< II Królewska 25 >

1 I stało się roku dziewiątego królowania jego, miesiąca dziesiątego, dnia dziesiątego tegoż miesiąca, że przyciągnął Nabuchodonozor, król Babiloński, on i wszystko wojsko jego przeciw Jeruzalemowi, i położył się obozem u niego, a porobił przeciwko niemu szańce w około.
Nígbà tí ó di ọdún kẹsànán ìjọba Sedekiah. Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli yan lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo àwọn ogun rẹ̀. Ó sì pàgọ́ sí ìta ìlú ó sì mu àwọn iṣẹ́ ìdọ̀tí fi yí gbogbo rẹ̀ ká.
2 A tak oblężone było miasto aż do jedenastego roku króla Sedekijasza.
Ìlú náà sì wà ní ìhámọ́ lábẹ́ ìgbóguntì títí di ọdún kọkànlá ti ọba Sedekiah.
3 Tedy dnia dziewiątego czwartego miesiąca był wielki głód w mieście, a nie miał chleba lud ziemi.
Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹsànán oṣù kẹrin, ìyàn tí mú ní ìlú tí ó jẹ́ wí pé kò sí oúnjẹ fún àwọn ènìyàn láti jẹ.
4 I przełamano mur miejski, a wszyscy ludzie rycerscy uciekli w nocy drogą, kędy idą do bramy, która jest między dwoma murami, które były podle ogrodu królewskiego; a Chaldejczycy leżeli około miasta, a król uszedł drogą do pustyni.
Nígbà náà odi ìlú náà sì fọ́nká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun sálọ ní òru láti ẹnu-ọ̀nà bodè láàrín ògiri méjì ní ẹgbẹ́ ọgbà ọba, àwọn ará Babeli wọ́n sì yí ìlú náà ká. Wọ́n sálọ sí ìkọjá Arabah.
5 I goniło wojsko Chaldejskie króla, i pojmało go na polach Jerycho; a wszystko wojsko jego rozpierzchnęło się od niego.
Ṣùgbọ́n ogun àwọn ará Kaldea sì lépa ọba, wọ́n sì lé e bá ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko. Gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì yà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì túká,
6 A tak pojmawszy króla przywiedli go do króla Babilońskiego do Rebli, kędy o nim uczynili sąd.
wọ́n sì mú un. Wọ́n sì mú lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli ní Ribla, níbi tí à ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀.
7 A synów Sedekijaszowych pozabijali przed oczyma jego; potem Sedekijasza oślepiwszy związali go łańcuchami miedzianemi, i zawiedli go do Babilonu.
Wọ́n sì pa ọmọ Sedekiah níwájú rẹ̀, wọ́n sì yọ ojú rẹ̀ jáde, wọn dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n idẹ wọ́n sì gbe é lọ sí Babeli.
8 Potem miesiąca piątego, siódmego dnia tegoż miesiąca, ( ten jest rok dziewiętnasty królowania Nabuchodonozora, króla Babilońskiego) przyciągnął Nabuzardan, hetman żołnierski, sługa króla Babilońskiego, do Jeruzalemu;
Ní ọjọ́ keje ní oṣù karùn-ún, ní ọdún kọkàndínlógún ti Nebukadnessari ọba Babeli, Nebusaradani olórí ẹ̀ṣọ́, ìránṣẹ́ ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu;
9 I spalił do Pański, i dom królewski, i wszystkie domy w Jeruzalemie, owa wszystko budowanie kosztowne popalił ogniem.
ó sì finá sí ilé Olúwa, ilé ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà ní Jerusalẹmu àti gbogbo ilé ńlá ńlá ni ó dáná sun.
10 Mury także Jeruzalemskie w około rozwaliło wszystko wojsko Chaldejskie, które było z onym hetmanem żołnierskim.
Gbogbo àwọn ogun Babeli, tí ó wà lọ́dọ̀ olórí ẹ̀ṣọ́, wó ògiri tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀.
11 A ostatek ludu, który był został w mieście, i zbiegi, którzy byli zbiegli do króla Babilońskiego, i inne pospólstwo, przeniósł Nabuzardan, hetman żołnierski.
Nebusaradani olórí ẹ̀ṣọ́ kó gbogbo àwọn tálákà àti gbogbo àwọn tí ó kù ní ìlú, ní ìgbèkùn lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn tí ó ya lọ, tí ó sì ya tọ ọba Babeli lọ, àti ìyókù àwọn ènìyàn náà.
