< دوم سموئیل 24 >

و خشم خداوند بار دیگر بر اسرائیل افروخته شد. پس داود را بر ایشان برانگیزانیده، گفت: «برو و اسرائیل و یهودا رابشمار.» ۱ 1
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli, ó sì ti Dafidi sí wọn, pé, “Lọ ka iye Israẹli àti Juda!”
و پادشاه به‌سردار لشکر خود یوآب که همراهش بود، گفت: «الان در تمامی اسباطاسرائیل از دان تا بئرشبع گردش کرده، قوم رابشمار تا عدد قوم را بدانم.» ۲ 2
Ọba sì wí fún Joabu olórí ogun, tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ ní ìsinsin yìí sí gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba, kí ẹ sì ka iye àwọn ènìyàn, kí èmi lè mọ iye àwọn ènìyàn náà!”
و یوآب به پادشاه گفت: «حال یهوه، خدای تو، عدد قوم را هر‌چه باشد، صد چندان زیاده کند، و چشمان آقایم، پادشاه، این را ببیند، لیکن چرا آقایم، پادشاه، خواهش این عمل دارد؟» ۳ 3
Joabu sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi kún iye àwọn ènìyàn náà, iyekíye tí ó wù kí wọn jẹ́, ní ọ̀rọ̀ọ̀rún, ojú olúwa mi ọba yóò sì rí i, ṣùgbọ́n èétiṣe tí olúwa mi ọba fi fẹ́ nǹkan yìí?”
اما کلام پادشاه بریوآب و سرداران لشکر غالب آمد و یوآب وسرداران لشکر از حضور پادشاه برای شمردن قوم اسرائیل بیرون رفتند. ۴ 4
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ọba borí ti Joabu, àti ti àwọn olórí ogun. Joabu àti àwọn olórí ogun sì jáde lọ kúrò níwájú ọba, láti lọ ka àwọn ènìyàn Israẹli.
و از اردن عبور کرده، در عروعیر به طرف راست شهری که در وسط وادی جاد در مقابل یعزیر است، اردو زدند. ۵ 5
Wọ́n sì kọjá odò Jordani, wọ́n sì pàgọ́ ní Aroeri, ní ìhà apá ọ̀tún ìlú tí ó wà láàrín àfonífojì Gadi, àti sí ìhà Jaseri.
و به جلعاد و زمین تحتیم حدشی آمدند و به دان یعن رسیده، به سوی صیدون دور زدند. ۶ 6
Wọ́n sì wá sí Gileadi, àti sí ilé Tatimi Hodṣi; wọ́n sì wá sí Dani Jaani àti yíkákiri sí Sidoni.
و به قلعه صور و تمامی شهرهای حویان و کنعانیان آمدند و به جنوب یهودا تا بئرشبع گذشتند. ۷ 7
Wọ́n sì wá sí ìlú olódi Tire, àti sí gbogbo ìlú àwọn Hifi, àti ti àwọn ará Kenaani, wọ́n sì jáde lọ síhà gúúsù ti Juda, àní sí Beerṣeba.
وچون در تمامی زمین گشته بودند، بعد ازانقضای نه ماه و بیست روز به اورشلیم مراجعت کردند. ۸ 8
Wọ́n sì la gbogbo ilẹ̀ náà já, wọ́n sì wá sí Jerusalẹmu ní òpin oṣù kẹsànán àti ogúnjọ́.
و یوآب عدد شمرده شدگان قوم را به پادشاه داد: از اسرائیل هشتصد هزار مردجنگی شمشیرزن و از یهودا پانصد هزار مردبودند. ۹ 9
Joabu sì fi iye tí àwọn ènìyàn náà jásí lé ọba lọ́wọ́. Ó sì jẹ́ ogójì ọ̀kẹ́ ọkùnrin alágbára ní Israẹli, àwọn onídà, àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn.
