< Daniela 9 >

1 Roku pierwszego Daryjusza, syna Aswerusowego, z nasienia Medów, który był postanowiony królem na królestwem Chaldejskiem;
Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
2 Roku pierwszego królowania jego, ja Danijel zrozumiałem z ksiąg liczbę lat, o których było słowo Pańskie do Jeremijasza proroka, że się wypełnić miało spustoszenie Jeruzalemskie w siedmdziesięt lat.
Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
3 I obróciłem oblicze moje do Pana Boga, szukając go modlitwą i prośbami w poście i w worze i w popiele.
Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
4 Modliłem się tedy Panu Bogu memu, a wzywając rzekłem: Proszę Panie! Boże wielki i straszny, strzegący przymierza i miłosierdzia tym, którzy cię miłują, i strzegą przykazań twoich;
Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
5 Zgrzeszyliśmy i przewrotnieśmy czynili, i niezbożnieśmy się sprawowali, i sprzeciwiliśmy się, a odstąpiliśmy od przykazań twoich i od sądów twoich;
Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
6 I nie słuchaliśmy sług twoich, proroków, którzy mawiali w imieniu twojem do królów naszych, do książąt naszych, i do ojców naszych, i do wszystkiego ludu ziemi.
Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
7 Tobie, Panie! sprawiedliwość, a nam zawstydzenie twarzy należy, jako się to dzieje dnia tego mężom Judzkim i obywatelom Jeruzalemskim i wszystkiemu Izraelowi, bliskim i dalekim we wszystkich ziemiach, do którycheś ich wygnał dla przestępstwa ich, którem wystąpili przeciwko tobie.
“Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
8 Panie! namci należy zawstydzenie twarzy, królom naszym, książętom naszym i ojcom naszym, bośmy zgrzeszyli przeciwko tobie:
Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
9 Ale Panu, Bogu naszemu, miłosierdzie i litość; ponieważeśmy mu odporni byli,
Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
10 A nie byliśmy posłuszni głosowi Pana, Boga naszego, żebyśmy chodzili w ustawach jego, które on dał przed oblicze nasze przez proroków, sług swoich;
àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
11 Owszem, wszyscy Izraelczycy przestąpili zakon twój i odchylili się, żeby nie słuchali głosu twego: przetoż się wylało na nas to złorzeczeństwo i przeklęstwo, które jest napisane w zakonie Mojżesza, sługi Bożego; bośmy zgrzeszyli przeciwko niemu.
Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
12 Skąd spełnił słowa swoje, które mówił przeciwko nam, i przeciwko sędziom naszym, którzy nas sądzili, a przywiódł na nas to wielkie złe, które się nie stało pod wszystkiem niebem, jakie się stało w Jeruzalemie.
Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
13 Tak jako napisano w zakonie Mojżeszowym, wszystko to złe przyszło na nas; a wżdyśmy nie prosili oblicza Pana, Boga naszego, abyśmy się odwrócili od nieprawości naszych, a mieli wzgląd na prawdę jego.
Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
14 Przetoż nie omieszkał Pan z tem złem, ale je przywiódł na nas; bo sprawiedliwy jest Pan, Bóg nasz, we wszystkich sprawach swoich, które czyni, któregośmy głosu nie słuchali.
Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
15 Wszakże teraz, o Panie, Boże nasz! któryś wywiódł lud swój z ziemi Egipskiej ręką możną, i uczyniłeś sobie imię. jako się to dziś pokazuje, zgrzeszyliśmy, niepobożnieśmy czynili.
“Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
16 O Panie! według wszystkich sprawiedliwości twoich niech się proszę odwróci popędliwość twoja i gniew twój od miasta twego Jeruzalemu, góry świętobliwości twojej: bo dla grzechów naszych i dla nieprawości ojców naszych Jeruzalem i lud twój nosi po hańbienie u wszystkich, którzy są około nas.
Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
17 Teraz tedy wysłuchaj, o Boże nasz! modlitwę sługi twego i prośby jego, a oświeć oblicze twoje nad spustoszoną świątnicą twoją, dla Pana.
“Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
18 Nakłoń, Boże mój! ucha twego a usłysz; otwórz oczy twoje a obacz spustoszenia nasze i miasto, które jest nazwane od imienia twego; bo my przekładamy modlitwy nasze przed obliczem twojem, nie dla jakiej naszej sprawiedliwości, ale dla obfitego miłosierdzia twego.
Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
19 O Panie! wysłuchaj, Panie! odpuść, Panie! obacz a uczyń; nie odwłaczaj sam dla siebie, Boże mój! bo od imienia twego nazwane jest to miasto i lud twój.
Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
20 A gdym ja jeszcze mówił, i modliłem się, i wyznawałem grzech mój i grzech ludu mego Izraelskiego, i przekładałem modlitwę moję przed twarzą Pana, Boga mego, za górę świętobliwości Boga mego;
Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
21 Prawie gdym ja jeszcze mówił i modliłem się, oto mąż on Gabryjel, któregom widział w widzeniu na początku, prędko lecąc dotknął się mnie czasu ofiary wieczornej,
Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
22 A usługując mi do zrozumienia mówił ze mną i rzekł: Danijelu! terazem wyszedł, abym cię nauczył wyrozumienia tajemnicy.
Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
23 Na początku modlitw twoich wyszło słowo, a jam przyszedł, abym ci je oznajmił, boś ty wielce przyjemny; a tak miej wzgląd na to słowo, a zrozumiej to widzenie.
Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
24 Siedmdziesiąt tego dni zamierzono ludowi twemu i miastu twemu świętemu na zniesienie przestępstwa, i na zagładzenie grzechów i na oczyszczenie nieprawości, i na przywiedzienie sprawiedliwości wiecznej, i na zapieczętowanie widzenia i proroctwa, a na pomazanie Świętego świętych.
“Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
25 Przetoż wiedz a zrozumiej, że od wyjścia słowa o przywróceniu i zbudowaniu Jeruzalemu aż do Mesyjasza wodza będzie tygodni siedm, potem tygodni sześćdziesiąt i dwa, gdy znowu zbudowana będzie ulica i przekopanie, a te czasy będą bardzo trudne.
“Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
26 A po onych sześćdzesięciu i dwóch tygodniach zabity będzie Mesyjasz, wszakże mu to nic nie zaszkodzi; owszem, to miasto i tę świątnicę skazi lud wodza przyszłego, tak, że koniec jego będzie z powodzią, i aż do skończenia wojny będzie ustawiczne pustoszenie.
Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
27 Wszakże zmocni przymierze wielom ich w tygodniu ostatnim; a w połowie onego tygodnia uczyni koniec ofierze palonej i ofierze śniednej, a przez wojsko obrzydliwe pustoszyciel przyjdzie, i aż do skończenia naznaczonego wyleje się spustoszenie na te go, który ma być spustoszony.
Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”

< Daniela 9 >