< I Samuela 14 >

1 I stało się dnia niektórego, że rzekł Jonatan, syn Saula, do sługi, który nosił broń jego: Pójdź, przejdziemy do straży Filistyńskiej, która jest na onej stronie; a ojcu swemu o tem nie oznajmił.
Ní ọjọ́ kan, Jonatani ọmọ Saulu wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìlú olódi àwọn Filistini tí ó wà ní ìhà kejì.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún baba rẹ̀.
2 Ale Saul został był przy pagórku pod jabłonią granatową, która była w Migron, i lud, który był z nim, około sześciu set mężów.
Saulu sì dúró ní ìhà etí ìpínlẹ̀ Gibeah lábẹ́ igi pomegiranate èyí tí ó wà ní Migroni. Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
3 A Achijas, syn Achitoba, brata Ichaboda, syna Fineesowego, syna Heli, kapłana Pańskiego w Sylo, nosił Efod: a lud nie wiedział, iż odszedł Jonatan.
lára wọn ni Ahijah, tí ó wọ efodu. Òun ni ọmọ arákùnrin Ikabodu Ahitubu, ọmọ Finehasi, ọmọ Eli, àlùfáà Olúwa ní Ṣilo kò sí ẹni tí ó mọ̀ pé Jonatani ti lọ.
4 Ale między przechodami, kędy szukał Jonatan przejścia ku straży Filistyńskiej, była skała ostra po jednej stronie, także skała ostra po drugiej stronie; jednej imię Boses a drugiej Sene.
Ní ọ̀nà tí Jonatani ti ń fẹ́ láti kọjá dé ìlú olódi àwọn Filistini, ní bèbè òkúta mímú kan wá, orúkọ èkínní sì ń jẹ́ Bosesi, orúkọ èkejì sì ń jẹ́ Sene.
5 Skała jedna była na północy przeciwko Machmas, a druga na południe przeciwko Gabaa.
Bèbè òkúta kan dúró sí àríwá ní ìhà Mikmasi, èkejì sì wà ní gúúsù ní ìhà Gibeah.
6 I rzekł Jonatan do wyrostka, który nosił broń jego: Pójdźmy, a przejdziemy do straży tych nieobrzezańców, snać uczyni Pan przez nas wybawienie; boć nie trudno Panu wybawić w wielu albo w trosze.
Jonatani sì wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ìlú olódi àwọn aláìkọlà yìí. Bóyá Olúwa yóò jà fún wa, kò sí ohun tó lè di Olúwa lọ́wọ́ láti gbàlà, yálà nípasẹ̀ púpọ̀ tàbí nípasẹ̀ díẹ̀.”
7 I rzekł mu sługa, noszący broń jego: Czyń, co się podoba sercu twemu; idź, gdzie chcesz, oto ja będę z tobą według woli twojej.
Ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì wí pé, “Ṣe gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ, tẹ̀síwájú, Èmi wà pẹ̀lú ọkàn àti ẹ̀mí rẹ.”
8 Tedy rzekł Jonatan: oto my idziemy do tych mężów, a ukażemy się im.
Jonatani sì wí pé, “Wá nígbà náà, àwa yóò rékọjá sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin wọ̀nyí, kí a sì jẹ́ kí wọ́n rí wa.
9 Jeźli nam tak rzeką: Czekajcie, aż przyjdziemy do was, stójmyż na miejscu swem, a nie chodźmy do nich;
Bí wọ́n bá sọ fún wa pé, ‘Ẹ dúró títí àwa yóò fi tọ̀ yín wá,’ àwa yóò dúró sí ibi tí a wà, àwa kì yóò sì gòkè tọ̀ wọ́n lọ.
10 Ale jeźliż tak rzeką: Pójdźcie do nas, pójdźmyż; boć je dał Pan w ręce nasze, a to będziemy mieli za znak.
Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá wí pé, ‘Ẹ gòkè tọ̀ wá wá,’ àwa yóò gòkè lọ, nítorí èyí ni yóò jẹ́ àmì fún wa pé Olúwa ti fi wọ́n lé wa lọ́wọ́.”
11 Ukazali się tedy obaj straży Filistyńskiej. I rzekli Filistynowie: Onoż Hebrejczycy wychodzą z jaskini, w której się byli pokryli.
Báyìí ní àwọn méjèèjì sì fi ara wọn hàn fún ìlú olódi Filistini. Àwọn Filistini sì wí pé, “Wò ó! Àwọn Heberu ń yọ jáde wá láti inú ihò tí wọ́n fi ara wọn pamọ́ sí.”
