< خروج 16 >

پس تمامی جماعت بنی‌اسرائیل ازایلیم کوچ کرده، به صحرای سین که درمیان ایلیم و سینا است در روز پانزدهم از ماه دوم، بعد از بیرون آمدن ایشان از زمین مصر، رسیدند. ۱ 1
Ìjọ àwọn ọmọ Israẹli mú ọ̀nà wọn pọ̀n kúrò ni Elimu, wọ́n dé sí ijù Sini tí ó wà láàrín Elimu àti Sinai, ni ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kejì tí wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
و تمامی جماعت بنی‌اسرائیل در آن صحرا برموسی و هارون شکایت کردند. ۲ 2
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì ń kùn sí Mose àti Aaroni ní ijù náà.
و بنی‌اسرائیل بدیشان گفتند: «کاش که در زمین مصر به‌دست خداوند مرده بودیم، وقتی که نزد دیگهای گوشت می‌نشستیم و نان را سیر می‌خوردیم، زیراکه ما را بدین صحرا بیرون آوردید، تا تمامی این جماعت را به گرسنگی بکشید.» ۳ 3
Àwọn ọmọ Israẹli wí fún wọn pé, “Àwa ìbá ti ọwọ́ Olúwa kú ni Ejibiti! Níbi tí àwa ti jókòó ti ìkòkò ẹran ti a sì ń jẹ ohun gbogbo tí a fẹ́ ni àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹ̀yin mú wa wá sí inú ijù yìí láti fi ebi pa wá tí a ó fi kú.”
آنگاه خداوند به موسی گفت: «همانا من نان از آسمان برای شما بارانم، و قوم رفته، کفایت هرروز را در روزش گیرند، تا ایشان را امتحان کنم که بر شریعت من رفتار می‌کنند یا نه. ۴ 4
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò rọ òjò oúnjẹ láti ọ̀run wá fún yín. Àwọn ènìyàn yóò sì máa jáde lọ ni ọjọ́ kọ̀ọ̀kan láti kó ìwọ̀nba oúnjẹ ti ó tó fún oúnjẹ òòjọ́ wọn. Ní ọ̀nà yìí ni, èmi yóò fi dán wọn wò láti mọ bóyá wọn yóò máa tẹ̀lé ìlànà mi.
و واقع خواهد شد در روز ششم، که چون آنچه را که آورده باشند درست نمایند، همانا دوچندان آن خواهدبود که هر روز برمی چیدند.» ۵ 5
Ní ọjọ́ kẹfà, ki wọn kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń ko ni ojoojúmọ́ tẹ́lẹ̀.”
و موسی و هارون به همه بنی‌اسرائیل گفتند: «شامگاهان خواهیددانست که خداوند شما را از زمین مصر بیرون آورده است. ۶ 6
Mose àti Aaroni sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ní ìrọ̀lẹ́, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ni ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.
و بامدادان جلال خداوند راخواهید دید، زیرا که او شکایتی را که بر خداوندکرده‌اید شنیده است، و ما چیستیم که بر ماشکایت می‌کنید؟» ۷ 7
Ní òwúrọ̀, ẹ̀yin yóò ri ògo Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn tí ẹ kùn sí i. Ta ni àwa ti ẹ̀yin yóò máa kùn sí wa?”
و موسی گفت: «این خواهدبود چون خداوند، شامگاه شما را گوشت دهد تابخورید، و بامداد نان، تا سیر شوید، زیرا خداوندشکایتهای شما را که بر وی کرده‌اید شنیده است، و ما چیستیم؟ بر ما نی، بلکه بر خداوند شکایت نموده‌اید.» ۸ 8
Mose tún wí pé, “Ẹ̀yin yóò mọ pé Olúwa ni, nígbà ti ó bá fún un yín ni ẹran ni ìrọ̀lẹ́ àti gbogbo oúnjẹ ti ẹ̀yin ń fẹ́ ni òwúrọ̀, nítorí kíkùn ti ẹ̀yin ń kùn sí i. Ta ni àwa? Ẹ̀yin kò kùn sí àwa, Olúwa ni ẹ̀yin kùn sí i.”
و موسی به هارون گفت: «به تمامی جماعت بنی‌اسرائیل بگو به حضور خداوندنزدیک بیایید، زیرا که شکایتهای شما را شنیده است.» ۹ 9
Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pe, ‘Ẹ wá sí iwájú Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn yín.’”
