< Powtórzonego 13 >

1 Gdyby powstał między wami prorok, albo sny miewający, i ukazałciby znak, albo cud;
Bí wòlíì tàbí alásọtẹ́lẹ̀ nípa àlá lílá bá farahàn láàrín yín, tí ó sì ń kéde iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu,
2 I stałby się on znak albo cud, o którym ci powiedział, a rzekłby: Pójdźmy za bogami obcymi, których ty nie znasz, a służmy im:
bí iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ bá ṣẹ tí òun sì wí pé, “ẹ wá ẹ jẹ́ kí a tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀ rí) “kí ẹ sì jẹ́ kí a máa sìn wọ́n,”
3 Nie usłuchasz słów proroka tego, ani tego, co sny miewa, gdyż was doświadcza Pan, Bóg wasz, aby wiedział, jeśli wy miłujecie Pana, Boga waszego, ze wszystkiego serca waszego, i ze wszystkiej duszy waszej.
ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wòlíì tàbí àlá náà, Olúwa Ọlọ́run yín ń dán an yín wò ni, láti mọ̀ bóyá ẹ fẹ́ràn rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn an yín.
4 Pana, Boga waszego, naśladujcie, i onego się bójcie, a przykazań jego strzegąc, i głosu jego słuchając, służcie mu, i przy nim trwajcie.
Olúwa Ọlọ́run yín ni kí ẹ tẹ̀lé, Òun ni kí ẹ bu ọlá fún, ẹ pa òfin rẹ̀ mọ́ kí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, ẹ sìn ín, kí ẹ sì dìímú ṣinṣin.
5 Ale prorok on, albo miewający sny, zabity będzie; bo to mówił, czem by was odwiódł od Pana Boga waszego, (który was wywiódł z ziemi Egipskiej, i odkupił cię z domu niewoli), aby cię zraził z drogi, którą przykazał tobie Pan, Bóg twój, żebyś nią chodził; a tak wykorzenisz to złe z pośrodku siebie
Wòlíì náà tàbí alálàá náà ni kí ẹ pa, nítorí pé wàásù ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú yín jáde láti Ejibiti wá, tí ó sì rà yín padà lóko ẹrú. Ó ti gbìyànjú láti fà yín kúrò lójú ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín láti máa rìn. Ẹ gbọdọ̀ yọ ibi náà kúrò láàrín yín.
6 Jeźliby cię też zwodził brat twój, syn matki twojej albo syn twój, albo córka twoja, albo żona łona twego, albo przyjaciel twój, który być był miły, jako dusza twoja, potajemnie mówiąc: Pójdźmy, a służmy bogom obcym, którycheś nie znał ty, ani ojcowie twoi;
Bí arákùnrin tìrẹ gan an ọmọ ìyá rẹ tàbí ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí obìnrin, aya tí o fẹ́ràn jù, tàbí ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ bá tàn ọ́ jẹ níkọ̀kọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn” (ọlọ́run tí ìwọ tàbí baba rẹ kò mọ̀,
7 Z bogów tych narodów, które około was są, którzy blisko są ciebie, albo daleko od ciebie, od końca ziemi, i aż do końca ziemi:
ọlọ́run àwọn tí ó wà láyìíká yín, yálà wọ́n jìnnà tàbí wọ́n wà nítòsí, láti òpin ilẹ̀ kan dé òmíràn),
8 Nie pozwolisz mu, ani go usłuchasz, ani mu folgować będzie oko twoje, ani się zmiłujesz nad nim, ani go utaisz;
má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.
9 Ale koniecznie zabijesz go; ręka twoja najpierwsza nad nim będzie, na zabicie jego, a ręka wszystkiego ludu potem.
Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.
10 I ukamionujesz go aż na śmierć, ponieważ chciał cię odwieść od Pana, Boga twego, który cię wywiódł z ziemi Egipskiej, z domu niewoli;
Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.
11 Aby wszystek Izrael usłyszawszy, bał się, a nie czynił więcej nic podobnego rzeczy tej bardzo złej między wami.
Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.
12 A jeźlibyś usłyszał, żeby w któremkolwiek mieście twojem, które Pan Bóg twój, dawa tobie ku mieszkaniu, ktokolwiek rzekł:
Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,
13 Wyszli niektórzy ludzie przewrotni z pośrodku ciebie, a podwiedli obywatele miasta swego mówiąc: Pójdźmy, a służmy bogom obcym, których nie znacie:
pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)
14 Tedy będziesz szukał i dochodził, a pilnie się wywiadował; a jeźli to prawda, a rzecz pewna, że się stała obrzydliwość taka między wami.
Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.
15 Koniecznie wytracisz obywatele miasta onego ostrzem miecza, zgładzisz je, i wszystko co w niem, i bydło jego pobijesz ostrzem miecza.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.
16 A wszystkie łupy jego zbierzesz w pośród ulicy jego, i spalisz ogniem jego miasto i z onym wszystkim łupem do szczętu Panu, Bogu twemu; i będzie mogiłą wieczną, a nie będzie budowane więcej.
Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.
17 I nie zostanie w rękach twoich nic z onych rzeczy przeklętych, aby się odwrócił Pan od gniewu popędliwości swojej, a uczynił z tobą miłosierdzie, i zmiłował się nad tobą, a rozmnożył cię, jako przysiągł ojcom twoim.
A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.
18 Gdy słuchać będziesz głosu Pana, Boga twego, zachowywując wszystkie przykazania jego, które ja dziś przykazuję tobie, żebyś czynił, co prawego jest przed oczyma Pana, Boga twego.
Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.

< Powtórzonego 13 >