< I Kronik 24 >

1 A synowie Aaronowi tym sposobem rozdzieleni byli: Synowie Aaronowi byli Nedab i Abiju, Eleazar i Itamar;
Àwọn wọ̀nyí sì ni pínpín àwọn ọmọ Aaroni. Àwọn ọmọ Aaroni ni Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
2 Ale iż Nadab i Abiju umarli przed obliczem ojca swego, a synów nie mieli: przetoż odprawowali urząd kapłański Eleazar i Itamar.
Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú kí ó tó di wí pé baba wọn kú, wọn kò sì ní àwọn ọmọ; bẹ́ẹ̀ ni Eleasari àti Itamari sì ṣe gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
3 I podzielił ich Dawid, to jest Sadoka z synów Eleazarowych, i Achimelecha z synów Itamarrowych, według urzędu ich w usługach ich.
Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Sadoku ọmọ Eleasari àti Ahimeleki ọmọ Itamari, Dafidi sì yà wọ́n nípa nínú ìpín fún ìyàsọ́tọ̀ àwọn iṣẹ́ ìsìn wọn.
4 I znalazło się synów Eleazarowych więcej przedniejszych mężów, niż synów Itamarowych, gdy ich podzielił. Z synów Eleazarowych było przedniejszych według domów ojcowskich szesnaście; ale synów Itamarowych według domów ojcowskich ośm.
A rí ọ̀pọ̀ àwọn olórí lára àwọn ọmọ Eleasari ju lára àwọn ọmọ Itamari lọ, wọ́n sì pín wọn lẹ́sẹ lẹ́sẹ: mẹ́rìndínlógún olórí láti ìdílé ọmọ Eleasari ìran wọn àti olórí méjọ ìdílé láti ara àwọn ọmọ Itamari.
5 A rozdzieleni są losem jedni od drugich; bo byli przełożonymi nad świątnicą, i przedniejszymi przed Bogiem, tak z synów Eleazarowych, jako i z synów Itamarowych.
Wọ́n sì pín wọn láìṣègbè nípa yíya ìpín, nítorí àwọn olórí ibi mímọ́ àti àwọn olórí ilé Ọlọ́run wà láàrín àwọn ọmọ méjèèjì Eleasari àti Itamari.
6 A popisał ich Senejasz, syn Natanaelowy, pisarz, z pokolenia Lewiego, przed królem i psiążętami, i przed Sadokiem kapłanem, i Achimelechem, synem Abijatarowym, i przedniejszymi z domów ojcowskich, kapłanów i Lewitów; a naznaczono jeden dom ojcowsk i Eleazarowi, a drugi naznaczono Itamarowi.
Ṣemaiah ọmọ Netaneli, akọ̀wé ọ̀kan lára àwọn ọmọ Lefi sì kọ orúkọ wọn níwájú ọba àti àwọn ìjòyè: Sadoku àlùfáà, Ahimeleki ọmọ Abiatari àti olórí ìdílé àwọn àlùfáà tí a mú láti ọ̀dọ̀ Eleasari àti ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ Itamari.
7 I padł los pierwszy na Jehojaryba, na Jedajasza wtóry;
Ìpín èkínní jáde sí Jehoiaribu, èkejì sí Jedaiah,
8 Na Haryma trzeci, na Seoryma czwarty;
ẹlẹ́ẹ̀kẹta sì ni Harimu, ẹ̀kẹrin sì ní Seorimu,
9 Na Malchyjasza piąty, na Mijamana szósty;
ẹ̀karùnún sì ni Malkiah, ẹlẹ́ẹ̀kẹfà sì ni Mijamini,
10 Na Akkosa siódmy, na Abijasza ósmy;
èkeje sì ni Hakosi, ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ sí ni Abijah,
