< II Samuela 15 >

1 I stało się potem, że sobie nasprawiał Absalom wozów, i koni, i pięćdziesiąt mężów, którzy chodzili przed nim.
Lẹ́yìn èyí náà, Absalomu sì pèsè kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin fún ara rẹ̀, àti àádọ́ta ọmọkùnrin tí yóò máa sáré níwájú rẹ̀.
2 I wstawając rano Absalom stawał podle drogi u bramy, a każdego męża, mającego sprawę a idącego do króla na sąd, przyzywał Absalom do siebie, i mówił: Z któregożeś ty miasta? A gdy mu odpowiedział: Z jednego pokolenia Izraelskiego jest sługa twój.
Absalomu sì dìde ní kùtùkùtù, ó sì dúró ní apá kan ọ̀nà ẹnu ibodè. Bí ẹnìkan bá ní ẹjọ́ tí ó ń fẹ́ mú tọ ọba wá fún ìdájọ́, a sì pè é sọ́dọ̀ rẹ̀, a sì bi í pé, “Ará ìlú wo ni ìwọ?” Òun a sì dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti inú ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli wá.”
3 Mówił mu Absalom: Oto, sprawa twoja dobra jest, i sprawiedliwa; ale niemasz, ktoby cię wysłuchał u króla.
Absalomu yóò sì wí fún un pé, “Wò ó, ọ̀ràn rẹ ṣá dára, ó sì tọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ọba fi àṣẹ fún láti gbọ́ ọ̀ràn rẹ.”
4 Nadto mówił Absalom: O ktoby mię postanowił sędzią w tej ziemi! aby do mnie chodził każdy, któryby miał sprawę u sądu, dopomógłbym mu do sprawiedliwości.
Absalomu a sì wí pé, “À bá jẹ́ fi mi ṣe onídàájọ́ ní ilẹ̀ yìí! Kí olúkúlùkù ẹni tí ó ní ẹjọ́ tàbí ọ̀ràn kan bá à lè máa tọ̀ mí wá, èmi ìbá sì ṣe ìdájọ́ òtítọ́ fún un.”
5 A gdy kto przystąpił, i ukłonił mu się, ściągnął rękę swą, a ująwszy go, całował go.
Bẹ́ẹ̀ ni bí ẹnìkan bá sì súnmọ́ láti tẹríba fún un, òun a sì nawọ́ rẹ̀, a sì dìímú, a sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
6 A toć czynił Absalom wszystkiemu Izraelowi, który przychodził na sądy do króla, i ukradał Absalom serca mężów Izraelskich.
Irú ìwà báyìí ni Absalomu a máa hù sí gbogbo Israẹli tí ó tọ́ ọba wá nítorí ìdájọ́, Absalomu sì fi fa ọkàn àwọn ènìyàn Israẹli sọ́dọ̀ rẹ̀.
7 I stało się po czterdziestu latach, że rzekł Absalom do króla: Niech idę proszę, a oddam ślub mój w Hebronie, którym poślubił Panu.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ogójì ọdún, Absalomu sì wí fún ọba pé, “Èmi bẹ́ ọ́, jẹ́ kí èmi ó lọ, kí èmi sì san ìlérí mi tí èmi ti ṣe fún Olúwa, ní Hebroni.
8 Albowiem ślub poślubił sługa twój, kiedym mieszkał w Giessur Syryjskim, mówiąc: Jeźliże mię zasię kiedy przywróci Pan do Jeruzalemu, tedy służyć będę Panu.
Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ kan nígbà tí èmi ń bẹ ní Geṣuri ní Siria pé, ‘Bí Olúwa bá mú mi padà wá sí Jerusalẹmu, nítòótọ́, èmi ó sì sin Olúwa.’”
9 I rzekł mu król: Idź w pokoju. A on wstawszy poszedł do Hebronu.
Ọba sì wí fún un pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Ó sì dìde, ó sì lọ sí Hebroni.
10 Tedy rozesłał Absalom szpiegi między wszystkie pokolenia Izraelskie, aby rzekli: Skoro usłszycie głos trąby, mówcież: Króluje Absalom w Hebronie.
