< متّی 11 >

و چون عیسی این وصیت را با دوازده شاگرد خود به اتمام رسانید، از آنجا روانه شد تا در شهرهای ایشان تعلیم دهد و موعظه نماید. ۱ 1
Lẹ́yìn ìgbà tí Jesu sì ti parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá, ó ti ibẹ̀ rékọjá láti máa kọ́ni àti láti máa wàásù ní àwọn ìlú Galili gbogbo.
و چون یحیی در زندان، اعمال مسیح راشنید، دو نفر از شاگردان خود را فرستاده، ۲ 2
Nígbà tí Johanu gbọ́ ohun tí Kristi ṣe nínú ẹ̀wọ̀n, ó rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀
بدو گفت: «آیا آن آینده تویی یا منتظر دیگری باشیم؟» ۳ 3
láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣe ìwọ ni ẹni tó ń bọ̀ wá tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
عیسی در جواب ایشان گفت: «بروید ویحیی را از آنچه شنیده و دیده‌اید، اطلاع دهید ۴ 4
Jesu dáhùn ó wí pé, “Ẹ padà lọ, ẹ sì sọ fún Johanu ohun tí ẹ̀yin gbọ́, àti èyí tí ẹ̀yin rí.
که کوران بینا می‌گردند و لنگان به رفتار می‌آیندو ابرصان طاهر و کران شنوا و مردگان زنده می‌شوند و فقیران بشارت می‌شنوند؛ ۵ 5
Àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a ń wẹ àwọn adẹ́tẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ wọn, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, a sì ń wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì.
وخوشابحال کسی‌که در من نلغزد.» ۶ 6
Alábùkún fún ni ẹni tí kò rí ohun ìkọ̀sẹ̀ nípa mi.”
و چون ایشان می‌رفتند، عیسی با آن جماعت درباره یحیی آغاز سخن کرد که «بجهت دیدن چه چیز بیرون شدید؟ آیا نی را که از باد درجنبش است؟ ۷ 7
Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu ti lọ tán, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn nípa ti Johanu: “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò ní aginjù? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mi?
بلکه بجهت دیدن چه چیز بیرون شدید؟ آیا مردی را که لباس فاخر در بر دارد؟ اینک آنانی که رخت فاخر می‌پوشند در خانه های پادشاهان می‌باشند. ۸ 8
Bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, kí ni ẹ̀yin lọ òde lọ í wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ni aṣọ dáradára? Rárá àwọn ti ó wọ aṣọ dáradára wà ní ààfin ọba.
لیکن بجهت دیدن چه چیزبیرون رفتید؟ آیا نبی را؟ بلی به شما می‌گویم ازنبی افضلی را! ۹ 9
Àní kí ní ẹ jáde láti lọ wò? Wòlíì? Bẹ́ẹ̀ ni, mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ.”
زیرا همان است آنکه درباره اومکتوب است: “اینک من رسول خود را پیش روی تو می‌فرستم تا راه تو را پیش روی تو مهیا سازد.” ۱۰ 10
Èyí ni ẹni tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé: “‘Èmi yóò rán ìránṣẹ́ mi síwájú rẹ, ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
هرآینه به شما می‌گویم که از اولاد زنان، بزرگتری از یحیی تعمید‌دهنده برنخاست، لیکن کوچکتر در ملکوت آسمان از وی بزرگ تر است. ۱۱ 11
Lóòótọ́ ni mó wí fún yín, nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí ẹni tí ó tí í dìde tí ó ga ju Johanu onítẹ̀bọmi lọ, síbẹ̀ ẹni tí ó kéré jù ní ìjọba ọ̀run ni ó pọ̀jù ú lọ.
و از ایام یحیی تعمید‌دهنده تا الان، ملکوت آسمان محبور می‌شود و جباران آن را به زورمی ربایند. ۱۲ 12
Láti ìgbà ọjọ́ Johanu onítẹ̀bọmi títí di àkókò yìí ni ìjọba ọ̀run ti di à fi agbára wọ̀, àwọn alágbára ló ń fi ipá gbà á.
زیرا جمیع انبیا و تورات تا یحیی اخبار می‌نمودند. ۱۳ 13
Nítorí náà gbogbo òfin àti wòlíì ni ó sọtẹ́lẹ̀ kí Johanu kí ó tó dé.
و اگر خواهید قبول کنید، همان است الیاس که باید بیاید. ۱۴ 14
Bí ẹ̀yin yóò bá gbà á, èyí ni Elijah tó ń bọ̀ wá.
هر‌که گوش شنوا دارد بشنود. ۱۵ 15
Ẹni tí ó bá ní etí, kí ó gbọ́.
لیکن این طایفه را به چه چیزتشبیه نمایم؟ اطفالی را مانند که در کوچه هانشسته، رفیقان خویش را صدا زده، ۱۶ 16
“Kí ni èmi ìbá fi ìran yìí wé? Ó dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ń jókòó ní ọjà tí wọ́n sì ń ké pe àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn:
می‌گویند: “برای شما نی نواختیم، رقص نکردید؛ نوحه گری کردیم، سینه نزدید.” ۱۷ 17
“‘Àwa ń fun fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó; àwa kọrin ọ̀fọ̀ ẹ̀yin kò káàánú.’
