< I Królewska 11 >

1 Tedy król Salomon rozmiłował się niewiast obcych wiele: nie tylko córki Faraonowej, ale i Moabitczanek, Ammonitczanek, Edomczanek, Sydończanek, Hetejczanek.
Solomoni ọba fẹ́ ọ̀pọ̀ àjèjì obìnrin yàtọ̀ sí ọmọbìnrin Farao, àwọn ọmọbìnrin Moabu, àti ti Ammoni, ti Edomu, ti Sidoni àti ti àwọn ọmọ Hiti.
2 Z tych narodów, o których powiedział Pan synom Izraelskim: Nie wchodźcie do nich, i one niech nie wchodzą do was; albowiem nakłoniłyby serce wasze za bogi swymi. Do tych przylgnął Salomon miłością.
Wọ́n wá láti orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ fẹ́ wọn níyàwó tàbí ní ọkọ, nítorí wọn yóò yí ọkàn yín padà sí òrìṣà wọn.” Síbẹ̀síbẹ̀ Solomoni fàmọ́ wọn ní ìfẹ́.
3 Tak iż miał żon królowych siedm set, a założnic trzy sta; i odwróciły żony jego serce jego.
Ó sì ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin obìnrin, àwọn ọmọ ọba àti ọ̀ọ́dúnrún àlè, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà.
4 I stało się, gdy już był Salomon stary, że żony jego nakłoniły serce jego za bogi cudzymi, tak iż nie było serce jego zupełne z Panem, Bogiem jego, jako serce Dawida, ojca jego.
Bí Solomoni sì ti di arúgbó, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà sí ọlọ́run mìíràn, ọkàn rẹ̀ kò sì ṣe déédé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
5 Ale udał się Salomon za Astarotą, boginią Sydońską, i za Molochem, obrzydliwością Ammonitów.
Solomoni tọ Aṣtoreti òrìṣà àwọn ará Sidoni lẹ́yìn, àti Moleki òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ammoni.
6 I uczynił Salomon, co się nie podobało Panu, ani chodził doskonale za Panem, jako Dawid, ojciec jego.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe búburú níwájú Olúwa; kò sì tọ Olúwa lẹ́yìn ní pípé, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
7 Tedy zbudował Salomon kaplicę Chamosowi, obrzydliwości Moabskiej, na górze przeciw Jeruzalemowi i Molochowi, obrzydliwości synów Ammonowych.
Lórí òkè tí ń bẹ níwájú Jerusalẹmu, Solomoni kọ́ ibi gíga kan fún Kemoṣi, òrìṣà ìríra Moabu, àti fún Moleki, òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ammoni.
8 I tak uczynił wszystkim żonom swym cudzoziemkom, które kadziły, i ofiarowały bogom swoim.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ fún gbogbo àwọn àjèjì obìnrin rẹ̀, ẹni tí ń sun tùràrí, tí wọ́n sì ń rú ẹbọ fún òrìṣà wọn.
9 I rozgniewał się Pan na Salomona, że się odwróciło serce jego od Pana, Boga Izraelskiego, który się mu był ukazał po dwa kroć.
Olúwa bínú sí Solomoni nítorí ọkàn rẹ̀ ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó ti fi ara hàn án lẹ́ẹ̀méjì.
10 I zakazał mu tego, aby nie chodził za bogi cudzymi; wszakże nie strzegł tego, co Pan przykazał.
Bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti kìlọ̀ fún Solomoni kí ó má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn, ṣùgbọ́n Solomoni kò pa àṣẹ Olúwa mọ́.
11 Przetoż rzekł Pan do Salomona: Ponieważeś się tego dopuścił, nie strzegąc przymierza mego, ani wyroków moich, którem ci przykazał, pewnie oderwę królestwo od ciebie, a dam je słudze twojemu,
Nítorí náà Olúwa wí fún Solomoni pé, “Nítorí bí ìwọ ti ṣe nǹkan yìí, tí ìwọ kò sì pa májẹ̀mú mi àti àṣẹ mi mọ́, tí mo ti pàṣẹ fún ọ, dájúdájú èmi yóò fa ìjọba ya kúrò lọ́wọ́ rẹ, èmi yóò sì fi fún ẹlòmíràn.
12 Wszakże za dni twoich nie uczynię tego dla Dawida, ojca twego; ale z ręki syna twego oderwę je.
Ṣùgbọ́n, nítorí Dafidi baba rẹ, Èmi kì yóò ṣe é ní ọjọ́ rẹ. Èmi yóò fà á ya kúrò lọ́wọ́ ọmọ rẹ.