Ṣùgbọ́n Absalomu rán àmì sáàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá gbọ́ ìró ìpè, kí ẹ̀yin sì wí pé, ‘Absalomu jẹ ọba ní Hebroni.’”
11 A z Absalomem poszło było dwieście mężów z Jeruzalemu zaproszonych, którzy szli w prostości swojej, niewiedząc o niczem.
Igba ọkùnrin sì bá Absalomu ti Jerusalẹmu jáde, nínú àwọn tí a ti pè; wọ́n sì lọ nínú àìmọ̀kan wọn, wọn kò sì mọ nǹkan kan.
12 Posłał też Absalom po Achitofela Giloniczyka, radcę Dawidowego, aby przyszedł z miasta swego Gilo, gdy miał sprawować ofiary. I stało się sprzysiężenie wielkie, a lud się schodził, i przybywało go Absalomowi.
Absalomu sì ránṣẹ́ pe Ahitofeli ará Giloni, ìgbìmọ̀ Dafidi, láti ìlú rẹ̀ wá, àní láti Giloni, nígbà tí ó ń rú ẹbọ. Ìdìmọ̀lù náà sì le; àwọn ènìyàn sì ń pọ̀ sọ́dọ̀ Absalomu.
13 Potem przyszedł poseł do Dawida, mówiąc: Obróciło się serce mężów Izraelskich za Absalomem.
Ẹnìkan sì wá rò fún Dafidi pé, “Ọkàn àwọn ọkùnrin Israẹli ṣí sí Absalomu.”
14 Tedy rzekł Dawid do wszystkich sług swoich, którzy z nim byli w Jeruzalemie: Wstańcie, a uciekajmy; inaczej nieuszlibyśmy przed twarzą Absalomową. Spieszcież się, azaż ujdziem, by się snać nie pospieszył, a nie zajechał nas, i nie obalił na nas z łego, i nie wysiekł miasta ostrzem miecza.
Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wá lọ́dọ̀ rẹ̀ ni Jerusalẹmu pé, “Ẹ dìde! Ẹ jẹ́ kí a sálọ, nítorí pé kò sí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ Absalomu; ẹ yára, kí a lọ kúrò, kí òun má bá à yára lé wa bá, kí ó má sì mú ibi bá wa, kí ó má sì fi ojú idà pa ìlú run.”
15 I rzekli słudzy królewscy do króla: Wszystko, cokolwiek sobie upodoba król, pan nasz, oto słudzy twoi.
Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa wa ọba ń fẹ́, wò ó, àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ ti murá.”
16 A tak wyszedł król, i wszystek dom jego pieszo; tylko zostawił król dziesięć niewiast założnic, aby strzegły domu.
Ọba sì jáde, gbogbo ilé rẹ̀ sì tẹ̀lé e. Ọba sì fì mẹ́wàá nínú àwọn obìnrin rẹ̀ sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé.
17 A gdy wyszedł król i wszystek lud pieszo, stanęli na jednem miejscu z daleka.
Ọba sì jáde, gbogbo ènìyàn sì tẹ̀lé e, wọ́n sì dúró ní ibìkan tí ó jìnnà.
18 Wszyscy też słudzy jego szli przy nim, i wszyscy Cheretczycy, i wszyscy Feletczycy, i wszyscy Gietejczycy, sześć set mężów, którzy byli przyszli pieszo z Giet, szli przed twarzą królewską.
Gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì kọjá sí iwájú rẹ̀, àti gbogbo àwọn Kereti, àti gbogbo àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ará Gitti, ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Gati wá, sì kọjá níwájú ọba.
19 Tedy rzekł król do Itaja Gietejczyka: Czemuż i ty z nami idziesz? Wróć się, a zostań przy królu; boś ty cudzoziemiec, a nie długo wrócisz się do miejsca twego.
Ọba sì wí fún Ittai ará Gitti pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá wa lọ pẹ̀lú, padà, kí o sì ba ọba jókòó; nítorí pé àlejò ni ìwọ, ìwọ sì ti fi ìlú rẹ sílẹ̀.
