< I Kronik 20 >

1 I stało się po roku tego czasu, gdy królowie zwykli wyjeżdżać na wojnę, iż wywiódł Joab co mężniejsze rycerstwo, i pustoszył ziemię synów Ammonowych, a przyciągnąwszy obległ Rabbę; (lecz Dawid zostawał w Jeruzalemie) i dobył Joab Rabby, i zburzył ją.
Ní àkókò àkọ́rọ̀ òjò, ni ìgbà tí àwọn ọba lọ sí ogun, Joabu ṣamọ̀nà àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun. Ó fi ilẹ̀ àwọn ará Ammoni ṣòfò. Ó lọ sí ọ̀dọ̀ Rabba. Ó sì fi ogun dúró tì í. Ṣùgbọ́n Dafidi dúró sí Jerusalẹmu Joabu kọlu Rabba, ó sì fi sílẹ̀ ní ìparun.
2 I wziął Dawid koronę króla ich z głowy jego, a znalazł w niej talent złota, i kamienie bardzo drogie. I włożono ją na głowę Dawidową, i wywiózł łupów z miasta bardzo wiele.
Dafidi mú adé kúrò lórí àwọn ọba wọn ìwọ̀n rẹ̀ dàbí i tálẹ́ǹtì wúrà, a sì tò ó jọ pẹ̀lú àwọn òkúta iyebíye. A sì gbé e ka orí Dafidi. Ó kó ọ̀pọ̀ ìkógun láti ìlú ńlá náà.
3 Lud też, który był w nim, wywiódł, i dał ich potrzeć piłami i wozami żelaznemi, i porąbać siekierami. Takci uczynił Dawid wszystkim miastom synów Ammonowych, i wrócił się Dawid ze wszystkim ludem do Jeruzalemu.
Ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ jáde, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ayùn àti ìtulẹ̀ onírin àti àáké. Dafidi ṣe eléyìí sí gbogbo àwọn ará ìlú Ammoni. Nígbà náà, Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ padà sí Jerusalẹmu.
4 Potem znowu gdy była wojna w Gazer z Filistynami, zabił Sobbochaj Husatczyk Syfę, który był z narodu olbrzymów; a tak Filistynowie poniżeni są.
Ní ẹ̀yìn èyí ni ogun bẹ́ sílẹ̀ ní Geseri pẹ̀lú àwọn ará Filistini, ní àkókò yìí ni Sibekai ará Huṣati pa Sipai, ọ̀kan lára àwọn ọmọ Refaimu, àti àwọn ará Filistini ni a ṣẹ́gun.
5 Była też jeszcze wojna z Filistynami, gdzie zabił Elchana, syn Jairowy, Lachmiego, brata Golijata Gietejczyka, którego drzewce u włóczni było nawój tkacki.
Nínú ogun mìíràn pẹ̀lú àwọn ará Filistini, Elhanani ọmọ Jairi pa Lahmi arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni ti ó ní ọ̀kọ̀ kan tí ó dàbí ọ̀pá ahunṣọ.
6 Nadto jeszcze była wojna w Get, gdzie był mąż wzrostu wielkiego, mając po sześć palców, wszystkich dwadzieścia i cztery; a ten też był z narodu tegoż olbrzyma.
Síbẹ̀síbẹ̀ nínú ogun mìíràn, tí ó wáyé ní Gati, ọkùnrin títóbi kan wà tí ó ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ìka mẹ́fà ní ẹsẹ̀ rẹ̀ mẹ́rìnlélógún lápapọ̀. Òun pẹ̀lú wá láti Rafa.
7 Ten gdy urągał Izraelowi, zabił go Jonatan, syn Samaja, brata Dawidowego.
Nígbà tí ó fi Israẹli ṣẹ̀sín, Jonatani ọmọ Ṣimea, arákùnrin Dafidi sì pa á.
8 Ci byli synowie jednego olbrzyma z Get, którzy polegli od ręki Dawidowej, i od ręki sług jego.
Wọ̀nyí ni ìran ọmọ Rafa ní Gati, wọ́n sì ṣubú sí ọwọ́ Dafidi àti àwọn ọkùnrin rẹ̀.

< I Kronik 20 >