< اشعیا 61 >

روح خداوند یهوه بر من است زیراخداوند مرا مسح کرده است تامسکینان را بشارت دهم و مرا فرستاده تا شکسته دلان را التیام بخشم و اسیران را به رستگاری ومحبوسان را به آزادی ندا کنم. ۱ 1
Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
و تا از سال پسندیده خداوند و از یوم انتقام خدای ما ندانمایم و جمیع ماتمیان را تسلی بخشم. ۲ 2
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
تا قراردهم برای ماتمیان صهیون و به ایشان ببخشم تاجی را به عوض خاکستر و روغن شادمانی را به عوض نوحه گری و ردای تسبیح را به‌جای روح کدورت تا ایشان درختان عدالت و مغروس خداوند به جهت تمجید وی نامیده شوند. ۳ 3
àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
و ایشان خرابه های قدیم را بنا خواهند نمودو ویرانه های سلف را بر پا خواهند داشت وشهرهای خراب شده و ویرانه های دهرهای بسیار را تعمیر خواهند نمود. ۴ 4
Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
و غریبان برپاشده، غله های شما را خواهند چرانید و بیگانگان، فلاحان و باغبانان شما خواهند بود. ۵ 5
Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
و شماکاهنان خداوند نامیده خواهید شد و شما را به خدام خدای ما مسمی خواهند نمود. دولت امت‌ها را خواهید خورد و در جلال ایشان فخرخواهید نمود. ۶ 6
A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
به عوض خجالت، نصیب مضاعف خواهید یافت و به عوض رسوایی ازنصیب خود مسرور خواهند شد بنابراین ایشان درزمین خود نصیب مضاعف خواهند یافت و شادی جاودانی برای ایشان خواهد بود. ۷ 7
Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
زیرا من که یهوه هستم عدالت را دوست می‌دارم و از غارت و ستم نفرت می‌دارم و اجرت ایشان را به راستی به ایشان خواهم داد و عهد جاودانی با ایشان خواهم بست. ۸ 8
“Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
و نسل ایشان در میان امت‌ها وذریت ایشان در میان قوم‌ها معروف خواهند شد. هر‌که ایشان را بیند اعتراف خواهد نمود که ایشان ذریت مبارک خداوند می‌باشند. ۹ 9
A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
در خداوند شادی بسیار می‌کنم و جان من در خدای خود وجد می‌نماید زیرا که مرا به‌جامه نجات ملبس ساخته، ردای عدالت را به من پوشانید. چنانکه داماد خویشتن را به تاج آرایش می‌دهد و عروس، خود را به زیورها زینت می‌بخشد. ۱۰ 10
Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
زیرا چنانکه زمین، نباتات خود رامی رویاند و باغ، زرع خویش را نمو می‌دهد، همچنان خداوند یهوه عدالت و تسبیح را پیش روی تمامی امت‌ها خواهد رویانید. ۱۱ 11
Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.

< اشعیا 61 >