< یوشع 1 >

و واقع شد بعد از وفات موسی، بنده خداوند، که خداوند یوشع بن نون، خادم موسی را خطاب کرده، گفت: ۱ 1
Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
«موسی بنده من وفات یافته است، پس الان برخیز و از این اردن عبور کن، تو و تمامی این قوم، به زمینی که من به ایشان، یعنی به بنی‌اسرائیل می‌دهم. ۲ 2
“Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
هر جایی که کف پای شما گذارده شود به شما داده‌ام، چنانکه به موسی گفتم. ۳ 3
Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
از صحرا و این لبنان تانهر بزرگ یعنی نهر فرات، تمامی زمین حتیان و تادریای بزرگ به طرف مغرب آفتاب، حدود شماخواهد بود. ۴ 4
Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
هیچکس را در تمامی ایام عمرت یارای مقاومت با تو نخواهد بود. چنانکه با موسی بودم با تو خواهم بود، تو را مهمل نخواهم گذاشت و ترک نخواهم نمود. ۵ 5
Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
قوی و دلیر باش، زیرا که تو این قوم را متصرف، زمینی که برای پدران ایشان قسم خوردم که به ایشان بدهم، خواهی ساخت. ۶ 6
“Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
فقط قوی و بسیار دلیر باش تابرحسب تمامی شریعتی که بنده من، موسی تو راامر کرده است متوجه شده، عمل نمایی. زنهار ازآن به طرف راست یا چپ تجاوز منما تا هر جایی که روی، کامیاب شوی. ۷ 7
Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
این کتاب تورات ازدهان تو دور نشود، بلکه روز و شب در آن تفکرکن تا برحسب هر‌آنچه در آن مکتوب است متوجه شده، عمل نمایی زیرا همچنین راه خود را فیروز خواهی ساخت، و همچنین کامیاب خواهی شد. ۸ 8
Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
آیا تو را امر نکردم؟ پس قوی ودلیر باش، مترس و هراسان مباش زیرا در هر جاکه بروی یهوه خدای تو، با توست.» ۹ 9
Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
پس یوشع روسای قوم را امر فرموده، گفت: ۱۰ 10
Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
«در میان لشکرگاه بگذرید و قوم را امرفرموده، بگویید: برای خود توشه حاضر کنید، زیرا که بعد از سه روز، شما از این اردن عبورکرده، داخل خواهید شد تا تصرف کنید در زمینی که یهوه خدای شما، به شما برای ملکیت می‌دهد.» ۱۱ 11
“Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
و یوشع روبینیان و جادیان و نصف سبطمنسی را خطاب کرده، گفت: ۱۲ 12
Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
«بیاد آورید آن سخن را که موسی، بنده خداوند، به شما امرفرموده، گفت: یهوه، خدای شما به شما آرامی می‌دهد و این زمین را به شما می‌بخشد. ۱۳ 13
“Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
زنان واطفال و مواشی شما در زمینی که موسی در آن طرف اردن به شما داد خواهند ماند، و اما شمامسلح شده، یعنی جمیع مردان جنگی پیش روی برادران خود عبور کنید، و ایشان را اعانت نمایید. ۱۴ 14
Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
تا خداوند برادران شما را مثل شما آرامی داده باشد، و ایشان نیز در زمینی که یهوه، خدای شمابه ایشان می‌دهد تصرف کرده باشند، آنگاه به زمین ملکیت خود خواهید برگشت و متصرف خواهید شد، در آن که موسی، بنده خداوند به آن طرف اردن به سوی مشرق آفتاب به شما داد.» ۱۵ 15
títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
ایشان در جواب یوشع گفتند: «هر‌آنچه به ما فرمودی خواهیم کرد، و هر جا ما را بفرستی، خواهیم رفت. ۱۶ 16
Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
چنانکه موسی را در هر چیزاطاعت نمودیم، تو را نیز اطاعت خواهیم نمود، فقط یهوه، خدای تو، با تو باشد چنانکه با موسی بود. ۱۷ 17
Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
هر کسی‌که از حکم تو رو گرداند و کلام تو را در هر چیزی که او را امر فرمایی اطاعت نکند، کشته خواهد شد، فقط قوی و دلیر باش.» ۱۸ 18
Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”

< یوشع 1 >