< یوحنا 3 >
و شخصی از فریسیان نیقودیموس نام ازروسای یهود بود. | ۱ 1 |
Ọkùnrin kan sì wà nínú àwọn Farisi, tí a ń pè ní Nikodemu, ìjòyè kan láàrín àwọn Júù.
او در شب نزد عیسی آمده، به وی گفت: «ای استاد میدانیم که تو معلم هستی که از جانب خدا آمدهای زیرا هیچکس نمی تواند معجزاتی را که تو مینمایی بنماید، جزاینکه خدا با وی باشد.» | ۲ 2 |
Òun náà ní ó tọ Jesu wá ní òru, ó sì wí fún un pé, Rabbi, àwa mọ̀ pé olùkọ́ni láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ìwọ ń ṣe, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè ṣe iṣẹ́ àmì wọ̀nyí tí ìwọ ń ṣe, bí kò ṣe pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
عیسی در جواب اوگفت: «آمین آمین به تو میگویم اگر کسی از سر نومولود نشود، ملکوت خدا را نمی تواند دید.» | ۳ 3 |
Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a tún ènìyàn bí, òun kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.”
نیقودیموس بدو گفت: «چگونه ممکن است که انسانی که پیر شده باشد، مولود گردد؟ آیا میشودکه بار دیگر داخل شکم مادر گشته، مولود شود؟» | ۴ 4 |
Nikodemu wí fún un pé, a ó ti ṣe lè tún ènìyàn bí nígbà tí ó di àgbàlagbà tan? Ó ha lè wọ inú ìyá rẹ̀ lọ nígbà kejì, kí a sì bí i?
عیسی در جواب گفت: «آمین، آمین به تومی گویم اگر کسی از آب و روح مولود نگردد، ممکن نیست که داخل ملکوت خدا شود. | ۵ 5 |
Jesu dáhùn wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a fi omi àti Ẹ̀mí bí ènìyàn, òun kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.
آنچه از جسم مولود شد، جسم است و آنچه از روح مولود گشت روح است. | ۶ 6 |
Èyí tí a bí nípa ti ara, ti ara ni; èyí tí a sì bí nípa ti Ẹ̀mí, ti Ẹ̀mí ni.
عجب مدار که به توگفتم باید شما از سر نو مولود گردید. | ۷ 7 |
Kí ẹnu kí ó má ṣe yà ọ́, nítorí mo wí fún ọ pé, ‘A kò lè ṣe aláìtún yín bí.’
باد هرجاکه میخواهد میوزد و صدای آن را میشنوی لیکن نمی دانی از کجا میآید و به کجا میرود. همچنین است هرکه از روح مولود گردد.» | ۸ 8 |
Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí ibi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”
نیقودیموس در جواب وی گفت: «چگونه ممکن است که چنین شود؟» | ۹ 9 |
Nikodemu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”
عیسی در جواب وی گفت: «آیا تو معلم اسرائیل هستی و این رانمی دانی؟ | ۱۰ 10 |
Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Israẹli ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?
آمین، آمین به تو میگویم آنچه میدانیم، میگوییم و به آنچه دیدهایم، شهادت میدهیم و شهادت ما را قبول نمی کنید. | ۱۱ 11 |
Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.
چون شما را از امور زمینی سخن گفتم، باور نکردید. پس هرگاه به امور آسمانی با شما سخن رانم چگونه تصدیق خواهید نمود؟ | ۱۲ 12 |
Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?
و کسی به آسمان بالا نرفت مگر آن کس که از آسمان پایین آمد یعنی پسر انسان که در آسمان است. | ۱۳ 13 |
Kò sì ṣí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.
وهمچنانکه موسی مار را در بیابان بلند نمود، همچنین پسر انسان نیز باید بلند کرده شود، | ۱۴ 14 |
Bí Mose sì ti gbé ejò sókè ní aginjù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ Ènìyàn sókè pẹ̀lú.
تاهرکه به او ایمان آرد هلاک نگردد، بلکه حیات جاودانی یابد. (aiōnios ) | ۱۵ 15 |
Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios )
زیرا خدا جهان را اینقدر محبت نمود که پسر یگانه خود را داد تا هرکه بر او ایمان آورد هلاک نگردد بلکه حیات جاودانی یابد. (aiōnios ) | ۱۶ 16 |
“Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
زیرا خدا پسر خود را در جهان نفرستاد تا برجهان داوری کند، بلکه تا به وسیله او جهان نجات یابد. | ۱۷ 17 |
Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.