20 Niedawnoś przyszedł, a dziśbym cię ruszyć miał, abyś z nami szedł? Gdyż ja idę, sam nie wiem dokąd; wróćże się, a odprowadź bracią swoję: niech będzie z tobą miłosierdzie i prawda.
Lánàá yìí ni ìwọ dé, èmi ó ha sì mú kí ìwọ máa bá wá lọ káàkiri lónìí bí? Èmi ń lọ sí ibikíbi tí mo bá rí: padà, kí o sì mú àwọn arákùnrin rẹ padà, kí àánú àti òtítọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
21 Ale odpowiedział Itaj królowi, mówiąc: Jako żywy Pan, jako żywy też król pan mój, że na któremkolwiek miejscu będzie król, pan mój, choć w śmierci, choć w żywocie, tam też bądzie sługa twój.
Ittai sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ láààyè, àti bí olúwa mi ọba ti ń bẹ láààyè, nítòótọ́ níbikíbi tí olúwa mi ọba bá gbé wà, ìbá à ṣe nínú ikú, tàbí nínú ìyè, níbẹ̀ pẹ̀lú ni ìránṣẹ́ rẹ yóò gbé wà.”
22 I rzekł Dawid do Itaja: Pójdźże, a przejdź. I przeszedł Itaj Gietejczyk, i wszyscy mężowie jego, i wszystkie dziatki, które były z nim.
Dafidi sì wí fún Ittai pé, “Lọ kí o sì rékọjá!” Ittai ará Gitti náà sì rékọjá, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
23 Tedy wszystka ziemia płakała głosem wielkim, i wszystek lud, który przechodził. A tak król przeszedł przez potok Cedron, a wszystek lud przeszedł przeciw drodze ku puszczy.
Gbogbo ìlú náà sì fi ohùn rara sọkún, gbogbo ènìyàn sì rékọjá; ọba sì rékọjá àfonífojì Kidironi, gbogbo àwọn ènìyàn náà sì rékọjá, sí ìhà ọ̀nà ijù.
24 A oto i Sadok i wszyscy Lewitowie byli z nim, niosąc skrzynię przymierza Bożego, i postawili skrzynię Bożą; szedł też Abijater, aż wszystek on lud przeszedł z miasta.
Sì wò ó, Sadoku pẹ̀lú àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ń ru àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà sọ̀kalẹ̀; Abiatari sí gòkè, títí gbogbo àwọn ènìyàn sì fi dẹ́kun àti máa kọjá láti ìlú wá.
25 I rzekł król do Sadoka: Odnieś zasię skrzynię Bożą do miasta. Jeźlić znajdę łaskę w oczach Pańskich, przywróci mię zasię, a ukaże mi ją, i przbytek swój.
Ọba sì wí fún Sadoku pé, “Sì tún gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà padà sí ìlú, bí èmi bá rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa, yóò sì tún mú mi padà wá, yóò sì fi àpótí ẹ̀rí náà hàn mí àti ibùgbé rẹ̀.
26 Ale jeźliby tak rzekł: Nie podobasz mi się; otom ja, niech mi uczyni, co dobrego jest w oczach jego.
Ṣùgbọ́n bí òun bá sì wí pé, ‘Èmi kò ní inú dídùn sí ọ,’ wò ó, èmi nìyìí, jẹ́ kí òun ó ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ ní ojú rẹ̀.”
27 Nadto rzekł król do Sadoka kapłana: Izaliś nie jest widzącym? Wróćże się do miasta w pokoju, i Achimaas, syn twój, i Jonatan, syn Abijatara, dwaj synowie wasi, z wami.
Ọba sì wí fún Sadoku àlùfáà pé, “Aríran ha kọ́ ni ọ́? Padà sí ìlú ní àlàáfíà, àti àwọn ọmọ rẹ méjèèjì pẹ̀lú rẹ, Ahimasi ọmọ rẹ, àti Jonatani ọmọ Abiatari.
