< II Samuela 13 >

1 I stało się potem, że Absalom syn Dawida, miał siostrę piękną, imieniem Tamar, której się rozmiłował Amnon, syn Dawida.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn èyí, Absalomu ọmọ Dafidi ní àbúrò obìnrin kan tí ó ṣe arẹwà, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Tamari; Amnoni ọmọ Dafidi sì fẹ́ràn rẹ̀.
2 I trapił się Amnon tak, że zachorował dla Tamary, siostry swojej; bo panną była, i trudno się zdało Amnonowi, aby jej co miał uczynić.
Amnoni sì banújẹ́ títí ó fi ṣe àìsàn nítorí Tamari àbúrò rẹ̀ obìnrin; nítorí pé wúńdíá ni; ó sì ṣe ohun tí ó ṣòro lójú Amnoni láti bá a dàpọ̀.
3 Lecz Amnon miał przyjaciela, którego zwano Jonadab, syn Semmy, brata Dawidowego; a ten Jonadab był mężem bardzo mądrym.
Ṣùgbọ́n Amnoni ní ọ̀rẹ́ kan, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Jonadabu, ọmọ Ṣimea ẹ̀gbọ́n Dafidi, Jonadabu sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn gidigidi.
4 Który mu rzekł: Czumuż tak schniesz, synu królewski, ode dnia do dnia? czemuż mi nie oznajmisz? Tedy mu rzekł Amnon: Romiłowałem się Tamary siostry Absaloma, brata mego.
Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ ọmọ ọba ń fi ń rù lójoojúmọ́ báyìí? Ǹjẹ́ o kò ní sọ fún mi?” Amnoni sì wí fún un pé, “Èmi fẹ́ Tamari àbúrò Absalomu arákùnrin mi.”
5 I rzekł mu Jonadab: Układź się na łóżku twojem, a uczyń się chorym; a gdy przyjdzie ojciec twój, aby cię nawiedził, rzeczesz mu: Niech przyjdzie proszę Tamar, siostra moja, i da mi jeść, a nagotuje przed oczyma memi potrawę, abym widział a jadł z ręki jej.
Jonadabu sì wí fún un pé, “Dùbúlẹ̀ ní ibùsùn rẹ kí ìwọ sì díbọ́n pé, ìwọ kò sàn, baba rẹ yóò sì wá wò ọ́, ìwọ ó sì wí fún un pé, ‘Jọ̀wọ́ jẹ́ kí Tamari àbúrò mi wá kí ó sì fún mi ní oúnjẹ kí ó sì ṣe oúnjẹ náà níwájú mi kí èmi ó rí i, èmi ó sì jẹ ẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀.’”
6 Tedy się układł Amnon, zmyślając sobie chorobę. A gdy przyszedł król nawiedzać go, rzekł Amnon do króla: Niech przyjdzie proszę Tamar, siostra moja, aby zgotowała przed oczyma memi dwa placki, abym jadł z ręki jej.
Amnoni sì dùbúlẹ̀, ó sì díbọ́n pé òun ṣàìsàn, ọba sì wá wò ó, Amnoni sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, jẹ́ kí Tamari àbúrò mi ó wá, kí ó sì dín àkàrà méjì lójú mi, èmi ó sì jẹ ní ọwọ́ rẹ̀.”
7 Przetoż posłał Dawid do Tamary w dom, mówiąc: Idź zaraz do domu Amnona, brata twego, a nagotuj mu potrawę.
Dafidi sì ránṣẹ́ sí Tamari ní ilé pé, “Lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ, kí ó sì se oúnjẹ fún un.”
8 Przyszła tedy Tamar do domu Amnona, brata swego, a on leżał; a wziąwszy mąki rozmąciła, i uczyniła placki przed oczyma jego, i upiekła je.
Tamari sì lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀, òun sì ń bẹ ní ìdùbúlẹ̀. Tamari sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà lójú rẹ̀, ó sì dín àkàrà náà.
9 Potem wziąwszy panewkę, wyłożyła przedeń; ale nie chciał jeść. I rzekł Amnon: Każcie wyjść precz wszystkim odemnie; a tak wyszli wszyscy od niego.