آنکه به او ایمان آرد، بر او حکم نشود؛ اما هرکه ایمان نیاورد الان بر او حکم شده است، بجهت آنکه به اسم پسر یگانه خدا ایمان نیاورده. | ۱۸ 18 |
Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.
و حکم این است که نور در جهان آمدو مردم ظلمت را بیشتر از نور دوست داشتند، ازآنجا که اعمال ایشان بد است. | ۱۹ 19 |
Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.
زیرا هرکه عمل بد میکند، روشنی را دشمن دارد و پیش روشنی نمی آید، مبادا اعمال او توبیخ شود. | ۲۰ 20 |
Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú ní ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kì í sì í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.
و لیکن کسیکه به راستی عمل میکند پیش روشنی میآید تا آنکه اعمال او هویدا گردد که در خداکرده شده است.» | ۲۱ 21 |
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ ní í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
و بعد از آن عیسی با شاگردان خود به زمین یهودیه آمد و با ایشان در آنجا بهسر برده، تعمیدمی داد. | ۲۲ 22 |
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Judea; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
و یحیی نیز در عینون، نزدیک سالیم تعمید میداد زیرا که در آنجا آب بسیار بود ومردم میآمدند و تعمید میگرفتند، | ۲۳ 23 |
Johanu pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Aenoni, ní agbègbè Salimu, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀, wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọ omi.
چونکه یحیی هنوز در زندان حبس نشده بود. | ۲۴ 24 |
(Nítorí tí a kò tí ì sọ Johanu sínú túbú).
آنگاه در خصوص تطهیر، در میان شاگردان یحیی ویهودیان مباحثه شد. | ۲۵ 25 |
Nígbà náà ni iyàn kan wà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.
پس به نزد یحیی آمده، به او گفتند: «ای استاد، آن شخصی که با تو درآنطرف اردن بود و تو برای او شهادت دادی، اکنون او تعمید میدهد و همه نزد اومی آیند.» | ۲۶ 26 |
Wọ́n sì tọ Johanu wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rabbi, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jordani, tí ìwọ ti jẹ́rìí rẹ̀, wò ó, òun tẹ àwọn ènìyàn bọ omi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”
یحیی در جواب گفت: «هیچکس چیزی نمی تواند یافت، مگر آنکه از آسمان بدو داده شود. | ۲۷ 27 |
Johanu dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí nǹkan kan gbà, bí kò ṣe pé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.
شما خود بر من شاهد هستید که گفتم من مسیح نیستم بلکه پیش روی او فرستاده شدم. | ۲۸ 28 |
Ẹ̀yin fúnra yín jẹ́rìí mi pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kristi náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi síwájú rẹ̀.’
کسیکه عروس دارد داماد است، اما دوست داماد که ایستاده آواز او را میشنود، از آواز دامادبسیار خشنود میگردد. پس این خوشی من کامل گردید. | ۲۹ 29 |
Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.
میباید که او افزوده شود و من ناقص گردم. | ۳۰ 30 |
Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàìmá rẹlẹ̀.
او که از بالا میآید، بالای همه است وآنکه از زمین است زمینی است و از زمین تکلم میکند؛ اما او که از آسمان میآید، بالای همه است. | ۳۱ 31 |
“Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.
و آنچه را دید و شنید، به آن شهادت میدهد و هیچکس شهادت او را قبول نمی کند. | ۳۲ 32 |
Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.
و کسیکه شهادت اورا قبول کرد، مهر کرده است بر اینکه خدا راست است. | ۳۳ 33 |
Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olóòtítọ́ ni Ọlọ́run.
زیرا آن کسی را که خدا فرستاد، به کلام خدا تکلم مینماید، چونکه خدا روح را به میزان عطا نمی کند. | ۳۴ 34 |
Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.
پدرپسر را محبت مینماید و همهچیز را بدست اوسپرده است. | ۳۵ 35 |
Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́.
آنکه به پسر ایمان آورده باشد، حیات جاودانی دارد و آنکه به پسر ایمان نیاوردحیات را نخواهد دید، بلکه غضب خدا بر اومی ماند.» (aiōnios ) | ۳۶ 36 |
Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun, ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè, nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.” (aiōnios )