و داود بعد از آنکه قوم را شمرده بود، دردل خود پشیمان گشت. پس داود به خداوندگفت: «در این کاری که کردم، گناه عظیمی ورزیدم و حال‌ای خداوند گناه بنده خود را عفوفرما زیرا که بسیار احمقانه رفتار نمودم.» ۱۰ 10
Àyà Dafidi sì gbọgbẹ́ lẹ́yìn ìgbà tí ó ka àwọn ènìyàn náà tán. Dafidi sì wí fún Olúwa pé, “Èmi ṣẹ̀ gidigidi ní èyí tí èmi ṣe, ṣùgbọ́n, èmi bẹ̀ ọ, Olúwa, fi ẹ̀ṣẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ jì ní, nítorí pé èmi hùwà aṣiwèrè gidigidi!”
وبامدادان چون داود برخاست، کلام خداوند به‌جاد نبی که رایی داود بود، نازل شده، گفت: ۱۱ 11
Dafidi sì dìde ní òwúrọ̀, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Gadi wòlíì wá, aríran Dafidi wí pé,
«برو داود را بگو خداوند چنین می‌گوید: سه چیز پیش تو می‌گذارم پس یکی از آنها را برای خود اختیار کن تا برایت به عمل آورم.» ۱۲ 12
“Lọ kí o sì wí fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, èmi fi nǹkan mẹ́ta lọ̀ ọ́; yan ọ̀kan nínú wọn, kí èmi ó sì ṣe é sí ọ.’”
پس جاد نزد داود آمده، او را مخبر ساخت و گفت: «آیا هفت سال قحط در زمینت برتو عارض شود، یا سه ماه از حضور دشمنان خود فرار نمایی وایشان تو را تعاقب کنند، یا وبا سه روز در زمین توواقع شود. پس الان تشخیص نموده، ببین که نزدفرستنده خود چه جواب ببرم.» ۱۳ 13
Gadi sì tọ Dafidi wá, ó sì bi í léèrè pé, “Kí ìyàn ọdún méje ó tọ̀ ọ́ wá ní ilẹ̀ rẹ bí? Tàbí kí ìwọ máa sá ní oṣù mẹ́ta níwájú àwọn ọ̀tá rẹ, nígbà tí wọn ó máa lé ọ? Tàbí kí ààrùn ìparun ọjọ́ mẹ́ta ó wá sí ilẹ̀ rẹ? Rò ó nísinsin yìí, kí o sì mọ èsì tí èmi ó mú padà tọ ẹni tí ó rán mi.”
داود به‌جادگفت: «در شدت تنگی هستم. تمنا اینکه به‌دست خداوند بیفتیم زیرا که رحمتهای او عظیم است وبه‌دست انسان نیفتم.» ۱۴ 14
Dafidi sì wí fún Gadi pé, “Ìyọnu ńlá bá mi. Jẹ́ kí a fi ara wa lé Olúwa ní ọwọ́; nítorí pé àánú rẹ̀ pọ̀; kí ó má sì ṣe fi mí lé ènìyàn ní ọwọ́.”
پس خداوند وبا براسرائیل از آن صبح تاوقت معین فرستاد و هفتاد هزار نفر از قوم، از دان تا بئرشبع مردند. ۱۵ 15
Olúwa sì rán ààrùn ìparun sí Israẹli láti òwúrọ̀ títí dé àkókò tí a dá, ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn sì kú nínú àwọn ènìyàn náà láti Dani títí fi dé Beerṣeba.
و چون فرشته، دست خود رابر اورشلیم دراز کرد تا آن را هلاک سازد، خداونداز آن بلا پشیمان شد و به فرشته‌ای که قوم راهلاک می‌ساخت گفت: «کافی است! حال دست خود را باز دار.» و فرشته خداوند نزد خرمنگاه ارونه یبوسی بود. ۱۶ 16
Nígbà tí angẹli náà sì nawọ́ rẹ̀ sí Jerusalẹmu láti pa á run, Olúwa sì káàánú nítorí ibi náà, ó sì sọ fún angẹli tí ń pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó tó, dá ọwọ́ rẹ dúró wàyí!” Angẹli Olúwa náà sì wà níbi ìpakà Arauna ará Jebusi.
و چون داود، فرشته‌ای را که قوم را هلاک می‌ساخت دید، به خداوند عرض کرده، گفت: «اینک من گناه کرده‌ام و من عصیان ورزیده‌ام اما این گوسفندان چه کرده‌اند؟ تمنااینکه دست تو بر من و برخاندان پدرم باشد.» ۱۷ 17
Dafidi sì wí fún Olúwa nígbà tí ó rí angẹli tí ń kọlu àwọn ènìyàn pé, “Wò ó, èmi ti ṣẹ̀, èmi sì ti hùwà búburú ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn wọ̀nyí, kín ni wọ́n ha ṣe? Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, kí ó wà lára mi àti ìdílé baba mi.”