Òun sì mú àwo náà, ó sì dà á sínú àwo mìíràn níwájú rẹ̀; ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti jẹ. Amnoni sì wí pé, “Jẹ́ kí gbogbo ọkùnrin jáde kúrò lọ́dọ̀ mi!” Wọ́n sì jáde olúkúlùkù ọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
10 Tedy rzekł Amnon do Tamary: Przynieś sama tę potrawę do pokoju, abym jadł z ręki twej. A tak wziąwszy Tamara placki, które nagotowała, przyniosła je przed Amnona, brata swego, do pokoju.
Amnoni sì wí fún Tamari pé, “Mú oúnjẹ náà wá sí yàrá, èmi ó sì jẹ ẹ́ lọ́wọ́ rẹ.” Tamari sì mú àkàrà tí ó ṣe, ó sì mú un tọ Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ní yàrá.
11 A gdy mu podawała, aby jadł, uchwyciwszy ją, rzekł do niej: Pójdź, leż ze mną, siostro moja.
Nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti fi oúnjẹ fún un, òun sì dìímú, ó sì wí fún un pé, “Wá dùbúlẹ̀ tì mí, àbúrò mi.”
12 Która mu rzekła: Zaniechaj, bracie mój, a nie czyń mi gwałtu, bo się niema dziać nic takiego w Izraelu; nie czyńże tego szaleństwa.
Òun sì dá a lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀gbọ́n mi, má ṣe tẹ́ mi; nítorí pé kò tọ kí a ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ní Israẹli, ìwọ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
13 Bo gdzieżebym się obróciła z zelżywością moją? a ty będziesz jako jeden z szalonych w Izraelu. Ale raczej mów proszę z królem; bo mię nie odmówi tobie.
Àti èmi, níbo ni èmi ó gbé ìtìjú mi wọ̀? Ìwọ ó sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn aṣiwèrè ní Israẹli. Ǹjẹ́ nítorí náà, èmi bẹ̀ ọ́, sọ fún ọba; nítorí pé òun kì yóò kọ̀ láti fi mí fún ọ.”
14 Lecz on nie chciał usłuchać głosu jej, ale zmógłszy ją, uczynił jej gwałt, i leżał z nią.
Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti gbọ́ ohùn rẹ̀; ó sì fi agbára mú un, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀, ó sì bá a dàpọ̀.
15 Potem nienawidział jej Amnon nienawiścią bardzo wielką, tak iż większa była nienawiść, którą ją nienawidział, niż miłość, którą ją pierwej miłował. I rzekł jej Amnon: Wstań, idź precz.
Amnoni sì kórìíra rẹ̀ gidigidi, ìríra náà sì wá ju ìfẹ́ tí òun ti ní sí i rí lọ. Amnoni sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ!”
16 Która mu odpowiedziała: Dlatego to większa złość, niż owa, którąś zemną popełnił, że mię wyganiasz. Ale jej on nie chciał usłuchać.
Òun sì wí fún un pé, “Kó ha ní ìdí bí! Lílé tí ìwọ ń lé mi yìí burú ju èyí tí ìwọ ti ṣe sí mi lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀.
17 Owszem zawoławszy chłopca swego, który mu posługiwał, rzekł: Wywiedźcie tę zaraz precz odemnie, a zamknij drzwi za nią.
Òun sì pe ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́, ti obìnrin yìí sóde fún mi, kí o sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.”
18 (Ale ona miała na sobie pstrą suknią; albowiem w takowych sukniach chadzały córki królewskie, panny, ) i wywiódł ją precz sługa jego, i zawarł drzwi za nią.
Òun sì ní aṣọ aláràbarà kan lára rẹ̀, nítorí irú aṣọ àwọ̀lékè bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọbìnrin ọba tí í ṣe wúńdíá máa ń wọ̀. Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì mú un jáde, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.
19 Tedy posypała Tamar popiołem głowę swą, a pstrą szatę, która była na niej, rozdarła, i włożywszy rękę swą na głowę swoję, poszła, a idąc krzyczała.