13 Lecz wszystkiego królestwa nie oderwę; pokolenie jedno dam synowi twemu dla Dawida, sługi mego, i dla Jeruzalemu, którem obrał.
Síbẹ̀ èmi kì yóò fa gbogbo ìjọba náà ya, ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi, àti nítorí Jerusalẹmu tí èmi ti yàn.”
14 Przetoż wzbudził Pan przeciwnika Salomonowi, Adada Edomczyka z nasienia królewskiego, który był w Edom.
Nígbà náà ni Olúwa gbé ọ̀tá kan dìde sí Solomoni, Hadadi ará Edomu ìdílé ọba ni ó ti wá ní Edomu.
15 Albowiem stało się, gdy Dawid był w Edom, a Joab, hetman wojska, wyjechał, aby pochował pobite, i pobił wszystkie mężczyzny w Edom;
Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi wà ní Edomu, Joabu olórí ogun sì gòkè lọ láti sin àwọn ọmọ-ogun Israẹli ti a pa lójú ogun, ó sì pa gbogbo ọkùnrin Edomu.
16 (Bo tam sześć miesięcy mieszkał Joab ze wszystkimi Izraelczykami, aż wytracił wszystkie mężczyzny w Edom.)
Nítorí Joabu àti gbogbo Israẹli sì dúró níbẹ̀ fún oṣù mẹ́fà, títí wọ́n fi pa gbogbo ọkùnrin Edomu run.
17 Tedy uciekł Adad sam, i niektórzy mężowie Edomscy z sług ojca jego z nim, aby szli do Egiptu; a Adad był chłopcem nie wielkim.
Ṣùgbọ́n Hadadi sálọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ará Edomu tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ baba rẹ̀. Hadadi sì wà ní ọmọdé nígbà náà.
18 Którzy wyszedłszy z Madyjan przyszli do Faran, a wziąwszy z sobą niektóre męże z Faran weszli do Egiptu, do Faraona króla Egipskiego, który mu dał dom, i żywność mu naznaczył, dał mu też i ziemię.
Wọ́n sì dìde kúrò ní Midiani, wọ́n sì lọ sí Parani. Nígbà náà ni wọ́n mú ènìyàn pẹ̀lú wọn láti Parani wá, wọ́n sì lọ sí Ejibiti, sọ́dọ̀ Farao ọba Ejibiti ẹni tí ó fún Hadadi ní ilé àti ilẹ̀, ó sì fún un ní oúnjẹ.
19 I znalazł Adad wielką łaskę w oczach Faraonowych, tak, iż mu dał za żonę siostrę żony swej, siostrę królowej Tafnes.
Inú Farao sì dùn sí Hadadi púpọ̀ tí ó fi fún un ní arábìnrin aya rẹ̀ ní aya, arábìnrin Tapenesi, ayaba.
20 I porodziła mu siostra Tafnes Gienubata, syna jego, którego odchowała Tafnes w domu Faraonowym. I był Gienubat w domu Faraonowym między syny Faraonowymi.
Arábìnrin Tapenesi bí ọmọkùnrin kan fún un tí à ń pe orúkọ rẹ̀ ní Genubati, ẹni tí Tapenesi tọ́ dàgbà ní ààfin ọba. Níbẹ̀ ni Genubati ń gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ Farao fúnra rẹ̀.
21 A gdy usłyszał Adad w Egipcie, iż zasnął Dawid z ojcy swymi, a iż umarł Joab, hetman wojska, tedy rzekł Adad do Faraona: Puść mię, że pójdę do ziemi mojej.
Nígbà tí ó sì wà ní Ejibiti, Hadadi sì gbọ́ pé Dafidi ti sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, àti pé Joabu olórí ogun sì ti kú pẹ̀lú. Nígbà náà ni Hadadi wí fún Farao pé, “Jẹ́ kí n lọ, kí èmi kí ó le padà sí ìlú mi.”
22 Któremu odpowiedział Farao: Czegoż ci niedostawa u mnie, że chcesz iść do ziemi twojej? A on rzekł: Niczego; a wszakże puść mię.
Farao sì wí fún un pé, “Kí ni ìwọ ṣe aláìní níbí, tí ìwọ fi fẹ́ padà lọ sí ìlú rẹ?” Hadadi sì wí pé, “Kò sí nǹkan, ṣùgbọ́n sá à jẹ́ kí èmi kí ó lọ!”
