< I Królewska 3 >

1 I spowinowacił się Salomon z Faraonem, królem Egipskim; bo pojął córkę Faraonową, i przyprowadził ją do miasta Dawidowego, ażby dobudował domu swego, i domu Pańskiego, i muru Jeruzalemskiego w około.
Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
2 Wszakże lud ofiarował po górach, przeto, że nie był jeszcze zbudowany dom imieniowi Pańskiemu aż do onych dni.
Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
3 I miłował Salomon Pana, chodząc w przykazaniach Dawida, ojca swego; tylko że na górach ofiarował i kadził.
Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
4 Szedł tedy król do Gabaon, aby tam ofiarował; bo tam była góra największa; tysiąc ofiar całopalonych ofiarował Salomon na onym ołtarzu.
Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
5 I ukazał się Pan w Gabaon Salomonowi przez sen w nocy, i rzekł Bóg: Proś czego chcesz, a dam ci.
Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
6 Tedy rzekł Salomon: Tyś uczynił z sługą twoim Dawidem, ojcem moim, miłosierdzie wielkie, gdyż chodził przed tobą w prawdzie i w sprawiedliwości, i w prostości serca stał przy tobie; i zachowałeś mu to miłosierdzie wielkie, iżeś mu dał syna, który by siedział na stolicy jego, jako się to dziś okazuje.
Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
7 A teraz, o Panie Boże mój, tyś postanowił królem sługę twego miasto Dawida, ojca mego, a jam jest dziecię małe, i nie umiem wychodzić ani wchodzić.
“Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
8 A sługa twój jest w pośrodku ludu twego, któryś obrał, ludu wielkiego, który nie może zliczony ani porachowany być przez mnóstwo.
Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
9 Przetoż daj słudze twemu serce rozumne, aby sądził lud twój, i aby rozeznawał między dobrem i złem; albowiem któż może sądzić ten lud twój tak wielki?
Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
10 I podobało się to Panu, że żądał Salomon tej rzeczy.
Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
11 Tedy rzekł Bóg do niego: Dla tego, żeś o to prosił, a nieżądałeś sobie długich dni, aniś żądał sobie bogactw, aniś prosił o wytracenie nieprzyjaciół twoich, aleś sobie prosił o rozum dla rozeznania sądu:
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
12 Otożem uczynił według słów twoich; otom ci dał serce mądre i rozumne, tak, iż żaden równy tobie nie był przed tobą, ani po tobie powstanie równy tobie.
èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
13 Do tego i to, czegoś nie żądał, dałem ci, to jest bogactwa i sławę, tak aby nie było żadnego tobie równego między królmi po wszystkie dni twoje.
Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
14 A będzieszli chodził drogami mojemi, strzegąc wyroków moich, i rozkazania mego, jako chodził Dawid, ojciec twój, tedy przedłużę dni twoje.
Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
15 A gdy się ocucił Salomon, zrozumiał, że to był sen. I przyszedł do Jeruzalemu, a stanąwszy przed skrzynią przymierza Pańskiego, sprawował całopalenia, i ofiarował ofiary spokojne, sprawił też ucztę na wszystkie sługi swoje.
Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
16 Tedy przyszły dwie niewiasty wszetecznice do króla, i stanęły przed nim.
Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
17 I rzekła jedna z onych niewiast: Proszę panie mój, ja i ta niewiasta mieszkamy w jednym domu, i porodziłam u niej w tymże domu.
Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
18 I stało się dnia trzeciego po porodzeniu mojem, że porodziła i ta niewiasta; i byłyśmy pospołu, a nie było nikogo obcego z nami w domu, oprócz nas dwóch w tymże domu.
Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
19 I umarł syn tej niewiasty w nocy, przeto, iż go była przyległa.
“Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
20 A wstawszy o północy, wzięła syna mego odemnie, gdy służebnica twoja spała, i położyła go na łonie swojem, a syna swego umarłego położyła na łonie mojem.
Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
21 A gdym wstała rano, chcąc dać ssać synowi memu, otom znalazła umarłego; któremu gdym się rano przypatrzyła, a oto nie był syn mój, któregom porodziła.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
22 I rzekła ona druga niewiasta: Nie tak; ale syn mój jest ten żywy, a syn twój ten umarły. Ale ona rzekła: Nie; ale syn twój jest ten umarły, a syn mój ten żywy. I tak się spierały przed królem.
Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
23 I rzekł król: Ta mówi: Ten żywy jest syn mój, a syn twój ten umarły; a ta zasię mówi: Nie tak; ale syn twój ten umarły, a syn mój ten żywy.
Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
24 Przetoż rzekł król: Przynieście mi miecz. I przyniesiono miecz przed króla.
Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
25 Tedy rzekł król: Rozetnijcie to żywe dziecię na dwoje, a dajcie połowę jednej, a połowę drugiej.
Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
26 Ale niewiasta, której był ten syn żywy, mówiła do króla, (bo się były poruszyły wnętrzności jej nad synem jej, ) i rzekła: Proszę, panie mój, dajcie jej to dziecię żywe, a żadnym sposobem nie zabijajcie go. Ale druga rzekła: Niech nie będzie ani mnie, ani tobie, rozetnijcie je.
Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
27 Tedy odpowiedział król, i rzekł: Dajcież tej dziecię żywe, a żadną miarą nie zabijajcie go; tać jest matka jego.
Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
28 A usłyszawszy wszystek lud Izraelski ten sąd, który osądził król, bali się króla: albowiem wiedzieli, że mądrość Boża była w sercu jego ku czynieniu sądu.
Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.

< I Królewska 3 >