Tamari sì bu eérú sí orí rẹ̀, ó sì fa aṣọ aláràbarà tí ń bẹ lára rẹ̀ ya, ó sì ká ọwọ́ rẹ̀ lé orí, ó sì ń kígbe bí ó ti ń lọ.
20 I rzekł do niej Absalom, brat jej: Albo Amnon, brat twój, był z tobą? Milczże, siostro moja; brat twój jest, nie przypuszczaj tego do serca swego. A tak mieszkała Tamar będąc opuszczona, w domu Absaloma, brata swego.
Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ sì bí i léèrè pé, “Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ bá ọ sùn bí? Ǹjẹ́ àbúrò mi, dákẹ́; ẹ̀gbọ́n rẹ ní í ṣe; má fi nǹkan yìí sí ọkàn rẹ.” Tamari sì jókòó ní ìbànújẹ́ ní ilé Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
21 A król Dawid usłyszawszy o tem wszystkiem, rozgniewał się bardzo.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Dafidi ọba gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi.
22 I nie mówił Absalom z Amnonem ani źle ani dobrze; bo nienawidział Absalom Amnona, przeto że zgwałcił Tamarę, siostrę jego.
Absalomu kò sì bá Amnoni sọ nǹkan rere, tàbí búburú, nítorí pé Absalomu kórìíra Amnoni nítorí èyí tí ó ṣe, àní tí ó fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
23 I stało się po wyjściu dwóch lat, gdy strzyżono owce Absalomowe w Baalchasor, które jest w Efraim, że wyzwał Absalom wszystkich synów królewskich.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọdún méjì, Absalomu sì ní olùrẹ́run àgùntàn ní Baali-Hasori, èyí tí ó gbé Efraimu, Absalomu sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba.
24 Bo przyszedł Absalom do króla i rzekł: Oto teraz strzygę owce słudze twemu; niech idzie proszę król i słudzy jego z sługą twoim.
Absalomu sì tọ ọba wá, ó sì wí pé, “Wò ó, jọ̀wọ́, ìránṣẹ́ rẹ ní olùrẹ́run àgùntàn, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ọba, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ bá ìránṣẹ́ rẹ lọ.”
25 I rzekł król do Absaloma: Nie, synu mój; niech teraz nie chodzimy wszyscy, abyśmy cię nie obciążyli. A choć mu przynaglał, nie chciał iść, ale mu błogosławił.
Ọba sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ, ọmọ mi, mo bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí gbogbo wa lọ, kí a má bá à mú ọ náwó púpọ̀.” Ó sì rọ̀ ọ́ gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ lọ, òun sì súre fún un.
26 Rzekł potem Absalom: Ponieważ ty nie chcesz, niechże idzie proszę z nami Amnon, brat mój. I rzekł mu król: A pocóżby miał iść z tobą?
Absalomu sì wí pé, “Bí kò bá le rí bẹ́ẹ̀, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí Amnoni ẹ̀gbọ́n mi bá wa lọ.” Ọba sì wí pé, “Ìdí rẹ̀ tí yóò fi bá ọ lọ.”
27 A gdy nań nalegał Absalom, posłał z nim Amnona i wszystkie syny królewskie.
Absalomu sì rọ̀ ọ́, òun sì jẹ́ kí Amnoni àti gbogbo àwọn ọmọ ọba bá a lọ.
28 Tedy przykazał Absalom sługom swoim, mówiąc: Pilnujcie proszę, gdy podweseli serce swoje Amnon winem, a rzekę do was: Bijcie Amnona, zabijcież go, nie bójcie się, bom ja wam rozkazał; zmocnijcież się, a mężnie sobie pocznijcie.
Absalomu sì fi àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Kí ẹ̀yin máa kíyèsi àkókò tí ọtí-wáinì yóò mú ọkàn Amnoni dùn, èmi ó sì wí fún yín pé, ‘Kọlu Amnoni,’ kí ẹ sì pa á. Ẹ má bẹ̀rù. Ṣé èmi ni ó fi àṣẹ fún yin? Ẹ ṣe gírí, kí ẹ ṣe bí alágbára ọmọ.”
