< مکاشفهٔ یوحنا 19 >

و بعد از آن شنیدم چون آوازی بلند ازگروهی کثیر در آسمان که می‌گفتند: «هللویاه! نجات و جلال و اکرام و قوت از آن خدای ما است، ۱ 1
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí mo gbọ́ ohùn ńlá ní ọ̀run bí ẹni pé tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, ń wí pé: “Haleluya! Ti Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà, àti ọlá àti agbára,
زیرا که احکام او راست و عدل است، چونکه داوری نمود بر فاحشه بزرگ که جهان را به زنای خود فاسد می‌گردانید و انتقام خون بندگان خود را از دست او کشید.» ۲ 2
nítorí òtítọ́ àti òdodo ni ìdájọ́ rẹ̀. Nítorí o ti ṣe ìdájọ́ àgbèrè ńlá a nì, tí o fi àgbèrè rẹ̀ ba ilẹ̀ ayé jẹ́, ó sì ti gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀ náà.”
و بار دیگر گفتند: «هللویاه، و دودش تاابدالاباد بالا می‌رود!» (aiōn g165) ۳ 3
Àti lẹ́ẹ̀kejì wọ́n wí pé: “Haleluya! Èéfín rẹ̀ sì gòkè lọ láé àti láéláé.” (aiōn g165)
و آن بیست و چهار پیر و چهار حیوان به روی درافتاده، خدایی را که بر تخت نشسته است سجده نمودند و گفتند: «آمین، هللویاه!» ۴ 4
Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún nì, àti àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin nì sì wólẹ̀, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run tí ó jókòó lórí ìtẹ́, wí pé: “Àmín, Haleluya!”
و آوازی از تخت بیرون آمده، گفت: «حمدنمایید خدای ما را‌ای تمامی بندگان او وترسندگان او چه کبیر و چه صغیر.» ۵ 5
Ohùn kan sì ti ibi ìtẹ́ náà jáde wá, wí pé: “Ẹ máa yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo, ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti èwe àti àgbà!”
و شنیدم چون آواز جمعی کثیر و چون آوازآبهای فراوان و چون آواز رعدهای شدید که می‌گفتند: «هللویاه، زیرا خداوند خدای ما قادرمطلق، سلطنت گرفته است. ۶ 6
Mo sì gbọ́ bí ẹni pé ohùn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àti bí ìró omi púpọ̀, àti bí ìró àrá ńlá ńlá, ń wí pé: “Haleluya! Nítorí Olúwa Ọlọ́run wa, Olódùmarè ń jẹ ọba.
شادی و وجدنماییم و او را تمجید کنیم زیرا که نکاح بره رسیده است و عروس او خود را حاضر ساخته است. ۷ 7
Ẹ jẹ́ kí a yọ̀, kí inú wa kí ó sì dùn gidigidi, kí a sì fi ògo fún un. Nítorí pé ìgbéyàwó Ọ̀dọ́-Àgùntàn dé, aya rẹ̀ sì ti múra tán.
وبه او داده شد که به کتان، پاک و روشن خود رابپوشاند، زیرا که آن کتان عدالتهای مقدسین است.» ۸ 8
Òun ni a sì fi fún pé kí ó wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ wíwẹ́ tí ó funfun gbòò.” (Nítorí pé aṣọ ọ̀gbọ̀ nì dúró fún iṣẹ́ òdodo àwọn ènìyàn mímọ́.)
و مرا گفت: «بنویس: خوشابحال آنانی که به بزم نکاح بره دعوت شده‌اند.» و نیز مرا گفت که «این است کلام راست خدا.» ۹ 9
Ó sì wí fún mi pé, “Kọ̀wé rẹ̀, ‘Ìbùkún ni fún àwọn tí a pè sí àsè alẹ́ ìgbéyàwó ọ̀dọ́-àgùntàn.’” Ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ òtítọ́ Ọlọ́run.”
و نزد پایهایش افتادم تا او را سجده کنم. اوبه من گفت: «زنهار چنین نکنی زیرا که من با توهمخدمت هستم و با برادرانت که شهادت عیسی را دارند. خدا را سجده کن زیرا که شهادت عیسی روح نبوت است.» ۱۰ 10
Mo sì wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ láti foríbalẹ̀ fún un. Ó sì wí fún mi pé, “Wò ó, má ṣe bẹ́ẹ̀: ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ tí wọ́n di ẹ̀rí Jesu mú. Foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run: nítorí pé ẹ̀rí Jesu ni ìsọtẹ́lẹ̀.”
و دیدم آسمان را گشوده و ناگاه اسبی سفیدکه سوارش امین و حق نام دارد و به عدل داوری وجنگ می‌نماید، ۱۱ 11
Mo sì rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, sì wò ó, ẹṣin funfun kan; ẹni tí ó jókòó lórí rẹ̀ ni à ń pè ní Olódodo àti Olóòtítọ́, nínú òdodo ni ó sì ń ṣe ìdájọ́, tí ó ń jagun.
