< I Kronik 12 >

1 A cić są, co byli przyszli do Dawida do Sycelegu, gdy się jeszcze krył przed Saulem, synem Cysowym; a ci byli między mocarzami posiłek dawający w bitwie,
Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin tí ó wá sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Siklagi, nígbà tí ó sá kúrò níwájú Saulu ọmọ Kiṣi (wọ́n wà lára àwọn jagunjagun ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti ibi ìjà.
2 Noszący łuk, a prawą i lewą ręką ciskający kamieńmi, i strzelający z łuku, a byli z braci Saulowych z pokolenia Benjaminowego:
Wọ́n sì mú wọn pẹ̀lú ìtẹríba wọ́n sì lágbára láti ta ọfà tàbí láti ta kànnàkànnà òkúta ní ọwọ́ òsì tàbí ní ọwọ́ ọ̀tún, wọ́n sì jẹ́ ìbátan ọkùnrin Saulu láti ẹ̀yà Benjamini):
3 Książe Achyjezer, i Joaz, synowie Semmai Gabatczyka, i Jezyjel, i Falet, synowie Azmawetowi, i Baracha, i Jehu Anatotczyk;
Ahieseri olórí wọn àti Joaṣi àwọn ọmọ Ṣemaah ará Gibeah: Jeṣieli àti Peleti ọmọ Asmafeti, Beraka, Jehu ará Anatoti.
4 Ismajasz też Gabaończyk, mężny między trzydziestoma, a był przełożony nad trzydziestoma; i Jeremijasz, i Jahazyjel, Johanan, i Jozabad Gliederatczyk;
Àti Iṣmaiah ará Gibeoni, ọkùnrin alágbára kan lára àwọn ọgbọ̀n ẹni tí ó jẹ́ olórí nínú àwọn ọgbọ̀n; Jeremiah, Jahasieli, Johanani, Josabadi ará Gedera,
5 Eluzaj, i Jerymot, i Bealijasz, i Semaryjasz, i Sefatyjasz Harufitszyk;
Elusai, Jerimoti, Bealiah, Ṣemariah àti Ṣefatia ará Harufiti;
6 Elkana, i Jesyjasz, i Asareel i Joezer, i Jasobam Korchytczyk;
Elkana, Iṣiah, Asareeli, Joeseri àti Jaṣobeamu ará Kora;
7 I Joela, i Zebadyjasz, synowie Jerohamowi z Giedor.
àti Joẹla, àti Sebadiah àwọn ọmọ Jerohamu láti Gedori.
8 A z pokolenia Gadowego zbiegli byli do Dawida na miejsce obronne na puszczę mężowie duży, mężowie sposobni do boju, noszący tarcz i kopiję, których twarze były jako lwie tarze, a jako sarny po górach prędcy;
Díẹ̀ lára àwọn ará Gadi yà sọ́dọ̀ Dafidi ní ibi gíga ní aginjù. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di asà àti ẹṣin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.
9 Eser przedniejszy, Obadyjasz wtóry, Elijab trzeci,
Eseri sì jẹ́ ìjòyè, Obadiah sì jẹ́ igbákejì akọgun, Eliabu ẹlẹ́ẹ̀kẹta,
10 Mismanna czwarty, Jeremijasz piąty,
Miṣimana ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀karùnún
11 Ataj szósty, Eliel siódmy,
Attai ẹlẹ́ẹ̀kẹfà, Elieli èkeje,
12 Jochanan ósmy, Elzebad dziewiąty,
Johanani ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ Elsabadi ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án
13 Jeremijasz dziesiąty, Machbanajasz jedenasty.
Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá àti Makbannai ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá.
14 Cić byli z synów Gadowych, hetmani wojska, jeden nad stem mniejszy, a większy nad tysiącem.
Àwọn ará Gadi wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.
15 Cić są, którzy przeszli Jordan miesiąca pierwszego, który był wylał ze wszystkich brzegów swoich; i wygnali wszystkich mieszkających w dolinach na wschód i na zachód słońca.
Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jordani ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà-oòrùn àti níhà ìwọ̀-oòrùn.
16 Przyszli także niektórzy z synów Benjaminowych i z Judowych, do miejsca obronnego, do Dawida.
Ìyókù ará Benjamini àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Juda lọ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní ibi gíga.
17 I wyszedł Dawid przeciwko nim a odpowiadając, rzekł im: Jeźliście spokojnie przyszli do mnie, abyście mię ratowali, serce też moje złączy się z wami; ale jeźliście przyszli, abyście mię wydali nieprzyjaciołom moim, (choć nie masz nieprawości przy mnie) niech w to wejrzy Bóg ojców naszych, a niech sądzi.
Dafidi sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo ṣetán láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀tá mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”
18 Tedy Duch przyoblekł Amazyjasza, przedniejszego między hetmanami, i rzekł: Twoiśmy, o Dawidzie! a z tobą przestajemy, synu Isajego. Pokój, pokój tobie, i pokój pomocnikom twoim! gdyż ci pomaga Bóg twój. A tak przyjął ich Dawid, i postanowił ich hetmanami wojska.
Nígbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ wa sórí Amasai ìjòyè àwọn ọgbọ̀n, ó sì wí pé, “Tìrẹ ni àwa ń ṣe, ìwọ Dafidi! Àwa pẹ̀lú rẹ, ìwọ ọmọ Jese! Àlàáfíà, àlàáfíà fún ọ, àti àlàáfíà fún àwọn tí ó ràn ó lọ́wọ́, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gbà wọ́n ó sì mú wọn jẹ olórí ẹgbẹ́ ogun.
19 A z pokolenia Manasesowego odpadli niektórzy do Dawida, gdy ciągnął z Filistynami przeciwko Saulowi na wojnę; ale im nie byli na pomocy, gdyż naradziwszy się książęta Filistyńscy odesłali go, mówiąc: Ten z niebezpieczeństwem głów naszych odpadnie do Saula, pana swego.
Díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin Manase sì yà sí ọ̀dọ̀ Dafidi nígbà tí ó lọ pẹ̀lú àwọn ará Filistini láti bá Saulu jà. (Òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ wọn kò sì ran ará Filistini lọ́wọ́ nítorí, lẹ́yìn tiwọn sọ̀rọ̀ papọ̀, àwọn olórí wọn rán wọn jáde, wọ́n sì wí pé, “Yóò jẹ́ ìparun fún wa tí ó bá padà tọ ọ̀gá rẹ̀ Saulu lọ.”)
20 Gdy tedy szedł do Syceleu, uciekli do niego niektórzy z pokolenia Manasesowego: Adnach i Josabad, i Jediael, i Michael, i Jozabad i Elihu, i Sylletaj, i hetmani nad tysiącami w pokoleniu Manasesowem.
Nígbà tí Dafidi lọ sí Siklagi, àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin ti Manase ẹni tí ó sì yà sọ́dọ̀ rẹ̀. Adina, Josabadi, Jediaeli, Mikaeli, Josabadi, Elihu àti Siletai, àwọn olórí ìrẹ́pọ̀ ti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní Manase.
21 A ci posiłkowali Dawida przeciw onemu hufowi; bo mężni byli wszyscy, przetoż byli hetmanami w wojsku jego.
Wọ́n sì ran Dafidi lọ́wọ́ lórí ẹgbẹ́ ogun náà, nítorí gbogbo wọn ni akọni ènìyàn àwọn sì tún ni olórí nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
22 Nawet na każdy dzień ściągali się do Dawida na pomoc jemu, aż było wojsko wielkie jako wojsko Boże.
Ọjọ́ dé ọjọ́ ni àwọn ọkùnrin wá láti ran Dafidi lọ́wọ́, títí tí ó fi ní àwọn ológun ńlá, bí ogun Ọlọ́run.
23 A tać jest liczba przedniejszych gotowych do boju, którzy przyszli do Dawida do Hebronu, aby przenieśli królestwo Saulowe do niego według słowa Pańskiego.
Àwọn wọ̀nyí sì ni iye ọkùnrin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun àwọn ẹni tí ó wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni láti yí ìjọba Dafidi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
24 Z synów Judowych, noszących tarcz i włócznię, sześć tysięcy i ośm set gotowych do boju.
Ọkùnrin Juda, tí o ń gbé asà àti ọ̀kọ̀, ẹgbàáta lé lẹ́gbẹ̀rin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun.
25 Z synów Symeonowych, mężnych do boju, siedm tysięcy i sto.
Àwọn ọkùnrin Simeoni, akọni tó mú fún ogun sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ó lé ọgọ́rùn-ún;
26 Z synów Lewiego cztery tysiące i sześć set.
àwọn ọkùnrin Lefi ẹgbàajì ó le ẹgbẹ̀ta,
27 Jojada także przedniejszy z synów Aaronowych, a z nim trzy tysiące i siedm set.
pẹ̀lú Jehoiada, olórí ìdílé Aaroni pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn,
28 A Sadok młodzieniec, rycerz mężny, i z domu ojca jego książąt dwadzieścia i dwóch.
àti Sadoku akọni ọ̀dọ́mọkùnrin, pẹ̀lú àwọn méjìlélógún ìjòyè láti ọ̀dọ̀ àwọn ìdílé rẹ̀;
29 A z synów Benjaminowych, braci Saulowych, trzy tysiące; bo jeszcze wielka część ich przestawała z domem Saulowym.
àwọn arákùnrin Benjamini ìbátan ọkùnrin Saulu ẹgbẹ̀rún mẹ́ta, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ẹni tí ó si kù ní olóòtítọ́ sí ilé Saulu títí di ìgbà náà;
30 A z synów Efraimowych dwadzieścia tysięcy i ośm set, ludzi mężnych, mężów sławnych w domach ojców ich.
àwọn arákùnrin Efraimu, ògbójú akọni, ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n nílé baba wọn ogún ẹgbẹ̀rún ó le ẹgbẹ̀rin;
31 A z połowy pokolenia Manasesowego ośmnaście tysięcy, którzy byli mianowani według imion, aby przyszli i postanowili Dawida królem.
