< ایّوب 1 >
در زمین عوص، مردی بود که ایوب نام داشت و آن مرد کامل و راست و خداترس بود و از بدی اجتناب مینمود. | ۱ 1 |
Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
و برای او، هفت پسر و سه دختر زاییده شدند. | ۲ 2 |
A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
و اموال او هفت هزار گوسفند و سه هزار شتر و پانصد جفت گاو وپانصد الاغ ماده بود و نوکران بسیار کثیر داشت وآن مرد از تمامی بنی مشرق بزرگتر بود. | ۳ 3 |
Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
و پسرانش میرفتند و در خانه هر یکی ازایشان، در روزش مهمانی میکردند و فرستاده، سه خواهر خود را دعوت مینمودند تا با ایشان اکل و شرب بنمایند. | ۴ 4 |
Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
و واقع میشد که چون دوره روزهای مهمانیایشان بسر میرفت، ایوب فرستاده، ایشان را تقدیس مینمود و بامدادان برخاسته، قربانی های سوختنی، به شماره همه ایشان میگذرانید، زیرا ایوب میگفت: «شایدپسران من گناه کرده، خدا را در دل خود ترک نموده باشند» و ایوب همیشه چنین میکرد. | ۵ 5 |
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
و روزی واقع شد که پسران خدا آمدند تا به حضور خداوند حاضر شوند و شیطان نیز در میان ایشان آمد. | ۶ 6 |
Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
و خداوند به شیطان گفت: «از کجاآمدی؟» شیطان در جواب خداوند گفت: «ازتردد کردن در زمین و سیر کردن در آن.» | ۷ 7 |
Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
خداوندبه شیطان گفت: «آیا در بنده من ایوب تفکر کردی که مثل او در زمین نیست؟ مرد کامل وراست و خداترس که از گناه اجتناب میکند.» | ۸ 8 |
Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
شیطان در جواب خداوند گفت: «آیا ایوب مجان از خدا میترسد؟ | ۹ 9 |
Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
آیا تو گرد او و گردخانه او و گرد همه اموال او، به هر طرف حصارنکشیدی و اعمال دست او را برکت ندادی ومواشی او در زمین منتشر نشد؟ | ۱۰ 10 |
“Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
لیکن الان دست خود را دراز کن و تمامی مایملک او رالمس نما و پیش روی تو، تو را ترک خواهدنمود.» | ۱۱ 11 |
Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
خداوند به شیطان گفت: «اینک همه اموالش در دست تو است، لیکن دستت را بر خوداو دراز مکن.» پس شیطان از حضور خداوندبیرون رفت. | ۱۲ 12 |
Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
و روزی واقع شد که پسران و دخترانش درخانه برادر بزرگ خود میخوردند و شراب مینوشیدند. | ۱۳ 13 |
Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
و رسولی نزد ایوب آمده، گفت: «گاوان شیار میکردند و ماده الاغان نزد آنهامی چریدند. | ۱۴ 14 |
oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
و سابیان بر آنها حمله آورده، بردند و جوانان را به دم شمشیر کشتند و من به تنهایی رهایی یافتم تا تو را خبر دهم.» | ۱۵ 15 |
àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
و اوهنوز سخن میگفت که دیگری آمده، گفت: «آتش خدا از آسمان افتاد و گله و جوانان راسوزانیده، آنها را هلاک ساخت و من به تنهایی رهایی یافتم تا تو را خبر دهم.» | ۱۶ 16 |
Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
و او هنوزسخن میگفت که دیگری آمده، گفت: «کلدانیان سه فرقه شدند و بر شتران هجوم آورده، آنها را بردند و جوانان را به دم شمشیر کشتند و من به تنهایی رهایی یافتم تا تو را خبر دهم.» | ۱۷ 17 |
Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
و اوهنوز سخن میگفت که دیگری آمده، گفت: «پسران و دخترانت در خانه برادر بزرگ خودمی خوردند و شراب مینوشیدند | ۱۸ 18 |
Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
که اینک بادشدیدی از طرف بیابان آمده، چهار گوشه خانه رازد و بر جوانان افتاد که مردند و من به تنهایی رهایی یافتم تا تو را خبر دهم.» | ۱۹ 19 |
Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
آنگاه ایوب برخاسته، جامه خود را درید وسر خود را تراشید و به زمین افتاده، سجده کرد | ۲۰ 20 |
Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
و گفت: «برهنه از رحم مادر خود بیرون آمدم وبرهنه به آنجا خواهم برگشت؛ خداوند داد وخداوند گرفت و نام خداوند متبارک باد.» | ۲۱ 21 |
wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
دراین همه، ایوب گناه نکرد و به خدا جهالت نسبت نداد. | ۲۲ 22 |
Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.