< لوقا 18 >

و برای ایشان نیز مثلی آورد در اینکه می باید همیشه دعا کرد و کاهلی نورزید. ۱ 1
Ó sì pa òwe kan fún wọn láti fi yé wọn pe, ó yẹ kí a máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí a má sì ṣàárẹ̀.
پس گفت که «در شهری داوری بود که نه ترس از خدا و نه باکی از انسان می‌داشت. ۲ 2
Wí pé, “Onídàájọ́ kan wà ní ìlú kan, tí kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn.
ودر همان شهر بیوه‌زنی بود که پیش وی آمده می‌گفت، داد مرا از دشمنم بگیر. ۳ 3
Opó kan sì wà ní ìlú náà, ó sì ń tọ̀ ọ́ wá, wí pé, ‘Gbẹ̀san mi lára ọ̀tá mi!’
و تا مدتی به وی اعتناننمود ولکن بعد از آن با خود گفت هرچند از خدا نمی ترسم و از مردم باکی ندارم، ۴ 4
“Lákọ̀ọ́kọ́ kò dá a lóhùn, ṣùgbọ́n níkẹyìn ó wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Bí èmi kò tilẹ̀ bẹ̀rù Ọlọ́run, tí èmi kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn,
لیکن چون این بیوه‌زن مرا زحمت می‌دهد، به داد او می‌رسم، مبادا پیوسته آمده مرا به رنج آورد. ۵ 5
Ṣùgbọ́n nítorí tí opó yìí ń yọ mí lẹ́nu, èmi ó gbẹ̀san rẹ̀, kí ó má ba à fi wíwá rẹ̀ nígbàkígbà dá mi lágara.’”
خداوند گفت بشنوید که این داوربی انصاف چه می‌گوید؟ ۶ 6
Olúwa sì wí pé, “Ẹ gbọ́ bí aláìṣòótọ́ onídàájọ́ ti wí!
و آیا خدا برگزیدگان خود را که شبانه‌روز بدو استغاثه می‌کنند، دادرسی نخواهد کرد، اگرچه برای ایشان دیرغضب باشد؟ ۷ 7
Ọlọ́run kì yóò ha sì gbẹ̀san àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, tí ń fi ọ̀sán àti òru kígbe pè é, tí ó sì mú sùúrù fún wọn?
به شما می‌گویم که به زودی دادرسی ایشان را خواهد کرد. لیکن چون پسرانسان آید، آیا ایمان را بر زمین خواهدیافت؟ ۸ 8
Mo wí fún yín, yóò gbẹ̀san wọn kánkán! Ṣùgbọ́n nígbà tí Ọmọ Ènìyàn bá dé yóò ha rí ìgbàgbọ́ ní ayé bí?”
و این مثل را آورد برای بعضی که بر خوداعتماد می‌داشتند که عادل بودند و دیگران راحقیر می‌شمردند. ۹ 9
Ó sì pa òwe yìí fún àwọn kan tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ara wọn pé, àwọn ni olódodo, tí wọ́n sì ń gan àwọn ẹlòmíràn,
که «دو نفر یکی فریسی ودیگری باجگیر به هیکل رفتند تا عبادت کنند. ۱۰ 10
pé, “Àwọn ọkùnrin méjì gòkè lọ sí tẹmpili láti gbàdúrà, ọ̀kan jẹ́ Farisi, èkejì sì jẹ́ agbowó òde.
آن فریسی ایستاده بدینطور با خود دعا کرد که خدایا تو را شکر می‌کنم که مثل سایر مردم حریص و ظالم و زناکار نیستم و نه مثل این باجگیر، ۱۱ 11
Èyí Farisi dìde, ó sì ń gbàdúrà nínú ara rẹ̀ báyìí pé, ‘Ọlọ́run mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí èmi kò rí bí àwọn ará ìyókù, àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà, aláìṣòótọ́, panṣágà, tàbí bí agbowó òde yìí.
هر هفته دو مرتبه روزه می‌دارم و ازآنچه پیدا می‌کنم ده‌یک می‌دهم. ۱۲ 12
Èmi ń gbààwẹ̀ lẹ́ẹ̀méjì ní ọ̀sẹ̀, mo ń san ìdámẹ́wàá ohun gbogbo tí mo ní.’
