< II Samuela 1 >

1 I stało się po śmierci Saulowej, gdy się Dawid wrócił od porażki Amalekitów, że zamieszkał Dawid w Sycelegu przez dwa dni.
Lẹ́yìn ikú Saulu, Dafidi ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki bọ̀, ó sì dúró ní Siklagi ní ọjọ́ méjì.
2 Tedy dnia trzeciego przybieżał mąż z obozu Saulowego, a szaty jego rozdarte były, i proch na głowie jego; który przyszedłszy do Dawida, upadł na ziemię, i pokłonił się.
Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Saulu, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dafidi, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.
3 I rzekł do niego Dawid: Skąd idziesz? I odpowiedział mu: Z obozum Izraelskiego uszedł.
Dafidi sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?” “Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Israẹli.”
4 Rzekł mu znowu Dawid: Cóż się stało? proszę powiedz mi. I odpowiedział: To, że uciekł lud z bitwy, a do tego wiele poległo z ludu i pomarło, także i Saul, i Jonatan, syn jego, polegli.
Dafidi béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” “Sọ fún mi.” Ó wí pé, “Àwọn ọkùnrin náà sá láti ojú ogun. Ọ̀pọ̀ wọn ṣubú, wọ́n sì kú. Saulu àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Jonatani sì kú pẹ̀lú.”
5 Zatem rzekł Dawid do młodzieńca, który mu to powiedział: Jakoż wiesz, iż umarł Saul i Jonatan, syn jego?
Nígbà náà, ní Dafidi sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Báwo ni o ṣe mọ̀ pé Saulu àti ọmọkùnrin rẹ̀ Jonatani ti kú.”
6 Odpowiedział mu młodzieniec, który mu to oznajmił: Przyszedłem z trafunku na górę Gilboe, a oto, Saul tkwiał na włóczni swojej, a wozy i jezdni doganiali go.
Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sọ pé, “Mo wà ní orí òkè Gilboa níbẹ̀ ni Saulu fi ara tí ọkọ̀ rẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin sì ń lépa rẹ̀.
7 Tedy obejrzawszy się, obaczył mię, i zawołał na mię, i rzekłem: Owom ja.
Nígbà tí ó wò yíká, tí ó rí mí, ó pè mi, mo sì wí pé, ‘Kí ni mo lè ṣe?’
8 I rzekł mi: Coś ty zacz? A jam mu odpowiedział: Jestem Amalekita.
“Ó bi mí wí pé, ‘Ta ni ìwọ?’ “Mo dáhùn pé, ‘Ará a Amaleki.’
9 I rzekł mi: Stań, proszę, nademną, a zabij mię: bo mię zdjęły ciężkości, gdyż jeszcze wszystka dusza moja we mnie jest.
“Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láààyè.’
10 Przetoż stanąwszy nad nim, zabiłem go: bom wiedzieł, że nie będzie żyw po upadku swoim, i wziąłem koronę, która była na głowie jego, i zawieszenie, które było na ramieniu jego, a przyniosłem je tu do pana mego.
“Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún olúwa mi.”
11 Tedy Dawid pochwyciwszy szaty swoje, rozdarł je, także i wszyscy mężowie, którzy z nim byli.
Nígbà náà ni, Dafidi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya.
12 A żałując płakali, i pościli aż do wieczora dla Saula, i dla Jonatana, syna jego, i dla ludu Pańskiego, i dla domu Izraelskiego, że polegli od miecza.
Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sọkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti fún àwọn ọmọ-ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Israẹli, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.
13 I rzekł Dawid do młodzieńca, który mu to oznajmił: Skądeś ty? I odpowiedział: Jestem synem męża przychodnia Amalekity.
Dafidi sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?” O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Amaleki.”
14 Zatem rzekł do niego Dawid: Jakożeś się nie bał ściągnąć ręki twej, abyś zabił pomazańca Pańskiego?
Dafidi béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ kò fi bẹ̀rù láti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti fi pa ẹni àmì òróró Olúwa?”
15 Zawołał tedy Dawid jednego z sług, i rzekł: Przystąp, a zabij go, a on go uderzył, że umarł.
Nígbà náà Dafidi pe ọ̀kan nínú ọkùnrin, ó sì wí pé, “Lọ, gbé e lulẹ̀!” Nígbà náà ó gbé e lulẹ̀, ó sì kú.