11 Na Jesuego dziewiąty, na Sechenijasza dziesiąty;
ẹ̀kẹsànán sì ni Jeṣua, ẹ̀kẹwàá sì ni Ṣekaniah,
12 Na Eliasyba jedenasty, na Jakima dwunasty;
ẹ̀kọkànlá sì ni Eliaṣibu, ẹlẹ́ẹ̀kẹjìlá sì ni Jakimu,
13 Na Huppa trzynasty, na Jesebaba czternasty;
ẹ̀kẹtàlá sì ni Hupa, ẹlẹ́ẹ̀kẹrìnlá sì ni Jeṣebeabu,
14 Na Bilgę piętnasty, na Immera szesnasty;
ẹ̀kẹdógún sì ni Bilgah, ẹ̀kẹrìndínlógún sì ni Immeri,
15 Na Chezyra siedmnasty, na Happisesa ośmnasty;
ẹ̀kẹtàdínlógún sì ni Hesiri, èkejìdínlógún sì ni Hafisesi,
16 Na Petachyjasza dziewiętnasty, na Ezechyjela dwudziesty;
ẹ̀kọkàndínlógún sì ni Petahiah, ogún sì ni Jeheskeli,
17 Na Jachyna dwudziesty i pierwszy, na Gamuela dwudziesty i wtóry;
ẹ̀kọkànlélógún sì ni Jakini, ẹ̀kẹrìnlélógún sì ni Gamuli,
18 Na Delajasza dwudziesty i trzeci, na Maazyjasza dwudziesty i czwarty.
ẹ̀kẹtàlélógún sì ni Delaiah, ẹ̀kẹrìnlélógún sì ni Maasiah.
19 Cić są sporządzeni w posługiwaniu swojem, aby wchodzili do domu Pańskiego w przemianach swych, jako zwykli pod rządem Aarona, ojca ich, jako mu był rozkazał Pan, Bóg Izraelski.
Àwọn wọ̀nyí ni a yàn fún iṣẹ́ ìsìn nígbà tí wọ́n wọ ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìlànà àti àṣẹ tí a ti fi fún wọn láti ọwọ́ baba ńlá wọn Aaroni gẹ́gẹ́ bí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí pàṣẹ fun un.
20 A z synów Lewiego, którzy byli pozostali z synów Amramowych, Subajel; z synów Subajelowych Jechdejasz.
Ìyókù àwọn ọmọ Lefi. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Amramu: Ṣubaeli láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣubaeli; Jehdeiah.
21 Z Rechabijasza, z synów Rechabijaszowych był przednjiejszy Jesyjasz.
Àti gẹ́gẹ́ bí Rehabiah, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Rehabiah, Iṣiah sì ni alákọ́kọ́.
22 Z Isaary Salomit, z synów Salomitowych Jachat.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti; láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣelomoti: Jahati.
23 A synowie Jeryjaszowi: Amaryjasz wtóry, Jehazylej trzeci, Jekmaan czwarty.
Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah alákọ́kọ́, Amariah ẹlẹ́ẹ̀kejì, Jahasieli ẹlẹ́ẹ̀kẹta àti Jekameamu ẹlẹ́ẹ̀kẹrin.
24 Synowie Husyjelowi Micha; z synów Michy Samir.
Àwọn ọmọ Usieli: Mika; nínú àwọn ọmọ Mika: Ṣamiri.
25 Brat Michasowy Jesyjasz; z synów Jesyjaszowych Zacharyjasz.
Àwọn arákùnrin Mika: Iṣi; nínú àwọn ọmọ Iṣiah: Sekariah.
26 Synowie Merarego: Maheli i Musy: synowie Jahasyjaszowi Beno.
Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Jaasiah: Beno.
27 Sunowie Merarego z Jahasyjasza: Beno, i Soam, i Zachur, i Hybry.
Àwọn ọmọ Merari. Láti Jaasiah: Beno, Ṣohamu, Sakkuri àti Ibri.
28 Z Mahalego Eleazar, który nie miał synów.
Láti Mahili: Eleasari, ẹni tí kò ni àwọn ọmọ.
29 Z Cysa, synowie Cysowi Jerahmeel.
Láti Kiṣi. Àwọn ọmọ Kiṣi: Jerahmeeli.
30 A synowie Musy: Maheli i Eder, i Jerymot. Cić byli synowie Lewitów według domów ojców ich.
Àti àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti. Èyí ni àwọn ọmọ Lefi, gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
31 I ci też miotali losy naprzeciwko braci swoich, synom Aaronowym, przed Dawidem królem, i Sadokiem, i Achimelechem, i przedniejszymi domów ojcowskich, z kapłanów i Lewitów, z domów ojcowskich, każdy przedniejszy przeciwko bratu swemu młodszemu.
Wọ́n sì ṣé kèké gẹ́gẹ́ bí àwọn arákùnrin wọn àwọn ọmọ Aaroni ṣe ṣẹ́, níwájú ọba Dafidi àti Sadoku, Ahimeleki, àti olórí ìdílé àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ìdílé àgbàgbà arákùnrin wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀ lórí àwọn arákùnrin wọn kéékèèké.

< I Kronik 24 >