28 Oto, ja pomieszkam w równinach na puszczy, póki nie przyjdzie od was poselstwo dawające mi znać.
Wò ó, èmi ó dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà, títí ọ̀rọ̀ ó fi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá láti sọ fún mi.”
29 A tak odprowadzili zasię Sadok i Abijatar skrzynię Bożą do Jeruzalemu, i zostali tam.
Sadoku àti Abiatari sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà sí Jerusalẹmu, wọ́n sì gbé ibẹ̀.
30 Ale Dawid szedł na górę oliwną wstępując i płacząc, mając głowę przykrytą, i idąc boso; wszystek też lud, który z nim był, zakryli każdy głowę swoję, a szli wstępując i płacząc.
Dafidi sì ń gòkè lọ ní òkè igi olifi, o sì ń sọkún bí ó ti ń gòkè lọ, ó sì bo orí rẹ̀, ó ń lọ láìní bàtà ní ẹsẹ̀, gbogbo ènìyàn tí o wà lọ́dọ̀ rẹ̀, olúkúlùkù ọkùnrin sì bo orí rẹ̀, wọ́n sì ń gòkè lọ, wọ́n ń sọkún bí wọ́n ti ń gòkè lọ.
31 Tedy dano znać Dawidowi, mówiąc: Achitofel jest z tymi, którzy się zbuntowali z Absalomem. I rzekł Dawid: O Panie, proszę, obróć w głupstwo radę Achitofelowę.
Ẹnìkan sì sọ fún Dafidi pé, “Ahitofeli wà nínú àwọn aṣọ̀tẹ̀ pẹ̀lú Absalomu.” Dafidi sì wí pé, “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, sọ ìmọ̀ Ahitofeli di asán.”
32 I stało się, gdy Dawid przyszedł aż na wierzch góry, aby się tam pomodlił Bogu, oto, spotkał się z nim Chusaj Arachita, miawszy rozdarte szaty swe, a proch na głowie swojej.
Ó sì ṣe, Dafidi dé orí òkè, níbi tí ó gbé wólẹ̀ sin Ọlọ́run, sì wò ó, Huṣai ará Arki sì wá láti pàdé rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ yíya, àti erùpẹ̀, lórí rẹ̀.
33 I rzekł mu Dawid: Jeźli pójdziesz ze mną, będziesz mi ciężarem;
Dafidi sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá bá mi kọjá, ìwọ ó sì jẹ́ ìdíwọ́ fún mi.
34 Ale jeźli się do miasta wrócisz, a rzeczesz do Absaloma: Królu, sługą twoim będę, bom był sługą ojca twego zdawna, ale teraz jam sługą twoim: tedy mi obrócisz wniwecz radę Achitofelową.
Bí ìwọ bá sì padà sí ìlú, tí o sì wí fún Absalomu pé, ‘Èmi ó ṣe ìránṣẹ́ rẹ ọba, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ṣe ìránṣẹ́ baba rẹ nígbà àtijọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sì jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nísinsin yìí,’ kí ìwọ sì bá ìmọ̀ Ahitofeli jẹ́.
35 Azaż tam nie będzie z tobą Sadoka i Abijatara, kapłanów? Przetoż cokolwiek usłyszysz z domu królewskiego, oznajmisz Sadokowi i Abijatarowi, kapłanom.
Ṣé Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà.
36 Są też tam z nimi dwaj synowie ich, Achimaas, syn Sadoka, i Jonatan, syn Abijatara, przez które dacie mi znać o wszystkiem, co jedno usłuszycie.
Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Ahimasi ọmọ Sadoku, àti Jonatani ọmọ Abiatari; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yin ó sì rán ohunkóhun tí ẹ̀yin bá gbọ́ sí mi.”
37 Szedł tedy Chusaj przyjaciel Dawida do miasta, a Absalom też wjechał do Jeruzalemu.
Huṣai ọ̀rẹ́ Dafidi sì wá sí ìlú, Absalomu sì wá sí Jerusalẹmu.

< II Samuela 15 >