12 I mówili mężowie, co na straży byli, do Jonatana, i do wyrostka, co za nim broń nosił, i rzekli: Pójdźcie ku nam, a oznajmiemy wam coś. I rzekł Jonatan do sługi swego: Pójdź za mną; boć je Pan podał w ręce Izraelczykom.
Àwọn ọkùnrin ìlú olódi náà sì kígbe sí Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Ẹ gòkè tọ̀ wá wá àwa yóò sì kọ́ ọ yín ní ẹ̀kọ́.” Jonatani sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Gòkè tọ̀ mí lẹ́yìn; Olúwa ti fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́.”
13 Lazł tedy Jonatan na rękach swych, i na nogach swych, a wyrostek jego za nim; i padli przed Jonatanem, i przed wyrostkiem jego, który też zabijał, idąc za nim.
Jonatani lo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ láti fà gòkè pẹ̀lú ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àwọn Filistini sì ṣubú níwájú Jonatani ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì tẹ̀lé e, ó sì ń pa lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
14 A tać była porażka pierwsza, w której pobił Jonatan i wyrostek jego, co broń za nim nosił, około dwudziestu mężów, jakoby na pół staja roli.
Ní ìkọlù èkínní yìí, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì pa ogún ọkùnrin ní agbègbè tó tó ìwọ̀n ààbọ̀ sáré ilẹ̀.
15 I przyszedł strach na obóz na polu, i na wszystek lud; straż też, i ci którzy byli wyjechali na zdobycz, lękali się, aż się ziemia trzęsła; bo była w strachu Bożym.
Nígbà náà ni ìbẹ̀rùbojo bá àwọn ọmọ-ogun; àwọn tí ó wà ní ibùdó àti ní pápá, àti àwọn tí ó wà ní ilé ìlú olódi àti àwọn tí ń kó ìkógun, ilẹ̀ sì mì. Ó jẹ́ ìbẹ̀rù tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
16 I obaczyła straż Saulowa w Gabaa Benjaminowym, że się ono mnóstwo rozsypało, i pierzchło, i że się go urywało.
Àwọn tí ó ń ṣọ́nà fún Saulu ní Gibeah ti Benjamini sì rí àwọn ọmọ-ogun ń túká ní gbogbo ọ̀nà.
17 Tedy rzekł Saul do ludu, który przy nim był: Wywiedzcie się zaraz, a obaczcie, kto odszedł z naszych; a gdy się wywiadowali, oto nie było Jonatana, i wyrostka, co za nim broń nosił.
Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ ka àwọn ènìyàn kí ẹ sì mọ ẹni tí ó jáde kúrò nínú wa.” Nígbà tí wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, sì wò ó, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ni kò sì sí níbẹ̀.
18 I rzekł Saul do Achijasa: Przystaw skrzynię Bożą; (bo była skrzynia Boża dnia onego z syny Izraelskimi.)
Saulu sì wí fún Ahijah pé, “Gbé àpótí Ọlọ́run wá.” Àpótí Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní ìgbà náà.
19 I stało się, gdy jeszcze Saul mówił do kapłana, że zamięszanie, które było w obozie Filistyńskim, wzmagało się i rozmnażało; przetoż rzekł Saul do kapłana: Zawściągnij ręki twojej.
Nígbà tí Saulu sì ń bá àlùfáà sọ̀rọ̀, ariwo ní ibùdó àwọn Filistini sì ń pọ̀ síwájú sí. Saulu sì wí fún àlùfáà pé, “Dá ọwọ́ rẹ dúró.”
20 A tak zebrawszy się Saul, i wszystek lud, który był z nim, przyszli, gdzie była bitwa, a oto, każdego miecz był obrócony na towarzysza jego, i była porażka bardzo wielka.
Saulu àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ sì péjọ, wọ́n sì lọ sí ojú ìjà. Wọ́n sì bá gbogbo àwọn Filistini ní ìdàrúdàpọ̀ ńlá, idà olúkúlùkù sì wà lára ọmọ ẹnìkejì rẹ̀.
21 A Hebrejczycy, którzy przedtem przestawali z Filistynami, którzy z nimi ciągnęli w obozie tam i sam, ci się też obróciwszy stanęli przy Izraelu, który był z Saulem i z Jonatanem.
Àwọn Heberu tí ó ti wà lọ́dọ̀ àwọn Filistini tẹ́lẹ̀, tí wọ́n sì ti gòkè tẹ̀lé wọn lọ sí àgọ́ wọn wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n ti wà pẹ̀lú Saulu àti Jonatani.