12 Tylko z ubogich onej ziemi zostawił hetman żołnierski, aby byli winiarzami i oraczami.
Ṣùgbọ́n olórí ẹ̀ṣọ́ fi àwọn tálákà ènìyàn ilẹ̀ náà sílẹ̀ láti máa bojútó àjàrà àti láti máa ṣe aroko.
13 Nadto słupy miedziane, które były w domu Pańskim, i podstawki, i morze miedziane, które było w domu Pańskim, potłukli Chaldejczycy, i przenieśli wszystkę miedź do Babilonu.
Àwọn ará Babeli fọ́ ọ̀wọ̀n idẹ wọ̀n-ọn-nì àti àwọn ìjókòó wọ̀n-ọn-nì, àti agbada idẹ títóbi wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ilé Olúwa, àwọn ará Babeli fọ́ túútúú, wọ́n sì kó idẹ náà lọ sí Babeli.
14 Kotły też i łopaty, i naczynia muzyczne, i misy i wszystko naczynie miedziane, którem usługiwano; pobrali.
Wọ́n sì kó àwọn ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọkọ́ wọ̀n-ọn-nì, ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, síbí wọ̀n-ọn-nì àti gbogbo ohun èlò idẹ wọ̀n-ọn-nì tí wọ́n fi ṣiṣẹ́ lọ.
15 I kadzielnice, i miednice, i co było złotego w złocie, i co było srebrnego w srebrze, pobrał hetman żołnierski.
Olórí ẹ̀ṣọ́ kó ohun ìfọnná wọ̀n-ọn-nì, àti ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, èyí tí wọ́n fi wúrà àti fàdákà ṣe lọ.
16 Słupy dwa, morze jedno, i podstawki, które był sprawił Salomon w domu Pańskim, a nie było wagi miedzi onego wszystkiego naczynia.
Àwọn ọ̀wọ́n méjì, agbada ńlá kan, àti ìjókòó wọ̀n-ọn-nì tí Solomoni ti ṣe fún ilé Olúwa, idẹ ni gbogbo ohun èló wọ̀nyí, ó ju èyí tí a lé wọ́n lọ.
17 Ośmnaście łokci wzwyż było słupa jednego, a gałka na nim miedziana; a gałka miała na wzwyż trzy łokcie, a siatka i jabłka granatowe na gałce w około, wszystko miedziane. Takiż też był i drugi słup z siatką,
Gíga ọ̀wọ́n kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjìdínlógún, àti ọnà-orí rẹ̀ idẹ ni: àti gíga ọnà-orí náà ni ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta; àti iṣẹ́ híhun náà, àti àwọn pomegiranate tí ó wà lórí ọnà-orí náà yíká, gbogbo rẹ̀ ti idẹ ni: gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́n yìí sì ni ọ̀wọ́n kejì pẹ̀lú iṣẹ́ híhun.
18 Wziął też hetman żołnierski Sarajego, kapłana przedniego, i Sofonijasza, kapłana wtórego, i trzech odźwiernych.
Olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ sì mú gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, Seraiah olórí àwọn àlùfáà, Sefaniah àlùfáà kejì, àti àwọn olùṣọ́ ìloro mẹ́ta.
19 Wziął też z miasta dworzanina jednego, który był przełożony nad ludem, rycerskim, i pięć mężów z tych, którzy stawali przed królem, którzy byli znalezieni w mieście, i pisarza przedniego wojskowego, który spisywał lud onej ziemi, i sześćdziesiąt mężów ludu z onej ziemi, którzy się znależli w mieście.
Àti àwọn tí ó kù ní ìlú, ó mú ìwẹ̀fà kan tí ó fi se olórí àwọn ológun, àti ọkùnrin márùn-ún nínú àwọn tó ń gba ọba ní ìmọ̀ràn. Ó sì tún mú akọ̀wé olórí ogun, tí ó ń to àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà àti ọgọ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ tí wọ́n rí ní ìlú.
20 Pojmawszy ich tedy Nabuzardan, hetman żołnierski, zawiódł ich do króla Babilońskiego do Ryblaty.
Nebusaradani, olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ kó gbogbo wọn, ó sì mú wọn tọ ọba Babeli wá ní Ribla.