29 I uczynili słudzy Absalomowi Amnonowi, jako im był rozkazał Absalom. Przetoż wstawszy wszyscy synowie królewscy, wsiedli każdy na muła swego, i uciekali.
Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì ṣe sí Amnoni gẹ́gẹ́ bí Absalomu ti pàṣẹ. Gbogbo àwọn ọmọ ọba sì dìde, olúkúlùkù gun ìbáaka rẹ̀, wọ́n sì sá.
30 Wtem gdy jeszcze byli w drodze, wieść przyszła do Dawida w te słowa: Pozabijał Absalom wszystkie syny królewskie, i nie został z nich ani jeden.
Nígbà tí wọ́n ń bẹ lọ́nà, ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Dafidi pé, “Absalomu pa gbogbo àwọn ọmọ ọba, ọ̀kan kò sì kù nínú wọn.”
31 Tedy wstał król i rozdarł szaty swoje, i padł na ziemię, a wszyscy słudzy jego stali około niego, rozdarłszy szaty swoje.
Ọba sì dìde, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dùbúlẹ̀ ni ilẹ̀; gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n dúró tì í sì fà aṣọ wọn ya.
32 Ozwawszy się Jonadab syn Semmy, brata Dawidowego, rzekł: Niech nie mówi pan mój, że wszystkie młodzieńce, syny królewskie, pobito; boć tylko sam Amnon zabity, gdyż to w umyśle Absalomowym ułożono było od onego dnia, którego zgwałcił Tamarę, siost rę jego.
Jonadabu ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì dáhùn ó sì wí pé, “Kí olúwa mi ọba má ṣe rò pé wọ́n ti pa gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin àwọn ọmọ ọba; nítorí pé Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú, nítorí láti ẹnu Absalomu wá ni a ti pinnu rẹ̀ láti ọjọ́ tí ó ti fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
33 Przetoż teraz niech nie przypuszcza tego król, pan mój, do serca swego, mówiąc: Wszyscy synowie królewscy polegli, gdyż tylko sam Amnon poległ.
Ǹjẹ́ kí olúwa mi ọba má ṣe fi nǹkan yìí sí ọkàn pé gbogbo àwọn ọmọ ọba ni o kú, nítorí Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú.”
34 Tedy uciekł Absalom; a podniósłszy sługa, który był na straży, oczy swe, ujrzał, a oto, lud wielki przychodził drogą, którą chadzano do niego z boku góry.
Absalomu sì sá. Ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ń ṣọ́nà sì gbé ojú rẹ̀ sókè, o si rí i pé, “Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń bọ́ lọ́nà lẹ́yìn rẹ̀ láti ìhà òkè wá.”
35 I rzekł Jonadab do króla: Oto synowie królewscy jadą; wedle słowa sługi twego tak się stało.
Jonadabu sì wí fún ọba pé, “Wò ó, àwọn ọmọ ọba ń bọ́; gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí.”
36 A gdy przestał mówić, oto synowie królewscy przyszli, a podniósłszy głosy swe płakali; także i król, i wszyscy słudzy jego płakali płaczem bardzo wielkim.
Nígbà tí ó sì parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ, sì wò ó àwọn ọmọ ọba dé, wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún, ọba àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú sì sọkún ńlá ńlá.
37 Ale Absalom uciekłszy uszedł do Tolmaja, syna Ammihudowego, króla Giessur; i żałował Dawid syna swego po one wszystkie dni.
Absalomu sì sá, ó sì tọ Talmai lọ, ọmọ Ammihudu, ọba Geṣuri. Dafidi sì ń káàánú nítorí ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́.
38 A Absalom uciekł, i przyszedł do Giessur, a był tam przez trzy lata.
Absalomu sì sá, ó sì lọ sí Geṣuri ó sì gbé ibẹ̀ lọ́dún mẹ́ta.
39 Potem pragnął król Dawid widzieć Absaloma; bo już był odżałował śmierci Amnonowej.
Ọkàn Dafidi ọba sì fà gidigidi sí Absalomu, nítorí tí ó tí gba ìpẹ̀ ní ti Amnoni: ó sá à ti kú.

< II Samuela 13 >