< Amosa 8 >

1 To mi jeszcze ukazał panujący Pan, oto był kosz letniego owocu.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
2 Tedy rzekł: Cóż widzisz Amosie? I rzekłem: Kosz letniego owocu. Znowu rzekł Pan do mnie: Przyszedł koniec ludowi memu Izraelskiemu, nie będę mu już więcej przeglądał.
Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
3 Tedy się obrócą w kwilenie pieśni kościelne dnia onego, mówi panujący Pan, mnóstwa trupów na każde miejsce po cichu narzucają.
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
4 Słuchajcież tego, którzy pożeracie ubogiego, abyście wygubili chudziny z ziemi;
Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
5 I mawiacie: Kiedyż przeminie nów miesiąca, abyśmy sprzedawali zboże? i sabat, abyśmy otworzyli spichlerze? abyśmy umniejszyli miary efa, a podwyższyli wagi, a szale zdradliwie sfałszowali.
Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
6 Kupując ubogich za pieniądze, a chudzinę za parę trzewików; nadto abyśmy odmieciny zbóż sprzedawali.
kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
7 Przysiągł Pan przez zacność Jakóbową, że nie zapomnę na wieki wszystkich spraw ich.
Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
8 Izali by się i ziemia nad tem nie poruszyła, i nie płakałby każdy, kto mieszka na niej? i owszem, wzbierze wszystka jako rzeka, i porwana i zatopiona będzie jako rzeką Egipską.
“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
9 A dnia onego, mówi panujący Pan, sprawię, że słońce zajdzie o południu, i przywiodę ciemność na ziemię w dzień jasny;
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 I obrócę w płacz święta wasze, a wszystkie pieśni wasze w narzekanie, i sprawię to, że będzie na wszystkich biodrach wór, i na każdej głowie obłysienie; i będzie w tej ziemi kwilenie, jako nad jednorocznym, a ostateczne rzeczy jej jako dzień gorz kości.
Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
11 Oto dni przychodzą, mówi panujący Pan, że poślę głód na ziemię, nie głód chleba, ani pragnienie wody, ale słuchania słów Pańskich,
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Tak, że się tułać będą od morza aż do morza, i od północy aż na wschód biegać będą, szukając słowa Pańskiego, wszakże nie znajdą.
Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
13 Dnia onego pomdleją panienki piękne, nawet i młodzieńcy od onego pragnienia;
“Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Którzy przysięgają przez obrzydliwość Samaryi, i mówią: Jako żyje Bóg twój, o Dan! i jako żyje droga Beerseba; i upadną, a nie powstaną więcej.
Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”

< Amosa 8 >