< اشعیا 14 >

زیرا خداوند بر یعقوب ترحم فرموده، اسرائیل را بار دیگر خواهد برگزید وایشان را در زمینشان آرامی خواهد داد. و غربا باایشان ملحق شده، با خاندان یعقوب ملصق خواهند گردید. ۱ 1
Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
و قوم‌ها ایشان را برداشته، به مکان خودشان خواهند‌آورد. و خاندان اسرائیل ایشان را در زمین خداوند برای بندگی و کنیزی، مملوک خود خواهند ساخت. و اسیرکنندگان خود را اسیر کرده، بر ستمکاران خویش حکمرانی خواهند نمود. ۲ 2
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
و در روزی که خداوند تو را از الم واضطرابت و بندگی سخت که بر تو می‌نهادندخلاصی بخشد واقع خواهد شد، ۳ 3
Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
که این مثل رابر پادشاه بابل زده، خواهی گفت: چگونه آن ستمکار تمام شد و آن جور پیشه چگونه فانی گردید. ۴ 4
ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
خداوند عصای شریران و چوگان حاکمان را شکست. ۵ 5
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
آنکه قوم‌ها را به خشم باصدمه متوالی می‌زد و بر امت‌ها به غضب با جفای بیحد حکمرانی می‌نمود، ۶ 6
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
تمامی زمین آرام شده و ساکت گردیده‌اند و به آواز بلند ترنم می‌نمایند. ۷ 7
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
صنوبرها نیز و سروهای آزاد لبنان درباره توشادمان شده، می‌گویند: «از زمانی که توخوابیده‌ای قطع کننده‌ای بر ما برنیامده است.» ۸ 8
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
هاویه از زیر برای تو متحرک است تا چون بیایی تو را استقبال نماید، و مردگان یعنی جمیع بزرگان زمین را برای تو بیدار می‌سازد. و جمیع پادشاهان امت‌ها را از کرسیهای ایشان برمی دارد. (Sheol h7585) ۹ 9
Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol h7585)
جمیع اینها تو را خطاب کرده، می‌گویند: «آیاتو نیز مثل ما ضعیف شده‌ای و مانند ماگردیده‌ای.» ۱۰ 10
Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
جلال تو و صدای بربطهای تو به هاویه فرود شده است. کرمها زیر تو گسترانیده شده و مورها تو را می‌پوشانند. (Sheol h7585) ۱۱ 11
Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol h7585)
‌ای زهره دخترصبح چگونه از آسمان افتاده‌ای؟ ای که امت‌ها راذلیل می‌ساختی چگونه به زمین افکنده شده‌ای؟ ۱۲ 12
Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
و تو در دل خود می‌گفتی: «به آسمان صعودنموده، کرسی خود را بالای ستارگان خدا خواهم افراشت. و بر کوه اجتماع در اطراف شمال جلوس خواهم نمود. ۱۳ 13
Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
بالای بلندیهای ابرها صعود کرده، مثل حضرت اعلی خواهم شد.» ۱۴ 14
Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
لکن به هاویه به اسفلهای حفره فرود خواهی شد. (Sheol h7585) ۱۵ 15
Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol h7585)
آنانی که تو را بینند بر تو چشم دوخته و درتو تامل نموده، خواهند گفت: «آیا این آن مرداست که جهان را متزلزل و ممالک را مرتعش می‌ساخت؟ ۱۶ 16
Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
که ربع مسکون را ویران می‌نمودو شهرهایش را منهدم می‌ساخت و اسیران خودرا به خانه های ایشان رها نمی کرد؟» ۱۷ 17
Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
همه پادشاهان امت‌ها جمیع هر یک در خانه خود با جلال می‌خوابند. ۱۸ 18
Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
اما تو از قبر خودبیرون افکنده می‌شوی و مثل شاخه مکروه ومانند لباس کشتگانی که با شمشیر زده شده باشند، که به سنگهای حفره فرو می‌روند و مثل لاشه پایمال شده. ۱۹ 19
Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
با ایشان در دفن متحدنخواهی بود چونکه زمین خود را ویران کرده، قوم خویش را کشته‌ای. ذریت شریران تا به ابد مذکورنخواهند شد. ۲۰ 20
a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
برای پسرانش به‌سبب گناه پدران ایشان قتل را مهیا سازید، تا ایشان برنخیزند و در زمین تصرف ننمایند و روی ربع مسکون را از شهرها پر نسازند. ۲۱ 21
Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
و یهوه صبایوت می‌گوید: «من به ضدایشان خواهم برخاست.» و خداوند می‌گوید: «اسم و بقیه را و نسل و ذریت را از بابل منقطع خواهم ساخت. ۲۲ 22
“Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
و آن را نصیب خارپشتها و خلابهای آب خواهم گردانید و آن رابا جاروب هلاکت خواهم رفت.» یهوه صبایوت می‌گوید. ۲۳ 23
Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
یهوه صبایوت قسم خورده، می‌گوید: «یقین به طوری که قصد نموده‌ام همچنان واقع خواهد شد. و به نهجی که تقدیر کرده‌ام همچنان بجا آورده خواهد گشت. ۲۴ 24
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
و آشور را در زمین خودم خواهم شکست و او را بر کوههای خویش پایمال خواهم کرد. و یوغ او از ایشان رفع شده، بار وی از گردن ایشان برداشته خواهد شد.» ۲۵ 25
Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
تقدیری که بر تمامی زمین مقدر گشته، این است. و دستی که بر جمیع امت‌ها دراز شده، همین است. ۲۶ 26
Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
زیرا که یهوه صبایوت تقدیرنموده است، پس کیست که آن را باطل گرداند؟ ودست اوست که دراز شده است پس کیست که آن را برگرداند؟ ۲۷ 27
Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
در سالی که آحاز پادشاه مرد این وحی نازل شد: ۲۸ 28
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
‌ای جمیع فلسطین شادی مکن از اینکه عصایی که تو را می‌زد شکسته شده است. زیرا که از ریشه مار افعی بیرون می‌آید و نتیجه او اژدهای آتشین پرنده خواهد بود. ۲۹ 29
Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
و نخست زادگان مسکینان خواهند چرید و فقیران در اطمینان خواهند خوابید. و ریشه تو را با قحطی خواهم کشت و باقی ماندگان تو مقتول خواهند شد. ۳۰ 30
Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
‌ای دروازه ولوله نما! و‌ای شهر فریاد برآور! ای تمامی فلسطین تو گداخته خواهی شد. زیراکه از طرف شمال دود می‌آید و از صفوف وی کسی دور نخواهد افتاد. ۳۱ 31
Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
پس به رسولان امت هاچه جواب داده شود: «اینکه خداوند صهیون رابنیاد نهاده است و مسکینان قوم وی در آن پناه خواهند برد.» ۳۲ 32
Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”

< اشعیا 14 >