22 Nadto wszyscy mężowie Izraelscy, którzy się byli pokryli na górze Efraim, gdy usłyszeli, iż uciekają Filistynowie, szli za nimi w pogoń w onej bitwie.
Nígbà tí gbogbo àwọn Israẹli tí ó ti pa ara wọn mọ́ nínú òkè ńlá Efraimu gbọ́ pé àwọn Filistini sá, wọ́n darapọ̀ mọ́ ìjà náà ní ìlépa gbígbóná.
23 I wybawił Pan dnia onego Izraela, a bitwa ona zaszła aż do Betawen.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì gba Israẹli ní ọjọ́ náà, ìjà náà sì rékọjá sí Beti-Afeni.
24 A mężowie Izraelscy strudzeni byli onego dnia. I poprzysiągł Saul lud, mówiąc: Przeklęty mąż, któryby jadł chleb przed wieczorem, aż się pomszczę nad nieprzyjacioły mymi. I nie skosztował wszystek lud chleba.
Gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wà ní ìpọ́njú ńlá ní ọjọ́ náà, nítorí pé Saulu ti fi àwọn ènìyàn gégùn ún wí pé, “Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ títí di alẹ́, títí èmi yóò fi gbẹ̀san mi lára àwọn ọ̀tá mi!” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkankan nínú ọ̀wọ́ ogun náà tí ó fi ẹnu kan oúnjẹ.
25 Tedy wszystek lud onej ziemi przyszedł do lasu, gdzie było wiele miodu na ziemi.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì wọ inú igbó, oyin sì wà lórí ilẹ̀ náà.
26 Wszedłszy tedy lud do lasu, ujrzał płynący miód; wszakże nie doniósł żaden z miodem ręki swojej do ust swoich, bo się bał lud onej przysięgi.
Nígbà tí wọ́n dé inú igbó náà, wọ́n sì rí oyin ń sun jáde, kò sí ẹni tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ kan ẹnu rẹ̀ síbẹ̀, nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìfiré.
27 Ale Jonatan nie słyszał, gdy poprzysięgał lud ojciec jego; i ściągnął koniec laski, którą miał w ręce swej, a omoczył go w plastrze miodu, i obrócił rękę swoję do ust swoich, i oświeciły się oczy jego.
Ṣùgbọ́n Jonatani kò gbọ́ pé baba rẹ̀ ti fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn náà, bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ orí ọ̀pá tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀ bọ afárá oyin náà, ó sì fi sí ẹnu rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dán.
28 A odpowiadając jeden z ludu, rzekł: Przysięgą zawiązał ojciec twój lud, mówiąc: Przeklęty mąż, któryby jadł chleb dzisiaj; stądże ustał lud.
Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ogun sọ fún un pé, “Baba rẹ fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ ní òní!’ Ìdí nìyìí tí àárẹ̀ fi mú àwọn ènìyàn.”
29 Tedy rzekł Jonatan: Strwożył ojciec mój lud ziemi. Patrzcie proszę jako są oświecone oczy moje, iżem skosztował trochę miodu tego;
Jonatani sì wí pé, “Baba mi ti mú ìdààmú bá ìlú, wò ó bí ojú mi ti dán nígbà tí mo fi ẹnu kan oyin yìí.
30 Jako daleko więcej, gdyby się był najadł dziś lud z łupu nieprzyjaciół swoich, których nabył; izaliby nie była większa porażka między Filistynami?
Báwo ni kò bá ti dára tó bí àwọn ènìyàn bá ti jẹ nínú ìkógun àwọn ọ̀tá wọn lónìí, pípa àwọn Filistini ìbá ti pọ̀ tó?”
31 Porazili tedy dnia onego Filistyny od Machmas aż do Ajalon, i spracował się lud bardzo.
Ní ọjọ́ náà, lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ọmọ Israẹli ti pa nínú àwọn Filistini láti Mikmasi dé Aijaloni, ó sì rẹ àwọn ènìyàn náà.
32 Tedy się lud udał na łup, a nabrawszy owiec, i wołów, i cieląt, rzezali je na ziemi, a jadł lud ze krwią.
Wọ́n sáré sí ìkógun náà, wọ́n sì mú àgùntàn. Màlúù àti ọmọ màlúù, wọ́n pa wọ́n sórí ilẹ̀, wọ́n sì jẹ wọ́n papọ̀ tẹ̀jẹ́tẹ̀jẹ̀.