23 Wzbudził także Bóg nań przeciwnika, Rezona, syna Elijadowego, który był uciekł od Adarezera, króla Soby, Pana swego.
Ọlọ́run sì gbé ọ̀tá mìíràn dìde sí Solomoni, Resoni ọmọ Eliada, ẹni tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ Hadadeseri olúwa rẹ̀, ọba Soba.
24 A zebrawszy do siebie męże, był książęciem roty, gdy je Dawid mordował; przetoż odszedłszy do Damaszku, mieszkali w nim, a królowali nad Damaszkiem.
Ó sì kó ènìyàn jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, ó sì di olórí ogun ẹgbẹ́ kan, nígbà tí Dafidi fi pa ogun Soba run; wọ́n sì lọ sí Damasku, wọ́n ń gbé ibẹ̀, wọ́n sì jẹ ọba ní Damasku.
25 I był przeciwnikiem Izraelowi po wszystkie dni Salomonowe, a to oprócz szkód, które mu czynił Adad; bo się brzydził Izraelem, gdy królował w Syryi.
Resoni sì jẹ́ ọ̀tá Israẹli ní gbogbo ọjọ́ Solomoni, ó ń pa kún ibi ti Hadadi ṣe. Bẹ́ẹ̀ ni Resoni jẹ ọba ní Siria, ó sì ṣòdì sí Israẹli.
26 Jeroboam też, syn Nabata Efratejczyka z Saredy, (a imię matki jego Serwa, która była wdową, ) sługa Salomonowy, podniósł przeciwko królowi rękę.
Bákan náà Jeroboamu ọmọ Nebati sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọba. Ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ Solomoni, ará Efraimu ti Sereda, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ opó, orúkọ rẹ̀ ni Serua.
27 A tać była przyczyna, dla której podniósł rękę swą przeciwko królowi, że Salomon zbudowawszy Mello, zaprawił dziurę w mieście Dawida, ojca swego.
Èyí sì ni ìdí tí ó fi ṣọ̀tẹ̀ sí ọba: Solomoni kọ́ Millo, ó sì di ẹ̀yà ìlú Dafidi baba rẹ̀.
28 A Jeroboam był mąż mocny i możny. Przetoż widząc Salomon młodzieńca, że był sprawny, postanowił go nad podatkami wszystkiemi domu Józefowego.
Jeroboamu jẹ́ ọkùnrin alágbára, nígbà tí Solomoni sì rí bí ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ dáradára, ó fi í ṣe olórí iṣẹ́ ìrú ilé Josẹfu.
29 I stało się tegoż czasu, gdy Jeroboam wyszedł z Jeruzalemu, że go znalazł na drodze Achyjasz Sylonitczyk, prorok, będąc odziany płaszczem nowym; a tylko sami dwaj byli na polu.
Ó sì ṣe, ní àkókò náà Jeroboamu ń jáde kúrò ní Jerusalẹmu. Wòlíì Ahijah ti Ṣilo sì pàdé rẹ̀ lójú ọ̀nà, ó sì wọ agbádá tuntun. Àwọn méjèèjì nìkan ni ó sì ń bẹ ní oko,
30 Tedy wziąwszy Achyjasz płaszcz nowy, który miał na sobie, rozdarł go na dwanaście sztuk.
Ahijah sì gbá agbádá tuntun tí ó wọ̀ mú, ó sì fà á ya sí ọ̀nà méjìlá.
31 I rzekł do Jeroboama: Weźmij sobie dziesięć sztuk; bo tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Oto Ja oderwę królestwo z rąk Salomonowych, a dam tobie dziesięć pokoleń.
Nígbà náà ni ó sọ fún Jeroboamu pé, “Mú ọ̀nà mẹ́wàá fún ara rẹ, nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Wò ó, èmi yóò fa ìjọba náà ya kúrò ní ọwọ́ Solomoni, èmi yóò sì fi ẹ̀yà mẹ́wàá fún ọ.
32 Jedno tylko pokolenie zostanie mu dla sługi mego Dawida, i dla miasta Jeruzalem, którem obrał ze wszystkich pokoleń Izraelskich;
Ṣùgbọ́n nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi àti nítorí Jerusalẹmu, ìlú tí mo ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, òun yóò ní ẹ̀yà kan.
33 Przeto, że mię opuścili, a kłaniali się Astarocie, bogini Sydońskiej, i Chamosowi, bogu Moabskiemu, i Molochowi, bogu synów Ammonowych, a nie chodzili drogami mojemi, aby czynili to, co się mnie podoba, ani też strzegli wyroków moich, i sądów mo ich, jako Dawid, ojciec jego.