اما آن باجگیر دور ایستاده نخواست چشمان خود را به سوی آسمان بلند کند بلکه به سینه خود زده گفت، خدایا بر من گناهکار ترحم فرما. ۱۳ 13
“Ṣùgbọ́n agbowó òde dúró lókèèrè, kò tilẹ̀ jẹ́ gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run, ṣùgbọ́n ó lu ara rẹ̀ ní oókan àyà, ó wí pé, ‘Ọlọ́run ṣàánú fún mi, èmi ẹlẹ́ṣẹ̀!’
به شمامی گویم که این شخص، عادل کرده شده به خانه خود رفت به خلاف آن دیگر، زیرا هر‌که خود رابرافرازد، پست گردد و هرکس خویشتن را فروتن سازد، سرافرازی یابد.» ۱۴ 14
“Mo wí fún yín, ọkùnrin yìí sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀ ní ìdáláre ju èkejì lọ: nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, òun ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹni tí ó bá sì rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ òun ni a ó gbéga.”
پس اطفال را نیز نزد وی آوردند تا دست برایشان گذارد. اما شاگردانش چون دیدند، ایشان رانهیب دادند. ۱۵ 15
Wọ́n sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn; ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rí i, wọ́n ń bá wọn wí.
ولی عیسی ایشان را خوانده، گفت: «بچه‌ها را واگذارید تا نزد من آیند و ایشان را ممانعت مکنید، زیرا ملکوت خدا برای مثل اینها است. ۱۶ 16
Ṣùgbọ́n Jesu pè wọ́n sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọ kékeré wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má sì ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí tí irú wọn ni ìjọba Ọlọ́run.
هرآینه به شما می‌گویم هر‌که ملکوت خدا را مثل طفل نپذیرد داخل آن نگردد.» ۱۷ 17
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí kò bá gbà ìjọba Ọlọ́run bí ọmọ kékeré, kì yóò wọ inú rẹ̀ bí ó ti wù kí ó rí.”
و یکی از روسا از وی سوال نموده، گفت: «ای استاد نیکو چه کنم تا حیات جاودانی راوارث گردم؟» (aiōnios g166) ۱۸ 18
Ìjòyè kan sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, wí pé, “Olùkọ́ rere, kín ni èmi ó ṣe tí èmi ó fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
عیسی وی را گفت: «از بهر‌چه مرا نیکو می‌گویی و حال آنکه هیچ‌کس نیکونیست جز یکی که خدا باشد. ۱۹ 19
Jesu wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń pè mí ní ẹni rere? Ẹni rere kan kò sí bí kò ṣe ẹnìkan, èyí sì ni Ọlọ́run.
احکام رامی دانی زنا مکن، قتل مکن، دزدی منما، شهادت دروغ مده و پدر و مادر خود را محترم دار.» ۲۰ 20
Ìwọ mọ̀ àwọn òfin: ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà, ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jalè, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jẹ́rìí èké, bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ.’”
گفت: «جمیع اینها را از طفولیت خود نگاه داشته‌ام.» ۲۱ 21
Ó sì wí pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti pamọ́ láti ìgbà èwe mi wá.”
عیسی چون این را شنید بدو گفت: «هنوز تو را یک چیز باقی است. آنچه داری بفروش و به فقرا بده که در آسمان گنجی خواهی داشت، پس آمده مرا متابعت کن.» ۲۲ 22
Nígbà tí Jesu sì gbọ́ èyí, ó wí fún un pé, “Ohun kan ni ó kù fún ọ síbẹ̀: lọ ta ohun gbogbo tí o ní, kí o sì pín in fún àwọn tálákà, ìwọ ó sì ní ìṣúra ní ọ̀run: sì wá, kí o máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
چون این راشنید محزون گشت، زیرا که دولت فراوان داشت. ۲۳ 23
Nígbà tí ó sì gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, nítorí tí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
اما عیسی چون او را محزون دید گفت: «چه دشوار است که دولتمندان داخل ملکوت خداشوند. ۲۴ 24
Nígbà tí Jesu rí i pé inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, ó wí pé, “Yóò ti ṣòro tó fún àwọn tí ó ní ọrọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run!
زیرا گذشتن شتر از سوراخ سوزن آسانتر است از دخول دولتمندی در ملکوت خدا.» ۲۵ 25
Nítorí ó rọrùn fún ìbákasẹ láti gba ojú abẹ́rẹ́ wọlé jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run lọ.”
اما شنوندگان گفتند: «پس که می‌تواندنجات یابد؟» ۲۶ 26
Àwọn tí ó sì gbọ́ wí pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha lè là?”
