< I Królewska 21 >

1 I stało się potem: Miał Nabot Jezreelita winnicę, która była w Jezreelu podle pałacu Achaba, króla w Samaryi.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
2 I rzekł Achab do Nabota, mówiąc: Daj mi winnicę twoję, abym miał z niej ogród dla jarzyn, albowiem bliska jest domu mego; a dam ci za nię winnicę lepszą, niżli ta jest; albo jeźlić się zda, dam ci pieniędzy, ile stoi.
Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
3 I odpowiedzał Nabot Achabowi: Nie daj tego Panie, abym ci miał dać dziedzictwo ojców moich.
Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
4 Tedy przyszedł Achab do domu swego smutny i zagniewany dla słowa, które mu rzekł Nabot Jezreelita, mówiąc: Nie dam ci dziedzictwa ojców moich; i układł się na łożu swem, a odwrócił twarz swoję, i nie jadł chleba.
Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
5 Wtem przyszedłszy do niego Jezabela, żona jego, rzekła mu: Przedże duch twój tak smutny, że nie jesz chleba?
Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
6 I odpowiedział jej: Przeto żem mówił z Nabotem Jezreelitą, i rzekłem mu: Daj mi winnicę twoję za pieniądze, albo jeźli chcesz, dam ci winnicę za nię; ale on odpowiedział: Nie dam ci winnicy mojej.
Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
7 Tedy rzekła do niego Jezabela, żona jego: I także ty sprawujesz królestwo Izraelskie? Wstań, jedz chleb, a bądź dobrej myśli; ja tobie dam winnicę Nabota Jezeelity.
Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
8 A tak napisała list imieniem Achabowem, który zapieczętowała pieczęcią jego, i posłała on list do starszych i do przedniejszych, którzy byli w mieście jego, i mieszkali z Nabotem.
Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
9 A napisała on list w ten sposób: Zapowiedźcie post, a posadźcie Nabota między przedniejszymi z ludu;
Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
10 I postawcie dwóch mężów przewrotnych przeciw niemu, którzyby przeciwko niemu świadczyli, mówiąc: Złożeczyłeś Bogu i królowi; potem wywiedźcie go, a ukamionujcie go, aby umarł.
Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
11 I uczynili mężowie onego miasta starsi i przedniejsi, którzy mieszkali w onem mieście jego, jako była wskazała do nich Jezabela, według tego, jako napisano było w liście, który posłała do nich.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
12 Zapowiedzieli post, i posadzili Nabota między przedniejszymi z ludu.
Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
13 Potem przyszli dwaj mężowie przewrotni, i usiedli przeciw niemu, a świadczyli przeciwko niemu oni mężowie przewrotni, to jest przeciw Nabotowi przed ludem, mówiąc: Złożeczył Nabot Bogu i królowi. I wywiedli go za miasto, i ukamionowali go, i umarł.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
14 I posłali do Jezabeli, mówiąc: Ukamionowan jest Nabot, i umarł.
Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
15 I stało się, gdy usłyszała Jezabela, że ukamionowany był Nabot, a iż umarł, rzekła Jezabela do Achaba: Wstań, posiądź winnicę Nabota Jezreelity, któryć jej nie chciał dać za pieniądze; albowiem nie żyje Nabot, ale umarł.
Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
16 A tak usłyszawszy Achab, że umarł Nabot, wstał, a szedł do winnicy Nabota Jezreelity, aby ją posiadł.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
17 Tedy się stało słowo Pańskie do Elijasza Tasbity, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
18 Wstań, idź przeciw Achabowi, królowi Izraelskiemu, który jest w Samaryi; oto jest na winnicy Nabotowej, do której szedł, aby ją posiadł.
“Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
19 I rzeczesz do niego, mówiąc: Tak mówi Pan: Azaś nie zabił i nie posiadł? Powiedzże mu, mówiąc: Tak mówi Pan: Tak jako psy lizali krew Nabotowę, tak też pewnie psy będą lizać krew twoję.
Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
20 I rzekł Achab do Elijasza: A jużeś mię znalazł nieprzyjacielu mój? A on odpowiedział: Znalazłem; albowiemeś się zaprzedał, abyś czynił złość przed oczyma Pańskiemi.
Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
21 Oto Ja przywiodę na cię złe, a odejmę potomki twe, i wytracę z domu Achabowego, aż do najmniejszego szczenięcia, i więźnia, i opuszczonego w Izraelu.
‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
22 A uczynię z domem twoim, jako z domem Jeroboama, syna Nabatowego, i jako z domem Baazy, syna Ahyjaszowego, dla rozdraźnienia, któremeś mię do gniewu pobudził, i przywiodłeś do grzechu Izraela.
Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
23 Także i o Jezabeli rzekł Pan, mówiąc: Psy zjedzą Jezabelę między murami Jezreelskimi.
“Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
24 Tego, który umrze z domu Achabowego w mieście, psy zjedzą, a tego, który umrze na polu, zjedzą ptaki powietrzne.
“Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
25 Albowiem nie był nikt jako Achab, któryby siebie samego zaprzedał, aby czynił złe przed oczyma Pańskiemi; bo go poduszczała Jezabela, żona jego.
(Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
26 Albowiem się dopuścił rzeczy bardzo obrzydłych, chodząc za bałwanami według wszystkiego, jako czynili Amorejczycy, których wygnał Pan przed obliczem synów Izraelskich.
Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
27 A gdy usłyszał Achab te słowa, rozdarł odzienie swoje, a włożywszy wór na ciało swoje, pościł i leżał w worze, a chodził po maluczku.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
28 I stało się słowo Pańskie do Elijasza Tesbity, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
29 Widziałżeś, jako się upokorzył Achab przed twarzą moją? Ponieważ się tedy upokorzył przed twarzą moją, nie przywiodę tego złego za dni jego; ale za dni syna jego przywiodę to złe na dom jego.
“Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”

< I Królewska 21 >