omi.

< Powtórzonego 15 >