و واقع شد که چون هارون به تمامی جماعت بنی‌اسرائیل سخن گفت، به سوی صحرانگریستند و اینک جلال خداوند در ابر ظاهر شد. ۱۰ 10
Ó sì ṣe bí Aaroni ti ń bá gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, wọn si bojú wo ìhà ijù, sì kíyèsi ògo Olúwa si farahàn ni àwọsánmọ̀.
و خداوند موسی را خطاب کرده، گفت: ۱۱ 11
Olúwa sọ fún Mose pé,
«شکایتهای بنی‌اسرائیل را شنیده‌ام، پس ایشان را خطاب کرده، بگو: در عصر گوشت خواهید خورد، و بامداد از نان سیر خواهید شد تابدانید که من یهوه خدای شما هستم.» ۱۲ 12
“Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
و واقع شد که در عصر، سلوی برآمده، لشکرگاه راپوشانیدند، و بامدادان شبنم گرداگرد اردونشست. ۱۳ 13
Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká.
و چون شبنمی که نشسته بودبرخاست، اینک بر روی صحرا چیزی دقیق، مدور و خرد، مثل ژاله بر زمین بود. ۱۴ 14
Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀.
و چون بنی‌اسرائیل این را دیدند به یکدیگر گفتند که این من است، زیرا که ندانستند چه بود. موسی به ایشان گفت: «این آن نان است که خداوند به شمامی دهد تا بخورید. ۱۵ 15
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, “Kí ni èyí?” Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe. Mose sì wí fún wọn pé, “Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.
این است امری که خداوندفرموده است، که هر کس به قدر خوراک خود ازاین بگیرد، یعنی یک عومر برای هر نفر به حسب شماره نفوس خویش، هر شخص برای کسانی که در خیمه او باشند بگیرد.» ۱۶ 16
Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ, ‘Kí olúkúlùkù máa kó èyí ti ó tó fún un láti jẹ. Ẹ mú òsùwọ̀n omeri kan fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ti ó wà nínú àgọ́ yín.’”
پس بنی‌اسرائیل چنین کردند، بعضی زیاد و بعضی کم برچیدند. ۱۷ 17
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí a ti sọ fún wọn; àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan kó kékeré.
اما چون به عومر پیمودند، آنکه زیاد برچیده بود، زیاده نداشت، و آنکه کم برچیده بود، کم نداشت، بلکه هر کس به قدر خوراکش برچیده بود. ۱۸ 18
Nígbà tí wọ́n fi òsùwọ̀n omeri wọ̀n-ọ́n, ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù. Ẹnìkọ̀ọ̀kan kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un.
و موسی بدیشان گفت: «زنهار کسی چیزی از این تا صبح نگاه ندارد.» ۱۹ 19
Mose sì wí fún wọ́n pé, “Kí ẹnikẹ́ni ó má ṣe kó pamọ́ lára rẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì.”
لکن به موسی گوش ندادند، بلکه بعضی چیزی از آن تا صبح نگاه داشتند. و کرمها بهم رسانیده، متعفن گردید، و موسی بدیشان خشمناک شد. ۲۰ 20
Ṣùgbọ́n, àwọn kan nínú wọn kò fetí sí Mose, wọ́n kó lára rẹ̀ pamọ́ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ohun ti wọ́n kó pamọ́ kún fún ìdin, ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní rùn. Nítorí náà Mose bínú sí wọn.
و هر صبح، هر کس به قدر خوراک خودبرمی چید، و چون آفتاب گرم می‌شد، می‌گداخت. ۲۱ 21
Ní òwúrọ̀, ni ojoojúmọ́ ni ẹnìkọ̀ọ̀kan ń lọ kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un láti jẹ, bí oòrùn bá sì mú, a sì yọ́.
و واقع شد در روز ششم که نان مضاعف، یعنی برای هر نفری دو عومر برچیدند. پس همه روسای جماعت آمده، موسی را خبردادند. ۲۲ 22
Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń kó tẹ́lẹ̀: òsùwọ̀n omeri méjì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan; àwọn olórí ìjọ ènìyàn sì wá, wọ́n sì sọ èyí fún Mose.
او بدیشان گفت: «این است آنچه خداوند گفت، که فردا آرامی است، و سبت مقدس خداوند. پس آنچه بر آتش باید پخت بپزید، و آنچه در آب باید جوشانید بجوشانید، وآنچه باقی باشد، برای خود ذخیره کرده، بجهت صبح نگاه دارید.» ۲۳ 23
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: ‘Ọ̀la jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ìsinmi mímọ́ fún Olúwa. Ẹ yan èyí ti ẹ̀yin ní yan, kí ẹ sì bọ èyí ti ẹ̀yin ní bọ̀. Ẹ tọ́jú èyí ti ó kù sílẹ̀, kí ẹ pa á mọ́ di òwúrọ̀.’”