33 I powiedziano Saulowi mówiąc: Oto lud grzeszy przeciw Panu, jedząc ze krwią; który rzekł: Zgrzeszyliście; przytoczcież sam do mnie teraz kamień wielki.
Nígbà náà ni ẹnìkan sì wí fún Saulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn tí ń dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa jíjẹ ẹran tí ó ní ẹ̀jẹ̀ lára.” Ó sì wí pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ yín ti pọ̀jù, yí òkúta ńlá sí ibi nísinsin yìí.”
34 Zatem rzekł Saul: Rozejdźcie się między lud, a rzeczcie do nich: Przywiedźcie do mnie każdy wołu swego, i każdy owcę swą, bijcież je tu, a jedzcie, a nie zgrzeszycie przeciw Panu, jedząc ze krwią. I przywiedli wszystek lud, każdy wołu swego w ręce swej w nocy, i bito je tam.
Nígbà náà ni ó wí pé, “Ẹ jáde lọ sáàrín àwọn ènìyàn náà kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Kí olúkúlùkù wọn mú màlúù àti àgùntàn tirẹ̀ tọ̀ mí wá, kí wọ́n sì pa wọ́n níhìn-ín, kí wọ́n sì jẹ́. Ẹ má ṣe ṣẹ̀ sí Olúwa, kí ẹ má ṣe jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ní olúkúlùkù mú màlúù tirẹ̀ wá ní alẹ́ ọjọ́ náà, wọ́n sì pa wọ́n níbẹ̀.
35 I zbudował Saul ołtarz Panu; toć najpierwszy ołtarz, który zbudował Panu.
Nígbà náà Saulu kọ́ pẹpẹ kan fún Olúwa; èyí sì jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ ṣe èyí.
36 I rzekł Saul: Puśćmy się za Filistynami nocą, a bijmy je aż do świtania, a nie zostawujmy z nich i jednego. Którzy mu odpowiedzieli: Cokolwiek dobrego jest w oczach twoich uczyń, ale kapłan rzekł: Przystąpmy sam do Boga.
Saulu sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ tọ Filistini lọ ní òru, kí a bá wọn jà títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, kí a má ṣì ṣe dá ẹnìkankan sí nínú wọn.” Wọ́n sì wí pé, “Ṣe ohun tí ó bá dára ní ojú rẹ̀.” Ṣùgbọ́n àlùfáà wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Ọlọ́run níhìn-ín.”
37 Tedy się radził Saul Boga: Mamli się puścić za Filistynami? podaszli je w ręce Izraela? I nie odpowiedział mu dnia tego.
Nígbà náà ni Saulu béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run pé, “Ṣé kí n sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn Filistini lọ bí? Ǹjẹ́ ìwọ yóò fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́ bí?” Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dá a lóhùn ní ọjọ́ náà.
38 Przetoż rzekł Saul: Przystąpcie sam wszyscy celniejsi z ludu, i wywiedzcie się, a patrzcie, przy kimby grzech dziś był.
Saulu sì wí pé, “Ẹ wá síyìn-ín ín, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olórí ogun, kí a ṣe ìwádìí irú ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ ti ṣẹ̀ lónìí.
39 Bo jako żywy Pan, który wybawia Izraela, choćby był i przy Jonatanie, synu moim, że śmiercią umrze. I nie odpowiedział mu nikt ze wszystkiego ludu.
Bí Olúwa tí ó gba Israẹli là ti wà, bí ó bá ṣe pé a rí í lára Jonatani ọmọ mi, ó ní láti kú.” Ṣùgbọ́n ẹnìkankan nínú wọn kò sọ ọ̀rọ̀ kan.
40 Nadto rzekł do wszystkiego Izraela: Wy będziecie na jednej stronie, a ja i Jonatan, syn mój, będziemy na drugiej stronie. I odpowiedział lud Saulowi: Co dobrego jest w oczach twoich, uczyń.
Nígbà náà ni Saulu wí fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ lọ sí apá kan; èmi àti Jonatani ọmọ mi yóò lọ sí apá kan.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú rẹ.”
41 Zatem rzekł Saul do Pana, Boga Izraelskiego: Panie, pokaż sprawiedliwą; i nalezion jest Jonatan i Saul, a lud wyszedł z tego.
Nígbà náà ni Saulu gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli pé, “Fún mi ní ìdáhùn tí ó tọ́.” A sì mú Jonatani àti Saulu nípa ìbò dídì, àwọn ènìyàn náà sì yege.