و چشمانش چون شعله آتش و بر سرش افسرهای بسیار و اسمی مرقوم داردکه جز خودش هیچ‌کس آن را نمی داند. ۱۲ 12
Ojú rẹ̀ dàbí ọ̀wọ́-iná, àti ní orí rẹ̀ ni adé púpọ̀ wà; ó sì ní orúkọ kan tí a kọ, tí ẹnikẹ́ni kò mọ́, bí kò ṣe òun tìkára rẹ̀.
وجامه‌ای خون آلود دربر دارد و نام او را «کلمه خدا» می‌خوانند. ۱۳ 13
A sì wọ̀ ọ́ ní aṣọ tí a tẹ̀ bọ inú ẹ̀jẹ̀, a sì ń pe orúkọ rẹ̀ ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
و لشکرهایی که درآسمانند، بر اسبهای سفید و به کتان سفید و پاک ملبس از عقب او می‌آمدند. ۱۴ 14
Àwọn ogun tí ń bẹ ní ọ̀run tí a wọ̀ ní aṣọ ọ̀gbọ̀ wíwẹ́, funfun àti mímọ́, sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn lórí ẹṣin funfun.
و از دهانش شمشیری تیز بیرون می‌آید تا به آن امت‌ها را بزندو آنها را به عصای آهنین حکمرانی خواهد نمودو او چرخشت خمر غضب و خشم خدای قادرمطلق را زیر پای خود می‌افشرد. ۱۵ 15
Àti láti ẹnu rẹ̀ ni idà mímú ti ń jáde lọ, kí ó lè máa fi sá àwọn orílẹ̀-èdè: “Òun ó sì máa fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn.” Ó sì ń tẹ ìfúntí àti ìbínú Ọlọ́run Olódùmarè.
و بر لباس وران او نامی مرقوم است یعنی «پادشاه پادشاهان ورب‌الارباب». ۱۶ 16
Ó sì ní lára aṣọ rẹ̀ àti ni ìtàn rẹ̀ orúkọ kan tí a kọ: Ọba àwọn ọba àti Olúwa àwọn olúwa.
و دیدم فرشته‌ای را در آفتاب ایستاده که به آواز بلند تمامی مرغانی را که در آسمان پروازمی کنند، ندا کرده، می‌گوید: «بیایید و بجهت ضیافت عظیم خدا فراهم شوید. ۱۷ 17
Mo sì rí angẹli kan dúró nínú oòrùn; ó sì fi ohùn rara kígbe, ó ń wí fún gbogbo àwọn ẹyẹ tí ń fò ní agbede-méjì ọ̀run pé, “Ẹ wá ẹ sì kó ara yín jọ pọ̀ sí àsè ńlá Ọlọ́run;
تا بخورید گوشت پادشاهان و گوشت سپه سالاران و گوشت جباران و گوشت اسبها و سواران آنها و گوشت همگان را، چه آزاد و چه غلام، چه صغیر و چه کبیر.» ۱۸ 18
kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ ẹran-ara àwọn ọba, àti ẹran-ara àwọn olórí ogun àti ẹran-ara àwọn ènìyàn alágbára, àti ẹran àwọn ẹṣin, àti ti àwọn tí ó jókòó lórí wọn, àti ẹran-ara ènìyàn gbogbo, àti ti òmìnira, àti ti ẹrú, àti ti èwe àti ti àgbà.”
و دیدم وحش و پادشاهان زمین ولشکرهای ایشان را که جمع شده بودند تا بااسب‌سوار و لشکر او جنگ کنند. ۱۹ 19
Mo sì rí ẹranko náà àti àwọn ọba ayé, àti àwọn ogun wọn tí a gbá jọ láti bá ẹni tí ó jókòó lórí ẹṣin náà àti ogun rẹ̀ jagun.
و وحش گرفتار شد و نبی کاذب با وی که پیش او معجزات ظاهر می‌کرد تا به آنها آنانی را که نشان وحش رادارند و صورت او را می‌پرستند، گمراه کند. این هر دو، زنده به دریاچه آتش افروخته شده به کبریت انداخته شدند. (Limnē Pyr g3041 g4442) ۲۰ 20
A sì mú ẹranko náà, àti wòlíì èké nì pẹ̀lú rẹ̀, tí ó ti ń ṣe iṣẹ́ ìyanu níwájú rẹ̀, èyí tí ó fi ń tan àwọn tí ó gba àmì ẹranko náà àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ fún àwòrán rẹ̀ jẹ. Àwọn méjèèjì yìí ni a sọ láààyè sínú adágún iná tí ń fi sulfuru jó. (Limnē Pyr g3041 g4442)
و باقیان به شمشیری که از دهان اسب‌سوار بیرون می‌آمد کشته شدند وتمامی مرغان از گوشت ایشان سیر گردیدند. ۲۱ 21
Àwọn ìyókù ni a sì fi idà ẹni tí ó jókòó lórí ẹṣin náà pa, àní idà tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde, gbogbo àwọn ẹyẹ sì ti ipa ẹran-ara wọn yó.

< مکاشفهٔ یوحنا 19 >