Èmi yóò ṣe èyí nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì ti sin Aṣtoreti òrìṣà àwọn ará Sidoni, Kemoṣi òrìṣà àwọn ará Moabu, àti Moleki òrìṣà àwọn ọmọ Ammoni, wọn kò sì rìn ní ọ̀nà mi, tàbí ṣe èyí tí ó dára lójú mi, tàbí pa àṣẹ àti òfin mi mọ́ bí Dafidi baba Solomoni ti ṣe.
34 Wszakże nie odejmę wszystkiego królestwa z ręki jego, owszem zostawię go książęciem po wszystkie dni żywota jego dla Dawida, sługi mego, któregom obrał, który strzegł rozkazania mego i wyroków moich.
“‘Ṣùgbọ́n èmi kì yóò gba gbogbo ìjọba náà lọ́wọ́ Solomoni; èmi ti mú un jẹ́ olórí ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi, ẹni tí mo yàn, tí ó sì ti pa òfin mi àti àṣẹ mi mọ́.
35 Ale wziąwszy królestwo z ręki syna jego, dam tobie z niego dziesięć pokoleń:
Èmi yóò gba ìjọba náà ní ọwọ́ ọmọ rẹ̀, èmi yóò sì fi ẹ̀yà mẹ́wàá fún ọ.
36 A synowi jego dam pokolenie jedno, aby została pochodnia Dawidowi, słudze memu, po wszystkie dni przedemną w mieście Jeruzalemie, którem sobie obrał, aby tam przebywało imię moje;
Èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ kí Dafidi ìránṣẹ́ mi lè máa ní ìmọ́lẹ̀ níwájú mi nígbà gbogbo ní Jerusalẹmu, ìlú tí mo ti yàn láti fi orúkọ mi síbẹ̀.
37 A ciebie wezmę, abyś królował nad wszystkiem, czego żąda dusza twoja, a będziesz królem nad Izraelem.
Ṣùgbọ́n ní ti ìwọ, Èmi yóò mú ọ, ìwọ yóò sì jẹ ọba lórí ohun gbogbo tí ọkàn rẹ ń fẹ́; ìwọ yóò jẹ ọba lórí Israẹli.
38 Przetoż jeźli będziesz słuchał wszystkiego, coć przykażę, a będziesz chodził drogami mojemi, czyniąc to, co dobrego jest w oczach moich, strzegąc wyroków moich, i przykazań moich, jako czynił Dawid, sługa mój: tedy będę z tobą, a zbudujęć dom mocny, jakom zbudował Dawidowi, i podam ci Izraela;
Bí ìwọ bá ṣe gbogbo èyí tí mo pàṣẹ fún ọ, tí o sì rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú mi nípa pípa òfin àti àṣẹ mi mọ́, bí i Dafidi ìránṣẹ́ mi ti ṣe, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò kọ́ ilé òtítọ́ fún ọ bí èyí tí mo kọ́ fún Dafidi, èmi yóò sì fi Israẹli fún ọ.
39 I trapić będę nasienie Dawidowe dla tego; a wszakże nie po wszystkie dni.
Èmi yóò sì rẹ irú-ọmọ Dafidi sílẹ̀ nítorí èyí, ṣùgbọ́n kì í ṣe títí láé.’”
40 Przetoż Salomon chciał zabić Jaroboama; ale wstawszy Jeroboam uciekł do Egiptu, do Sesaka, króla Egipskiego, i był w Egipcie aż do śmierci Salomonowej.
Solomoni wá ọ̀nà láti pa Jeroboamu, ṣùgbọ́n Jeroboamu sálọ sí Ejibiti, sọ́dọ̀ Ṣiṣaki ọba Ejibiti, ó sì wà níbẹ̀ títí Solomoni fi kú.
41 A inne sprawy Salomonowe, którekolwiek czynił, i mądrość jego, izali nie są wypisane w księgach spraw Salomonowych?
Ìyókù iṣẹ́ Solomoni àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ọgbọ́n rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìṣe Solomoni bí?
42 A dni, których królował Salomon w Jeruzalemie nad wszystkim Izraelem, było czterdzieści lat.
Solomoni sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu lórí gbogbo Israẹli ní ogójì ọdún.
43 I zasnął Salomon z ojcy swymi, a pogrzebiony jest w mieście Dawida, ojca swego; i królował Roboam, syn jego, miasto niego.
Nígbà náà ni Solomoni sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Rehoboamu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< I Królewska 11 >