< II Kronik 5 >

1 A tak dokończona jest wszystka robota, którą sprawił Salomon do domu Pańskiego, i wniósł tam Salomon rzeczy, które był poświęcił Dawid ojciec jego: srebro, i złoto, i wszystkie naczynia włożył do skarbów domu Bożego.
Nígbà tí gbogbo iṣẹ́ tí Solomoni ti ṣe fún tẹmpili Olúwa ti parí, ó kó gbogbo àwọn nǹkan tí Dafidi baba rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀: wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò ọ̀ṣọ́, ó sì fi wọ́n sínú ìṣúra ilé Ọlọ́run.
2 Tedy zebrał Salomon starszych z Izraela, i wszystkich przedniejszych z każdego pokolenia, i przedniejszych z ojców synów Izraelskich, do Jeruzalemu, aby przenieśli skrzynię przymierza Pańskiego z miasta Dawidowego, które jest Syon.
Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli jọ sí Jerusalẹmu, gbogbo àwọn olórí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan àti àwọn olóyè àwọn ìdílé Israẹli, kí wọn kí ó gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá láti Sioni ìlú Dafidi.
3 I zebrali się do króla wszyscy mężowie Izraelscy w święto uroczyste, które bywa miesiąca siódmego.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli péjọ sí ọ̀dọ̀ ọba ní àkókò àjọ àgọ́.
4 A gdy się zeszli wszyscy starsi z Izraela, wzięli Lewitowie skrzynię;
Gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli sì wá, àwọn ọmọ Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
5 I nieśli skrzynię, i namiot zgromadzenia, i wszystkie naczynia święte, które były w namiocie, przenieśli je kapłani i Lewitowie.
Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí náà gòkè àti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ni ó mú wọn gòkè wá.
6 Zatem król Salomon, i wszystko zgromadzenie Izraelskie, co się byli zeszli do niego przed skrzynię, ofiarowali owce i woły, których nie można obliczyć, ani obrachować przez mnóstwo.
Nígbà náà ni ọba Solomoni àti gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, wà níwájú àpótí ẹ̀rí náà wọ́n sì fi àgùntàn àti màlúù tí a kò le è kà tán rú ẹbọ, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è mọ iye wọn tán nítorí bí wọ́n ti pọ̀ tó.
7 Wnieśli tedy kapłani skrzynię przymierza Pańskiego na miejsce jej, do wnętrznego domu, to jest do świątnicy najświętszej pod skrzydła Cherubinów;
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
8 Albowiem Cherubinowie mieli rozciągnione skrzydła nad miejscem skrzyni, i okrywali Cherubinowie skrzynię, i drążki jej z wierzchu.
Àwọn Kérúbù na ìyẹ́ wọn bo ibi àpótí ẹ̀rí náà àti àwọn ọ̀pá tí ó gbé e ró.
9 I powyciągali one drążki, tak że końce ich było widać z skrzyni na przodku świątnicy; ale ich nie widać było zewnątrz, i tamże zostały aż do dnia tego.
Àwọn ọ̀pá rẹ̀ náà gùn tó bẹ́ẹ̀ tí a fi rí orí àwọn ọ̀pá náà láti ibi àpótí ẹ̀rí náà níwájú Ibi Mímọ́ náà, ṣùgbọ́n a kò rí wọn lóde. Níbẹ̀ ni ó sì wà títí di òní yìí.
10 A nic nie było w skrzyni, tylko dwie tablice, które tam był włożył Mojżesz na Horebie, gdy stanowił przymierze Pan z synami Izraelskimi po wyjściu ich z Egiptu.
Kò sí ohun kan nínú àpótí ẹ̀rí náà bí kò ṣe wàláà méjì tí Mose fi sínú rẹ̀ ní Horebu, ní ìgbà tí Olúwa fi bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti.
11 A gdy wychodzili kapłani z świątnicy, (bo wszyscy kapłani, ile ich było, poświęcili się byli, a nie przestrzegali porządków.)
Lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà jáde wá láti Ibi Mímọ́. Gbogbo àwọn àlùfáà tí ó wà níbẹ̀ ni ó ya ara wọn sí mímọ́ láìbìkítà fún ìpín wọn.
12 Stali Lewitowie śpiewacy, i wszyscy, którzy byli przy Asafie, Hemmanie, i Jedytunie, i synowie ich, i bracia ich, obleczeni będąc w szaty bisiorowe, z cymbałami i z harfami i z cytrami, stali mówię na wschodniej stronie ołtarza, a przy nich kapłanów sto i dwadzieścia trąbiących w trąby.
Gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ akọrin: Asafu, Hemani, Jedutuni àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ẹbí wọn, wọ́n dúró ní igun ìlà-oòrùn pẹpẹ náà wọ́n wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ tuntun wọ́n ń lo kimbali, dùùrù àti ohun èlò orin olókùn. Ìwọ̀n ọgọ́fà àwọn àlùfáà tí wọ́n ń fun ìpè ni wọ́n tẹ̀lé wọn.
13 I stało się, gdy jednostajnie trąbili, i śpiewali, i wydawali jednaki głos, chwaląc i sławiąc Pana: i gdy podnosili głos na trąbach, i na cymbałach, i na innych instrumentach muzycznych, i chwalili Pana, że dobry, że na wieki miłosierdzie jego, tedy dom on napełniony jest obłokiem, to jest dom Pański.
Àwọn afùnpè àti àwọn akọrin pa ohùn wọn pọ̀ sí ọ̀kan ṣoṣo, láti fi ìyìn àti ọpẹ́ fun Olúwa. Wọ́n fi ìpè, kimbali àti àwọn ohun èlò orin mìíràn mọ́ ọn, wọ́n gbé ohùn wọn sókè láti fi yin Olúwa, wọ́n ń kọrin pé, “Ó dára; ìfẹ́ rẹ̀ wà títí láéláé.” Nígbà náà ni ìkùùkuu ojú ọ̀run kún inú tẹmpili Olúwa,
14 Tak iż się nie mogli kapłani ostać, i służyć dla onego obłoku; albowiem napełniła była chwała Pańska dom Boży.
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn àlùfáà kò le è ṣiṣẹ́ ìsìn wọn nítorí ìkùùkuu náà, nítorí ògo Olúwa kún inú tẹmpili Ọlọ́run.

< II Kronik 5 >