زیرا که یحیی آمد، نه می‌خورد و نه می‌آشامید، می‌گویند دیو دارد. ۱۸ 18
Nítorí Johanu wá kò bá a yín jẹ bẹ́ẹ̀ ni kò mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù.’
پسر انسان آمد که می‌خورد و می‌نوشد، می‌گویند اینک مردی پرخور و میگسار و دوست باجگیران و گناهکاران است. لیکن حکمت ازفرزندان خود تصدیق کرده شده است.”» وعده آرامش درون ۱۹ 19
Ọmọ Ènìyàn wá bá a yín jẹun, ó sì bá yin mu, wọ́n wí pé, ‘Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtí; ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.’ Ṣùgbọ́n a dá ọgbọ́n láre nípa ìṣe rẹ̀.”
آنگاه شروع به ملامت نمود بر آن شهرهایی که اکثر از معجزات وی در آنها ظاهرشد زیرا که توبه نکرده بودند: ۲۰ 20
Nígbà náà ni Jesu bẹ̀rẹ̀ sí í bá ìlú tí ó ti ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ wí, nítorí wọn kò ronúpìwàdà.
«وای بر تو‌ای خورزین! وای بر تو‌ای بیت صیدا! زیرا اگرمعجزاتی که در شما ظاهر گشت، در صور وصیدون ظاهر می‌شد، هرآینه مدتی در پلاس وخاکستر توبه می‌نمودند. ۲۱ 21
Ó wí pé, “Ègbé ni fún ìwọ Korasini, ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Ìbá ṣe pé a ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu tí a ṣe nínú yín ní a ṣe ni Tire àti Sidoni, àwọn ènìyàn wọn ìbá ti ronúpìwàdà ti pẹ́ nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
لیکن به شما می‌گویم که در روز جزا حالت صور و صیدون از شماسهلتر خواهد بود. ۲۲ 22
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Tire àti Sidoni ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún yín.
و تو‌ای کفرناحوم که تا به فلک سرافراشته‌ای، به جهنم سرنگون خواهی شد زیرا هرگاه معجزاتی که در تو پدید آمد درسدوم ظاهر می‌شد، هرآینه تا امروز باقی می‌ماند. (Hadēs g86) ۲۳ 23
Àti ìwọ Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga sókè ọ̀run? Rárá, a ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ sí ipò òkú. Nítorí, ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ ìyanu tí a ṣe nínú rẹ ní Sodomu, òun ìbá wà títí di òní. (Hadēs g86)
لیکن به شما می‌گویم که در روز جزاحالت زمین سدوم از تو سهل تر خواهد بود.» ۲۴ 24
Lóòótọ́ yóò sàn fún ilẹ̀ Sodomu ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún ìwọ lọ.”
در آن وقت، عیسی توجه نموده، گفت: «ای پدر، مالک آسمان و زمین، تو را ستایش می‌کنم که این امور را از دانایان و خردمندان پنهان داشتی و به کودکان مکشوف فرمودی! ۲۵ 25
Nígbà náà ni Jesu wí pé, “Mo yìn ọ Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, nítorí ìwọ ti fi òtítọ́ yìí pamọ́ fún àwọn tó jẹ́ ọlọ́gbọ́n àti amòye, Ìwọ sì ti fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
بلی‌ای پدر، زیرا که همچنین منظور نظر تو بود. ۲۶ 26
Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, nítorí ó wù ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
پدر همه‌چیز را به من سپرده است و کسی پسر را نمی شناسد بجز پدر و نه پدر را هیچ‌کس می‌شناسد غیر از پسر و کسی‌که پسر بخواهد بدومکشوف سازد. ۲۷ 27
“Ohun gbogbo ni Baba mi ti fi sí ìkáwọ́ mi. Kò sí ẹni tí ó mọ ọmọ bí kò ṣe Baba, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí ó mọ Baba, bí kò ṣe ọmọ, àti àwọn tí ọmọ yan láti fi ara hàn fún.
بیاید نزد من‌ای تمام زحمتکشان و گرانباران و من شما را آرامی خواهم بخشید. ۲۸ 28
“Ẹ wá sọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ tí a sì di ẹrù wíwúwo lé lórí, èmi yóò sì fún yín ní ìsinmi.
یوغ مرا بر خود گیرید و از من تعلیم یابید زیرا که حلیم و افتاده‌دل می‌باشم و درنفوس خود آرامی خواهید یافت؛ ۲۹ 29
Ẹ gbé àjàgà mi wọ̀. Ẹ kọ́ ẹ̀kọ́ lọ́dọ̀ mi nítorí onínútútù àti onírẹ̀lẹ̀ ọkàn ni èmi, ẹ̀yin yóò sì ri ìsinmi fún ọkàn yín.
زیرا یوغ من خفیف است و بار من سبک.» ۳۰ 30
Nítorí àjàgà mi rọrùn ẹrù mi sì fúyẹ́.”

< متّی 11 >