او گفت: «آنچه نزد مردم محال است، نزد خدا ممکن است.» ۲۷ 27
Ó sì wí pé, “Ohun tí ó ṣòro lọ́dọ̀ ènìyàn kò ṣòro lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
پطرس گفت: «اینک ما همه‌چیز را ترک کرده پیروی تو می‌کنیم.» ۲۸ 28
Peteru sì wí pé, “Sá wò ó, àwa ti fi ilé wa sílẹ̀, a sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn!”
به ایشان گفت: «هرآینه به شما می‌گویم، کسی نیست که خانه یاوالدین یا زن یا برادران یا اولاد را بجهت ملکوت خدا ترک کند، ۲۹ 29
Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kò sí ẹni tí ó fi ilé, tàbí aya, tàbí ará, tàbí òbí, tàbí ọmọ sílẹ̀, nítorí ìjọba Ọlọ́run,
جز اینکه در این عالم چند برابربیابد و در عالم آینده حیات جاودانی را.» (aiōn g165, aiōnios g166) ۳۰ 30
tí kì yóò gba ìlọ́po púpọ̀ sí i ní ayé yìí, àti ní ayé tí ń bọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
پس آن دوازده را برداشته، به ایشان گفت: «اینک به اورشلیم می‌رویم و آنچه به زبان انبیادرباره پسر انسان نوشته شده است، به انجام خواهد رسید. ۳۱ 31
Nígbà náà ni ó pe àwọn méjìlá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Sá wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, a ó sì mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
زیرا که او را به امت‌ها تسلیم می‌کنند و استهزا و بی‌حرمتی کرده آب دهان بروی انداخته ۳۲ 32
Nítorí tí a ó fi lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́, a ó fi ṣe ẹlẹ́yà, a ó sì fi ṣe ẹ̀sín, a ó sì tutọ́ sí i lára.
و تازیانه زده او را خواهند کشت ودر روز سوم خواهد برخاست.» ۳۳ 33
Wọn ó sì nà án, wọn ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.”
اما ایشان چیزی از این امور نفهمیدند و این سخن از ایشان مخفی داشته شد و آنچه می‌گفت، درک نکردند. ۳۴ 34
Ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò sì yé wọn, ọ̀rọ̀ yìí sì pamọ́ fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ ohun tí a wí.
و چون نزدیک اریحا رسید، کوری بجهت گدایی بر سر راه نشسته بود. ۳۵ 35
Bí ó ti súnmọ́ Jeriko, afọ́jú kan jókòó lẹ́bàá ọ̀nà ó ń ṣagbe.
و چون صدای گروهی را که می‌گذشتند شنید، پرسید چه چیزاست؟ ۳۶ 36
Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ ń kọjá lọ, ó béèrè pé, kín ni ìtumọ̀ èyí.
گفتندش عیسی ناصری در گذر است. ۳۷ 37
Wọ́n sì wí fún un pé, “Jesu ti Nasareti ni ó ń kọjá lọ.”
در حال فریاد برآورده گفت: «ای عیسی، ای پسر داود، بر من ترحم فرما.» ۳۸ 38
Ó sì kígbe pé, “Jesu, ìwọ ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
و هرچند آنانی که پیش می‌رفتند او را نهیب می‌دادند تا خاموش شود، او بلندتر فریاد می‌زد که پسر داودا بر من ترحم فرما. ۳۹ 39
Àwọn tí ń lọ níwájú bá a wí, pé, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n òun sì kígbe sókè sí í pé, “Ìwọ Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
آنگاه عیسی ایستاده فرمود تا او رانزد وی بیاورند. و چون نزدیک شد از وی پرسیده، ۴۰ 40
Jesu sì dúró, ó ní, kí á mú un tọ òun wá nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn, ó bi í
گفت: «چه می‌خواهی برای توبکنم؟» عرض کرد: «ای خداوند، تا بینا شوم.» ۴۱ 41
wí pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe fún ọ?” Ó sì wí pé, “Olúwa jẹ́ kí èmi ríran.”
عیسی به وی گفت: «بینا شو که ایمانت تو راشفا داده است.» ۴۲ 42
Jesu sì wí fún un pé, “Ríran; ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
در ساعت بینایی یافته، خدا راتمجید‌کنان از عقب او افتاد و جمیع مردم چون این را دیدند، خدا را تسبیح خواندند. ۴۳ 43
Lójúkan náà ó sì ríran, ó sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo àti gbogbo ènìyàn nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n fi ìyìn fún Ọlọ́run.

< لوقا 18 >