< عاموس 3 >

این کلام را بشنوید که خداوند آن را به ضدشما‌ای بنی‌اسرائیل و به ضد تمامی خاندانی که از زمین مصر بیرون آوردم، تنطق نموده و گفته است: ۱ 1
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
من شما را فقط از تمامی قبایل زمین شناختم پس عقوبت تمام گناهان شما را بر شما خواهم رسانید. ۲ 2
“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
آیا دو نفر با هم راه می‌روند جز آنکه متفق شده باشند؟ آیا شیر در جنگل غرش می‌کند حینی که شکار نداشته باشد؟ آیا شیر ژیان آواز خود را از بیشه‌اش می‌دهد حینی که چیزی نگرفته باشد؟ ۳ 3
Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
آیا مرغ به دام زمین می‌افتد، جایی که تله برای او نباشد؟ آیا دام از زمین برداشته می‌شود، حینی که چیزی نگرفته باشد؟ ۴ 4
Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
آیا کرنادر شهر نواخته می‌شود و خلق نترسند؟ ۵ 5
Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
آیا بلابر شهر وارد بیاید و خداوند آن را نفرموده باشد؟ ۶ 6
Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
زیرا خداوند یهوه کاری نمی کند جز اینکه سرخویش را به بندگان خود انبیا مکشوف می‌سازد. ۷ 7
Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
شیر غرش کرده است، کیست که نترسد؟ خداوند یهوه تکلم نموده است: کیست که نبوت ننماید؟ ۸ 8
Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
بر قصرهای اشدود و بر قصرهای زمین مصرندا کنید و بگویید بر کوههای سامره جمع شوید و ملاحظه نمایید که چه هنگامه های عظیم دروسط آن و چه ظلمها در میانش واقع شده است. ۹ 9
Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
زیرا خداوند می‌گوید: آنانی که ظلم و غارت را در قصرهای خود ذخیره می‌کنندراست کرداری را نمی دانند. ۱۰ 10
“Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
بنابراین خداوندیهوه چنین می‌گوید: دشمن به هر طرف زمین خواهد بود و قوت تو را از تو به زیر خواهد آوردو قصرهایت تاراج خواهد شد. ۱۱ 11
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
خداوند چنین می‌گوید: چنانکه شبان دوساق یا نرمه گوش را از دهان شیر رها می‌کند، همچنان بنی‌اسرائیل که در سامره در گوشه‌ای بستری و در دمشق در فراشی ساکنند رهایی خواهند یافت. ۱۲ 12
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
خداوند یهوه خدای لشکرهامی گوید: بشنوید و به خاندان یعقوب شهادت دهید. ۱۳ 13
“Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
زیرا در روزی که عقوبت تقصیرهای اسرائیل را به وی رسانم بر مذبح های بیت ئیل نیزعقوبت خواهم رسانید و شاخهای مذبح قطع شده، به زمین خواهد افتاد. ۱۴ 14
“Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
و خداوند می‌گوید که خانه زمستانی را باخانه تابستانی خراب خواهم کرد و خانه های عاج تلف خواهد شد و خانه های عظیم منهدم خواهدگردید.» ۱۵ 15
Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.

< عاموس 3 >