پس آن را تا صبح ذخیره کردند، چنانکه موسی فرموده بود، و نه متعفن گردید و نه کرم در آن پیدا شد. ۲۴ 24
Wọ́n sì tọ́jú rẹ̀ di òwúrọ̀ bí Mose ti pàṣẹ; kò sì rùn bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní ìdin.
و موسی گفت: «امروز این را بخورید زیرا که امروز سبت خداوند است، و در این‌روز آن را در صحرانخواهید یافت. ۲۵ 25
Mose sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ ẹ́ ní òní nítorí òní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi Olúwa. Ẹ̀yin kò ni rí i ni orí ilẹ̀ ní ọjọ́ òní.
شش روز آن را برچینید، وروز هفتمین، سبت است. در آن نخواهد بود.» ۲۶ 26
Ní ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi kó o, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ keje ọjọ́ ìsinmi, kò ní sí i fún un yín ni ọjọ́ náà.”
و واقع شد که در روز هفتم، بعضی از قوم برای برچیدن بیرون رفتند، اما نیافتند. ۲۷ 27
Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ènìyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje láti kó o, ṣùgbọ́n wọn kò ri nǹkan kan kó.
و خداوند به موسی گفت: «تا به کی از نگاه داشتن وصایا وشریعت من ابا می‌نمایید؟ ۲۸ 28
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Yóò ti pẹ́ tó ti ẹ ó kọ̀ láti pa àṣẹ mi àti ìlànà mi mọ́?
ببینید چونکه خداوند سبت را به شما بخشیده است، از این سبب در روز ششم، نان دو روز را به شما می‌دهد، پس هر کس در جای خود بنشیند و در روز هفتم هیچ‌کس از مکانش بیرون نرود.» ۲۹ 29
Wò ó? Olúwa ti fún un yín ni ọjọ́ ìsinmi, nítorí náà, ni ọjọ́ kẹfà, ó fún un yín ni oúnjẹ ọjọ́ méjì; kí ẹnìkọ̀ọ̀kan dúró ni ibi tí ó gbé wà; kí ẹ má ṣe kúrò ni ibi tí ẹ wà ni ọjọ́ keje.”
پس قوم درروز هفتمین آرام گرفتند. ۳۰ 30
Nítorí náà, àwọn ènìyàn sinmi ní ọjọ́ keje.
و خاندان اسرائیل آن را من نامیدند، و آن مثل تخم گشنیز سفید بود، و طعمش مثل قرصهای عسلی. ۳۱ 31
Àwọn ènìyàn Israẹli sì pe oúnjẹ náà ní manna. Ó funfun bí irúgbìn korianderi, ó sì dùn bí àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ ti a fi oyin ṣe.
و موسی گفت: «این امری است که خداوند فرموده است که عومری از آن پرکنی، تا در نسلهای شما نگاه داشته شود، تا آن نان را ببینند که در صحرا، وقتی که شما را از زمین مصر بیرون آوردم، آن را به شما خورانیدم.» ۳۲ 32
Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, ‘Ẹ mú òsùwọ̀n omeri manna kí ẹ sì pa á mọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀, kí wọn kí ó lè rí oúnjẹ ti èmi fi fún un yín jẹ ní ijù, nígbà tí mo mú un yín jáde ni ilẹ̀ Ejibiti.’”
پس موسی به هارون گفت: «ظرفی بگیر، وعومری پر از من در آن بنه و آن را به حضورخداوند بگذار، تا در نسلهای شما نگاه داشته شود.» ۳۳ 33
Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó manna tí ó kún òsùwọ̀n omeri kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
چنانکه خداوند به موسی‌امر فرموده بود، همچنان هارون آن را پیش (تابوت ) شهادت گذاشت تا نگاه داشته شود. ۳۴ 34
Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, Aaroni gbé manna sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
و بنی‌اسرائیل مدت چهل سال من را می‌خوردند، تا به زمین آبادرسیدند، یعنی تا به‌سرحد زمین کنعان داخل شدند، خوراک ایشان من بود. ۳۵ 35
Àwọn ará Israẹli jẹ manna fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kenaani ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ, wọ́n jẹ manna títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbègbè Kenaani.
و اما عومر، ده‌یک ایفه است. ۳۶ 36
(Òsùwọ̀n omeri kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdámẹ́wàá efa.)

< خروج 16 >