42 Potem rzekł Saul: Rzućcie los między mną i między Jonatanem, synem moim; i znaleźony jest Jonatan.
Saulu sì wí pé, “Ẹ dìbò láàrín èmi àti Jonatani ọmọ mi.” Ìbò náà sì mú Jonatani.
43 Zatem rzekł Saul do Jonatana: Powiedz mi, coś uczynił? I powiedzał mu Jonatan, i rzekł: Skosztowałem tylko końcem laski, którąm miał w ręce mojej, trochę miodu, i dla tegoż ja mam umrzeć?
Saulu sì wí fún Jonatani pé, “Sọ nǹkan tí ìwọ ṣe fún mi.” Jonatani sì sọ fún un pé, “Mo kàn fi orí ọ̀pá mi tọ́ oyin díẹ̀ wò. Nísinsin yìí ṣé mo ní láti kú?”
44 I odpowiedzał Saul: To a to mi niech Bóg uczyni, że śmiercią umrzesz Jonatanie.
Saulu sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí mi, nítorí pé ìwọ Jonatani yóò sá à kú dandan.”
45 Ale lud rzekł do Saula: Izali Jonatan umrze, który uczynił to wybawienie wielkie w Izraelu? Boże uchowaj! jako żywy Pan, nie spadnie i włos z głowy jego na ziemię; albowiem za pomocą Bożą uczynił to dzisiaj. A tak wybawił lud Jonatana, że nie umarł.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wí fún Saulu pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí Jonatani kú, ẹni tí ó ti mú ìgbàlà ńlá yìí wá fún Israẹli? Kí a má rí í! Bí Olúwa ti wà, ọ̀kan nínú irun orí rẹ̀ kì yóò bọ́ sílẹ̀, nítorí tí ó ṣe èyí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́.” Báyìí ni àwọn ènìyàn gba Jonatani sílẹ̀, kò sì kú.
46 Tedy się wrócił Saul od Filistynów, a Filistynowie odeszli na miejsce swoje.
Nígbà náà ni Saulu sì dẹ́kun lílépa àwọn Filistini, àwọn Filistini sì padà sí ìlú wọn.
47 A Saul otrzymawszy królestwo nad Izraelem, walczył przeciwko okolicznym wszystkim nieprzyjaciołom swoim, przeciw Moabitom, i przeciw synom Ammonowym, i przeciw Edomczykom, i przeciw królom Soba, i przeciw Filistynom; a gdzie się kolwiek obrócił, mężnie się sprawował.
Lẹ́yìn ìgbà tí Saulu ti jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì bá gbogbo ọ̀tá wọn jà yíká: Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni; Edomu, àti àwọn ọba Soba, àti àwọn Filistini. Ibikíbi tí ó bá kọjú sí, ó máa ń fi ìyà jẹ wọ́n.
48 Zebrawszy też wojsko, poraził Amalekity, i wyrwał Izraela z ręki tego, który go pustoszył.
Ó sì jà tagbára tagbára, ó ṣẹ́gun àwọn Amaleki, ó sì ń gba Israẹli sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ń kọlù wọ́n.
49 A miał Saul syny Jonatana, i Jesujego, i Melchisua, a imiona dwóch córek jego: imię pierworodnej Merob, a młodszej Michol;
Àwọn ọmọ Saulu sì ni Jonatani, Iṣifi àti Malikiṣua. Orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ àgbà sì ni Merabu àti orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ni Mikali.
50 A imię żony Saulowej Achinoam, która była córką Achimaasową; a imię Hetmana wojska jego Abner, syn Nera, stryja Saulowego.
Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ní Ahinoamu ọmọbìnrin Ahimasi. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Abneri ọmọ Neri arákùnrin baba Saulu.
51 Bo Cys był ojciec Saula, a Ner ojciec Abnera, syn Abijela.
Kiṣi baba Saulu àti Neri baba Abneri wọ́n sì jẹ́ ọmọ Abieli.
52 I była wojna wielka z Filistynami po wszystkie dni Saulowe. Przetoż, gdziekolwiek widział Saul jakiego silnego i dzielnego męża, przyjmował go do siebie.
Ní gbogbo ọjọ́ Saulu, ogun náà sì gbóná sí àwọn Filistini, níbikíbi tí Saulu bá sì ti rí alágbára tàbí akíkanjú ọkùnrin, a sì mú u láti máa bá a ṣiṣẹ́.

< I Samuela 14 >