و در آن روز جاد نزد داود آمده، گفت: «بروو مذبحی در خرمنگاه ارونه یبوسی برای خداوندبرپا کن.» ۱۸ 18
Gadi sì tọ Dafidi wá ní ọjọ́ náà, ó sì wí fún un pé, “Gòkè, tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa lórí ilẹ̀ ìpakà Arauna ará Jebusi.”
پس داود موافق کلام جاد چنانکه خداوند امر فرموده بود، رفت. ۱۹ 19
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Gadi, Dafidi sì gòkè lọ bí Olúwa ti pa á ní àṣẹ.
و چون ارونه نظر انداخته، پادشاه و بندگانش را دید که نزد وی می‌آیند، ارونه بیرون آمده، به حضور پادشاه به روی خود به زمین افتاده، تعظیم نمود. ۲۰ 20
Arauna sì wò, ó sì rí ọba àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ wá lọ́dọ̀ rẹ̀, Arauna sì jáde, ó sì wólẹ̀ níwájú ọba ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀.
و ارونه گفت: «آقایم، پادشاه، چرا نزد بنده خود آمده است؟» داود گفت: «تا خرمنگاه را از تو بخرم ومذبحی برای خداوند بنا نمایم و تا وبا از قوم رفع شود.» ۲۱ 21
Arauna sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ọba ṣe tọ ìránṣẹ́ rẹ̀ wá?” Dafidi sì dáhùn pé, “Láti ra ibi ìpakà rẹ lọ́wọ́ rẹ, láti tẹ́ pẹpẹ kan fún Olúwa, kí ààrùn ìparun lè dá lára àwọn ènìyàn náà.”
و ارونه به داود عرض کرد: «آقایم پادشاه آنچه را که در نظرش پسند آیدگرفته، قربانی کند و اینک گاوان به جهت قربانی سوختنی و چومها و اسباب گاوان به جهت هیزم. این همه را‌ای پادشاه، ارونه به پادشاه می‌دهد. و ارونه به پادشاه گفت: «یهوه، خدایت، تو را قبول فرماید.» ۲۲ 22
Arauna sì wí fún Dafidi pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba ó mú èyí tí ó dára lójú rẹ̀, kí o sì fi í rú ẹbọ, wò ó, màlúù nìyìí láti fi ṣe ẹbọ sísun, àti ohun èlò ìpakà, àti ohun èlò mìíràn ti màlúù fún igi.
اما پادشاه به ارونه گفت: «نی، بلکه البته به قیمت از توخواهم گرفت، و برای یهوه، خدای خود، قربانی های سوختنی بی‌قیمت نخواهم گذرانید.» پس داود خرمنگاه و گاوان را به پنجاه مثقال نقره خرید. ۲۳ 23
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni Arauna fi fún ọba, bí ọba.” Arauna sì wí fún ọba pé, “Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ ó gba ọrẹ rẹ.”
و داود در آنجا مذبحی برای خداوند بنانموده، قربانی های سوختنی و ذبایح سلامتی گذرانید. پس خداوند به جهت زمین اجابت فرمود و وبا از اسرائیل رفع شد. گذرانید. پس خداوند به جهت زمین اجابت فرمود و وبا از اسرائیل رفع شد. ۲۴ 24
Ọba sì wí fún Arauna pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́; ṣùgbọ́n èmi ó rà á ní iye kan lọ́wọ́ rẹ, bí ó ti wù kí ó ṣe; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi èyí tí èmi kò náwó fún, rú ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run mi.” Dafidi sì ra ibi ìpakà náà, àti àwọn màlúù náà ní àádọ́ta ṣékélì fàdákà.
۲۵ 25
Dafidi sì tẹ́ pẹpẹ kan níbẹ̀ sí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ti ìlàjà. Olúwa sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ fún ilẹ̀ náà, ààrùn náà sì dá kúrò ní Israẹli.

< دوم سموئیل 24 >