16 I rzekł do niego Dawid: Krew twoja na głowę tweję: bo usta twoje świadczyły przeciw tobie, mówiąc: Jam zabił pomazańca Pańskiego.
Nítorí Dafidi wí fún un pé, “Ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò wà lórí ara rẹ, nítorí ẹnu ara rẹ ni o fi sọ pé, ‘Mo pa ẹni àmì òróró Olúwa.’”
17 Lamentował tedy Dawid lamentem takowym nad Saulem, i nad Jonatanem, synem jego;
Dafidi sì fi orin ọ̀fọ̀ yìí ṣọ̀fọ̀ lórí Saulu àti lórí Jonatani ọmọ rẹ̀,
18 (Rozkazawszy jednak, aby uczono synów Judzkich z łuku strzelać, jako napisano w księgach Jasar.)
Ó sì pàṣẹ pé kí a kọ́ àwọn ọkùnrin Juda ní orin arò yìí tí ó jẹ́ ti ọrun (a kọ ọ́ sí inú ìwé Jaṣari):
19 O ozdobo Izraelska! na górach twoich zranionyś jest; jakoż polegli mocarze twoi!
“Ògo rẹ, Israẹli ni a pa ní òkè gíga rẹ. Wò bí àwọn alágbára ṣe ń ṣubú!
20 Nie powiadajcież w Get, a nie rozgłaszajcie po ulicach w Aszkalonie, aby się snać nie weseliły córki Filistyńskie, by się snać nie radowały córki nieobrzezańców.
“Ẹ má ṣe sọ ọ́ ní Gati, ẹ má ṣe kéde rẹ̀ ní òpópónà Aṣkeloni, kí àwọn ọmọbìnrin Filistini má bá à yọ̀, kí àwọn ọmọbìnrin aláìkọlà má ba à dunnú.
21 O góry Gielboe! ani rosa, ani deszcz niech nie upada na was, i niech tam nie będą pola urodzajne; albowiem tam porzucona jest tarcz mocarzów, tarcz Saulowa, jakoby nie był pomazany olejem.
“Ẹ̀yin òkè Gilboa, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe rí ìrì tàbí òjò, tàbí oko tí ó mú èso ọrẹ wá. Nítorí ibẹ̀ ni asà alágbára ti ṣègbé, asà Saulu, bí ẹni pé a kò fi òróró yàn án.
22 Od krwi zabitych, i od sadła mocarzów strzała łuku Jonatanowego nie wracała się na wstecz, a miecz Saulowy nie wracał się próżno.
“Ọrun Jonatani kì í padà bẹ́ẹ̀ ni idà Saulu kì í padà lásán, láì kan ẹ̀jẹ̀ àwọn tí a pa, àti ẹran àwọn alágbára.
23 Saul i Jonatan miłośni i przyjemni za żywota swego, i w śmierci swojej nie są rozłączeni, nad orły lekciejsi, nad lwy mocniejsi byli.
Saulu àti Jonatani— ní ọjọ́ ayé, wọ́n fẹ́ràn ara, wọn sì dùn, ní ikú, wọn kò sì yà ara wọ́n. Wọ́n yára ju idì lọ, wọ́n lágbára ju kìnnìún lọ.
24 Córki Izraelskie płaczcie nad Saulem, który was przyodziewał szarłatem rozkosznym, a który was ubierał w klejnoty złote na szaty wasze.
“Ẹ̀yin ọmọbìnrin Israẹli, ẹ sọkún lórí Saulu, ẹni tí ó fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára wọ̀ yín, ẹni tí ó fi wúrà sí ara aṣọ yín.
25 Jakoż polegli mocarze pośród bitwy! Jonatan na górach twoich zabity jest.
“Wò ó bí alágbára ti ṣubú ní ojú ogun! Jonatani, ìwọ tí a pa ní òkè gíga.
26 Bardzo mi cię żal, bracie mój Jonatanie, byłeś mi bardzo wdzięcznym; większa u mnie była miłość twoja, niż miłość niewieścia.
Ọkàn mi gbọgbẹ́ fún ọ Jonatani arákùnrin mi; ìwọ ṣọ̀wọ́n fún mi. Ìfẹ́ rẹ sí mi jẹ́ ìyanu, ó jẹ́ ìyanu ju ti obìnrin lọ.
27 Jakoż polegli mocarze, a poginęła broń wojenna!
“Wò ó bí alágbára ti ṣubú! Ohun ìjà sì ti ṣègbé!”

< II Samuela 1 >