< II Kronik 11 >

1 Przyjechawszy tedy Roboam do Jeruzalemu, zebrał dom Judowy i pokolenie Benjaminowe, sto i ośmdziesiąt tysięcy mężów przebranych do boju, aby walczyli z Izraelem, a żeby przywrócone było królestwo do Roboama.
Nígbà tí Rehoboamu dé Jerusalẹmu, ó kó ilé Juda àti Benjamini jọ, ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n jẹ́ ológun, láti bá Israẹli jà kí ó lè mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀.
2 I stało się słowo Pańskie do Semejasza, męża Bożego, mówiąc:
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
3 Powiedz Roboamowi, synowi Salomonowemu, królowi Judzkiemu, i wszystkiemu Izraelowi w Judzie i w pokoleniu Benjaminowem, mówiąc:
“Wí fún Rehoboamu ọmọ Solomoni ọba Juda, sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní Juda àti Benjamini,
4 Tak mówi Pan: Nie wychodźcie, ani walczcie z braćmi waszymi, wróćcie się każdy do domu swego; albowiem odemnie stała się ta rzecz. I usłuchali słowa Pańskiego, i wrócili się, a nie ciągnęli przeciw Jeroboamowi.
‘Èyí ní ohun tí Olúwa wí. Ẹ má ṣe gòkè lọ láti lọ jà pẹ̀lú arákùnrin yín, ẹ lọ sílé, gbogbo yín, nítorí ti ìṣe mi nìyí.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n sì padà sẹ́yìn láti yan lọ dojúkọ Jeroboamu.
5 I mieszkał Roboam w Jeruzalemie, a pobudował miasta obronne w Judzie.
Rehoboamu ń gbe ní Jerusalẹmu ó sì kọ́ àwọn ìlú fún olódi ní Juda.
6 I zbudował Betlehem, i Etam i Tekue;
Bẹtilẹhẹmu, Etamu, Tekoa,
7 I Betsur, i Soko, i Adullam:
Beti-Suri, Soko, Adullamu,
8 I Get, i Maresa, i Zyf:
Gati, Meraṣa Sifi,
9 I Adoraim, i Lachis, i Aseka;
Adoraimu, Lakiṣi, Aseka
10 I Sora, i Ajalon, i Hebron, które były w Judzie i w pokoleniu Benjaminowem miasta obronne.
Sora, Aijaloni, àti Hebroni. Wọ̀nyí ni àwọn ìlú ìdáàbòbò ní Juda àti Benjamini.
11 A gdy zmocnił one twierdze, postanowił w nich starostów, i wystawił szpichlerze dla zboża, i dla oliwy, i dla wina.
Ó sì mú àwọn ìlú olódi lágbára, ó sì fi àwọn balógun sínú wọn àti àkójọ oúnjẹ, àti òróró àti ọtí wáìnì.
12 A w każdem mieście złożył tarcze i włócznie, a opatrzył je bardzo mocno: a tak panował nad Judą i Benjaminem.
Àti ní olúkúlùkù ìlú ni ó fi asà àti ọ̀kọ̀ sí, ó sì mú wọn lágbára gidigidi, ó sì ní Juda àti Benjamini lábẹ́ rẹ̀.
13 Kapłani też i Lewitowie, którzy byli we wszystkim Izraelu, zebrali się do niego ze wszystkich granic swoich.
Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi, láti gbogbo ẹ̀yà wọn jákèjádò Israẹli wà ní ẹ̀bá rẹ̀.
14 Bo opuściwszy Lewitowie przedmieścia swoje, i osiadłości swoje, szli do Judy i do Jeruzalemu; (gdyż był ich wyrzucił Jeroboam i synowie jego, aby nie odprawowali urzędu kapłańskiego Panu.
Àwọn ará Lefi fi ìgbèríko sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Juda àti Jerusalẹmu nítorí Jeroboamu àti àwọn ọmọ rẹ̀, ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà Olúwa.
15 I postanowił sobie kapłanów po wyżynach, i dyjabłom, i cielcom, których był naczynił.)
Ó sì yan àwọn àlùfáà tirẹ̀ fún àwọn ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, àti fún àwọn ère òbúkọ, àti fún ẹgbọrọ màlúù tí ó ṣe.
16 A za nimi ze wszystkich pokoleń Izraelskich, którzy obrócili serca swe ku szukaniu Pana, Boga Izraelskiego, przyszli do Jeruzalemu, aby ofiarowali Panu, Bogu ojców swoich.
Àwọn tó wá láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli tí wọ́n fi ọkàn wọn fún wíwá Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tẹ̀lé àwọn ará Lefi lọ sí Jerusalẹmu láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run baba a wọn.
17 A tak umocnili królestwo Judzkie, i utwierdzili Roboama, syna Salomonowego, przez trzy lata; albowiem chodzili drogą Dawida i Salomona przez one trzy lata.
Ó fún ìjọba Juda ní agbára, ó sì ti Rehoboamu ọmọ Solomoni lẹ́yìn fún ọdún mẹ́ta nítorí ọdún mẹ́ta ni wọ́n fi rìn ní ọ̀nà ti Dafidi àti Solomoni ní àkókò yí.
18 Potem pojął sobie Roboam za żonę Mahalatę córkę Jerymota, syna Dawidowego, i Abihailę, córkę Elijaba, syna Isajego.
Rehoboamu fẹ́ Mahalati tí ó jẹ́ ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Dafidi Jerimoti bi àti ti Abihaili, ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Jese Eliabu bí.
19 Która mu urodziła synów: Jehusa, i Semaryjasza, i Zaama.
Ó bí àwọn ọmọ fún un: Jeuṣi, Ṣemariah àti Sahamu.
20 A po niej pojął Maachę, córkę Absalomową, która mu urodziła Abijasza, i Etaja, i Sysę, i Salomitę.
Nígbà náà, ó fẹ́ Maaka ọmọbìnrin Absalomu, tí ó bí Abijah fún Attai, Sisa àti Ṣelomiti.
21 I miłował Roboam Maachę, córkę Absalomową, nad wszystkie żony swoje, i nad założnice swoje. Albowiem pojął był żon ośmnaście, a założnic sześćdziesiąt, i spłodził dwadzieścia i ośm synów i sześćdziesiąt córek.
Rehoboamu fẹ́ràn Maaka ọmọbìnrin Absalomu ju èyíkéyìí nínú àwọn ìyàwó rẹ̀ àti àwọn àlè rẹ̀ lọ. Ní gbogbo rẹ̀, ó ní ìyàwó méjìdínlógún àti ọgọ́ta àlè ọmọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n àti ọgọ́ta ọmọbìnrin.
22 I postanowił Roboam Abijasza, syna Maachy, za księcia, za hetmana między braćmi jego; albowiem zamyślał go uczynić królem.
Rehoboamu yan Abijah ọmọ Maaka láti jẹ́ olóyè ọmọ-aládé láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, kí ó ba à lè ṣe é ní ọba.
23 A roztropnie sobie postępując, rozsadził wszystkich innych synów swych po wszystkich krainach Judzkich i Benjaminowych, po wszystkich miastach obronnych, i opatrzył ich dostatkiem żywności, i nadał im wiele żon.
Ó hùwà ọlọ́gbọ́n, nípa fí fọ́n díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ jákèjádò ká àwọn agbègbè Juda àti Benjamini àti sí gbogbo àwọn ìlú ńlá olódi. Ó fún wọn ní ọ̀pọ̀ ohun tí wọ́n fẹ́, ó sì fẹ́ ọ̀pọ̀ ìyàwó fún wọn.

< II Kronik 11 >