< ارمیا 30 >

کلامی که از جانب خداوند بر ارمیا نازل شده، گفت: ۱ 1
Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
«یهوه خدای اسرائیل تکلم نموده، چنین می‌گوید: تمامی سخنانی را که من به تو گفته‌ام، در طوماری بنویس. ۲ 2
“Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
زیراخداوند می‌گوید: اینک ایامی می‌آید که اسیران قوم خود اسرائیل و یهودا را باز خواهم آورد وخداوند می‌گوید: ایشان را به زمینی که به پدران ایشان داده‌ام، باز خواهم رسانید تا آن را به تصرف آورند.» ۳ 3
Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
و این است کلامی که خداوند درباره اسرائیل و یهودا گفته است. ۴ 4
Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
زیرا خداوند چنین می‌گوید: «صدای ارتعاش شنیدیم. خوف است وسلامتی نی. ۵ 5
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
سوال کنید و ملاحظه نمایید که آیاذکور اولاد می‌زاید؟ پس چرا هر مرد را می‌بینم که مثل زنی که می‌زاید دست خود را بر کمرش نهاده و همه چهره‌ها به زردی مبدل شده است؟» ۶ 6
Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
وای بر ما زیرا که آن روز، عظیم است و مثل آن دیگری نیست و آن زمان تنگی یعقوب است اما از آن نجات خواهد یافت. ۷ 7
Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
و یهوه صبایوت می‌گوید: «هر آینه در آن روز یوغ او را از گردنت خواهم شکست وبندهای تو را خواهم گسیخت. و غریبان بار دیگراو را بنده خود نخواهند ساخت. ۸ 8
“‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
و ایشان خدای خود یهوه و پادشاه خویش داود را که برای ایشان برمی انگیزانم خدمت خواهند کرد. ۹ 9
Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
پس خداوند می‌گوید که‌ای بنده من یعقوب مترس وای اسرائیل هراسان مباش زیرا اینک من تو را از جای دور و ذریت تو را از زمین اسیری ایشان خواهم رهانید و یعقوب مراجعت نموده، دررفاهیت و امنیت خواهد بود و کسی او را نخواهدترسانید. ۱۰ 10
“‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
زیرا خداوند می‌گوید: من با تو هستم تا تو را نجات‌بخشم و جمیع امت‌ها را که تو را درمیان آنها پراکنده ساختم، تلف خواهم کرد. اما تورا تلف نخواهم نمود، بلکه تو را به انصاف تادیب خواهم کرد و تو را بی‌سزا نخواهم گذاشت. ۱۱ 11
Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
زیرا خداوند چنین می‌گوید: جراحت توعلاج ناپذیر و ضربت تو مهلک می‌باشد. ۱۲ 12
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
کسی نیست که دعوی تو را فیصل دهد تا التیام یابی وبرایت دواهای شفابخشنده‌ای نیست. ۱۳ 13
Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
جمیع دوستانت تو را فراموش کرده، درباره تواحوال پرسی نمی نمایند زیرا که تو را به صدمه دشمن و به تادیب بیرحمی به‌سبب کثرت عصیانت و زیادتی گناهانت مبتلا ساخته‌ام. ۱۴ 14
Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
چرا درباره جراحت خود فریاد می‌نمایی؟ دردتو علاج ناپذیر است. به‌سبب زیادتی عصیانت وکثرت گناهانت این کارها را به تو کرده‌ام. ۱۵ 15
Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
«بنابراین آنانی که تو را می‌بلعند، بلعیده خواهند شد و آنانی که تو را به تنگ می‌آورند، جمیع به اسیری خواهند رفت. و آنانی که تو راتاراج می‌کنند، تاراج خواهند شد و همه غارت کنندگانت را به غارت تسلیم خواهم کرد. ۱۶ 16
“‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
زیرا خداوند می‌گوید: به تو عافیت خواهم رسانید و جراحات تو را شفا خواهم داد، از این جهت که تو را (شهر) متروک می‌نامند (ومی گویند) که این صهیون است که احدی درباره آن احوال پرسی نمی کند. ۱۷ 17
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
خداوند چنین می‌گوید: اینک خیمه های اسیری یعقوب را بازخواهم آورد و به مسکنهایش ترحم خواهم نمودو شهر بر تلش بنا شده، قصرش برحسب عادت خود مسکون خواهد شد. ۱۸ 18
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
و تسبیح و آوازمطربان از آنها بیرون خواهد آمد و ایشان راخواهم افزود و کم نخواهند شد و ایشان را معززخواهم ساخت و پست نخواهند گردید. ۱۹ 19
Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
وپسرانش مانند ایام پیشین شده، جماعتش درحضور من برقرار خواهند ماند و بر جمیع ستمگرانش عقوبت خواهم رسانید. ۲۰ 20
Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
و حاکم ایشان از خود ایشان بوده، سلطان ایشان از میان ایشان بیرون خواهد آمد و او را مقرب می‌گردانم تا نزدیک من بیاید زیرا خداوند می‌گوید: کیست که جرات کند نزد من آید؟ ۲۱ 21
Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
و شما قوم من خواهید بود و من خدای شما خواهم بود. ۲۲ 22
‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
اینک باد شدید خداوند با حدت غضب وگردبادهای سخت بیرون می‌آید که بر سر شریران هجوم آورد. ۲۳ 23
Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
تا خداوند تدبیرات دل خود رابجا نیاورد و استوار نفرماید، حدت خشم اونخواهد برگشت. در ایام آخر این را خواهیدفهمید.» ۲۴ 24
Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.

< ارمیا 30 >