21 I pobił ich król Babiloński, a pomordował ich w Ryblacie w ziemi Emat; a tak przeniesiony jest Juda z ziemi swojej.
Níbẹ̀ ní Ribla, ní ilẹ̀ Hamati, ọba Babeli sì kọlù wọ́n. Bẹ́ẹ̀ ni a mú Juda kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀.
22 Ale nad ludem, który jeszcze był został w ziemi Judzkiej, którego był zostawił Nabuchodonozor, król Babiloński, przełożył Godolijasza, syna Ahykamowego, syna Safanowego.
Nebukadnessari ọba Babeli ó mú Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani, láti jẹ baálẹ̀ lórí àwọn ènìyàn tí ó kù sílẹ̀ ní ilẹ̀ Juda.
23 A gdy usłyszeli wszyscy hetmani wojska, sami i mężowie ich, że przełożył król Babiloński Godolijasza, tedy przyszli do Godolijasza do Masfy; mianowicie, Izmael, syn Natanijaszowy, i Johanan, syn Kareaszowy, i Serajasz, syn Tanhumeta Netofatczyk a, i Jezonijasz, syn Maachatowy sami i mężowie ich.
Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ọkùnrin wọn gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ni Mispa. Iṣmaeli ọmọ Netaniah, Johanani ọmọ Karea, Seraiah ọmọ Tanhumeti ará Netofa, Jaaṣaniah ọmọ ará Maakati, àti àwọn ọkùnrin wọn.
24 Którym przysiągł Godolijasz, i mężom ich, i rzekł im: Nie bójcie się być poddanymi Chaldejczykom; zostańcie w ziemi, a służcie królowi Babilońskiemu, i będzie wam dobrze.
Gedaliah sì búra láti fi dá àwọn ènìyàn rẹ̀ lójú. “Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn ìjòyè ará Babeli,” ó wí pé, “Ẹ máa gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.”
25 I stało się miesiąca siódmego, że przyszedł Izmael, syn Natanijasza, syna Elisamowego, z nasienia królewskiego, i dziesięć mężów z nim, i zabili Godolijasza, i umarł; także Żydów i Chaldejczyków, którzy z nim byli w Masfa.
Ní oṣù keje, ni Iṣmaeli ọmọ Netaniah, ọmọ Eliṣama, nínú irú-ọmọ ọba, wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mẹ́wàá, ó sì kọlù Gedaliah àti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mẹ́wàá ará Juda àti àwọn ará Babeli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Mispa.
26 Tedy powstał wszystek lud od małego aż do wielkiego, i hetmani wojsk, a poszli do Egiptu; bo się bali Chaldejczyków.
Nítorí èyí, gbogbo àwọn ènìyàn láti ẹni kékeré títí dé ẹni ńlá, àti pẹ̀lú àwọn olórí ogun, sálọ si Ejibiti nítorí ẹ̀rù àwọn ará Babeli.
27 Stało się także trzydziestego i siódmego roku pojmania Joachyna, króla Judzkiego, dwunastego miesiąca dnia dwudziestego siódmego tegoż miesiąca, że wywyższył Ewilmerodach, król Babiloński, tegoż roku, gdy począł królować, głowę Joachyna, króla Judzkiego, uwolniwszy go z więzienia.
Ní ọdún kẹtàdínlógójì ìgbèkùn Jehoiakini ọba Juda, ní oṣù kejìlá, ọjọ́ kẹtàdínlógbọ̀n oṣù, Efili-Merodaki ọba Babeli, ní ọdún tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba, ó gbé orí Jehoiakini ọba Juda sókè, ó sì tú sílẹ̀ kúrò nínú túbú.
28 I rozmawiał z nim łaskawie, a wystawił stolicę jego nad stolicę innych królów, którzy z nim byli w Babilonie.
Ó ń sọ̀rọ̀ rere fún un, ó sì gbé ìtẹ́ rẹ̀ ga ju ìtẹ́ àwọn ọba tókù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Babeli.
29 Odmienił też odzienie jego, w którem był w więzieniu, i jadł chleb zawsze przed obliczem jego po wszystkie dni żywota swego.
Ó sì pàrọ̀ àwọn aṣọ túbú rẹ̀, ó sì ń jẹun ní gbogbo ìgbà ní iwájú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
30 Obrok też jemu naznaczony ustawicznie mu dawano od króla, na każdy dzień po wszystkie dni żywota jego.
Ní ojoojúmọ́, ọba fún Jehoiakini ní ìpín tirẹ̀ bí ó tí ń bẹ láààyè.

< II Królewska 25 >