àwọn ọkùnrin nínú ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, tí a yàn nípa orúkọ láti wá àti láti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba, ẹgbàá mẹ́sàn.
32 A z synów Isascharowych, umiejących rozeznawać czasy, tak iż wiedzieli, co kiedy czynić miał Izrael, książąt ich dwieście; a wszyscy bracia ich przestawali na radzie ich.
Àti ní ti àwọn ọmọ Isakari, àwọn ẹni tí ó ní òye àkókò, láti mọ ohun tí Israẹli ìbá máa ṣe; olórí wọn jẹ́ ìgbà; àti gbogbo àwọn ìbátan wọn ń bẹ ní ìkáwọ́ wọn.
33 Z pokolenia Zabulonowego, którzy wychodzili na wojnę, gotowych do boju z każdym orężem wojennym, pięćdziesiąt tysięcy, stawających w szyku jednostajnem sercem.
Àwọn ọkùnrin Sebuluni, àti àwọn jagunjagun tí ó ti nípa ogun múra fún ogun pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ohun èlò ìjà, láti ran Dafidi lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn tí kò fi iyèméjì ṣe ìjólóòótọ́ wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
34 A z pokolenia Neftalimowego książąt tysiąc, a z nimi z tarczami i z kopijami trzydzieści i siedm tysięcy.
Àwọn ọkùnrin Naftali, ẹgbẹ̀rún ìjòyè àpapọ̀ pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún. Ọkùnrin tí wọ́n gbé asà àti ọ̀kọ̀ wọn.
35 A z pokolenia Danowego, gotowych do boju, dwadzieścia i ośm tysięcy i sześć set.
Àwọn ọkùnrin Dani, tí wọ́n ṣetán fún ogun ẹgbàá mẹ́tàlá.
36 A z pokolenia Aserowego, którzy wychodzili na wojnę, i umieli się szykować do bitwy, czterdzieści tysięcy.
Àwọn ọkùnrin Aṣeri, àwọn tí ó ti ní ìmọ̀ ogun múra fún ogun ọ̀kẹ́ méjì.
37 A z Za-Jordania z pokolenia Rubenowego i Gadowego, i z połowy pokolenia Manasesowego ze wszystkim orężemwojennym sto i dwadzieścia tysięcy.
Láti ìlà-oòrùn Jordani, ọkùnrin Reubeni, Gadi, àti ìdajì ẹ̀yà Manase, dìmọ́ra pẹ̀lú gbogbo onírúurú ohun èlò ìjà ọ̀kẹ́ mẹ́fà.
38 Ci wszyscy mężowie waleczni sprawni ku bitwie, sercem uprzejmem przyszl do Hebronu, aby postanowili Dawida królem nad wszystkim Izraelem. Nadto i wszyscy inni z Izraela jednego serca byli, aby postanowili królem Dawida.
Gbogbo èyí ni àwọn ọkùnrin ológun tí ó fi ara wọn fún ogun láti ṣe iṣẹ́ fún nínú ẹgbẹ́. Wọ́n wá sí Hebroni tí ó kún fún ìpinnu láti fi Dafidi jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. Gbogbo àwọn ìyókù lára àwọn ọmọ Israẹli sì jẹ́ onínú kan láti fi Dafidi jẹ ọba.
39 I byli tam z Dawidem przez trzy dni jedząc i pijąc: bo im byli nagotowali bracia ich.
Àwọn ọkùnrin náà lo ọjọ́ mẹ́ta níbẹ̀ pẹ̀lú Dafidi, wọ́n jẹ, wọ́n sì ń mu, nítorí ìdílé wọn ti pèsè oúnjẹ fún wọn.
40 Także i którzy blisko ich byli aż do Isaschar i Zabulon i Neftalim, przynosili chleby na osłach, i na wielbłądach, i na mułach, i na wołach, potrawy, mąki, figi, rodzynki, i wino, i oliwę, i wołów, i owiec wielkim dostatkiem; bo była radość w Izraelu.
Àwọn aládùúgbò láti ọ̀nà jíjìn gẹ́gẹ́ bí Isakari, Sebuluni àti Naftali gbé oúnjẹ wá lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, lórí ràkunmí, àti lórí ìbáaka àti lórí màlúù, àní oúnjẹ ti ìyẹ̀fun, èso àjàrà gbígbẹ, èso ọ̀pọ̀tọ́, àkàrà dídùn, ọtí wáìnì, òróró, màlúù àti àgùntàn, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ wà ní Israẹli.

< I Kronik 12 >