< دوم تواریخ 33 >

منسی دوازده ساله بود که پادشاه شد وپنجاه و پنج سال در اورشلیم سلطنت نمود. ۱ 1
Manase jẹ́ ọmọ ọdún méjìlá nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta.
و آنچه در نظر خداوند ناپسند بود، موافق رجاسات امت هایی که خداوند آنها را از حضوربنی‌اسرائیل اخراج کرده بود، عمل نمود. ۲ 2
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa. Nípa títẹ̀lé ọ̀nà iṣẹ́ ìríra ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli rìn.
زیرامکانهای بلند را که پدرش حزقیا خراب کرده بود، بار دیگر بنا نمود و مذبحها برای بعلیم برپا کرد واشیره‌ها بساخت و به تمامی لشکر آسمان سجده نموده، آنها را عبادت کرد. ۳ 3
Ó tún kọ́ àwọn ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah ti fọ́ túútúú. Ó sì gbé àwọn pẹpẹ dìde fún àwọn Baali ó sì ṣe àwọn ère Aṣerah. Ó foríbalẹ̀ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run ó sì sìn wọ́n.
و مذبح‌ها در خانه خداوند بنا نمود که درباره‌اش خداوند گفته بود: «اسم من در اورشلیم تا به ابد خواهد بود.» ۴ 4
Ó kọ́ àwọn pẹpẹ sínú ilé Olúwa ní èyí tí Olúwa ti wí pé, “Orúkọ mi yóò wà ní Jerusalẹmu títí láé.”
ومذبح‌ها برای تمامی لشکر آسمان در هر دوصحن خانه خداوند بنا نمود. ۵ 5
Nínú ààfin méjèèje ti ilé Olúwa, ó kọ́ àwọn pẹpẹ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run
و پسران خود رادر وادی ابن هنوم از آتش گذرانید و فالگیری وافسونگری و جادوگری می‌کرد و با اصحاب اجنه و جادوگران مراوده می‌نمود و در نظرخداوند شرارت بسیار ورزیده، خشم او را به هیجان آورد. ۶ 6
Ó sì mú kí àwọn ọmọ ara rẹ̀ kí ó kọjá láàrín iná ní àfonífojì Beni-Hinnomu, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
و تمثال ریخته شده بت را که ساخته بود، در خانه خداوند برپا داشت که درباره‌اش خدا به داود و به پسرش سلیمان گفته بود: «در این خانه و در اورشلیم که آن را از تمامی اسباط بنی‌اسرائیل برگزیده‌ام، اسم خود را تا به ابد قرار خواهم داد. ۷ 7
Ó mú ère gbígbẹ́ tí ó ti gbẹ́ ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, ní èyí tí Ọlọ́run ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí mo ti yàn kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò fi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé.
و پایهای اسرائیل را اززمینی که مقر پدران شما ساخته‌ام، بار دیگر آواره نخواهم گردانید، به شرطی که توجه نمایند تابرحسب هر‌آنچه به ایشان امر فرموده‌ام و برحسب تمامی شریعت و فرایض و احکامی که به‌دست موسی داده‌ام، عمل نمایند.» ۸ 8
Èmi kì yóò ṣí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli kúrò mọ́ ní ilẹ̀ náà tí èmi ti yàn fún àwọn baba ńlá yín, níwọ̀n bí wọ́n bá ṣe pẹ̀lẹ́ láti ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ fún wọn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo òfin, àṣẹ àti àwọn ìlànà tí a fún yín láti ọwọ́ Mose wá.”
امامنسی، یهودا و ساکنان اورشلیم را اغوا نمود تا ازامت هایی که خداوند پیش بنی‌اسرائیل هلاک کرده بود، بدتر رفتار نمودند. ۹ 9
Ṣùgbọ́n Manase mú kí Juda àti àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu yapa, àti láti ṣe búburú ju àwọn orílẹ̀-èdè lọ, àwọn tí Olúwa ti parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
و خداوند به منسی و به قوم او تکلم نمود، اما ایشان گوش نگرفتند. ۱۰ 10
Olúwa bá Manase sọ̀rọ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò kọbi ara sí i.
پس خداوندسرداران لشکر آشور را بر ایشان آورد و منسی رابا غلها گرفته، او را به زنجیرها بستند و به بابل بردند. ۱۱ 11
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa mú àwọn alákòóso ọmọ-ogun ọba Asiria láti dojúkọ wọ́n, tí ó mú Manase nígbèkùn, ó fi ìwọ̀ mú un ní imú rẹ̀, ó dè é pẹ̀lú ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ ó sì mú un lọ sí Babeli.
و چون در تنگی بود یهوه خدای خود راطلب نمود و به حضور خدای پدران خویش بسیار تواضع نمود. ۱۲ 12
Nínú ìpọ́njú rẹ̀, ó wá ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ gidigidi níwájú Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀.
و چون از او مسالت نمودوی را اجابت نموده، تضرع او را شنید و به مملکتش به اورشلیم باز آورد، آنگاه منسی دانست که یهوه خدا است. ۱۳ 13
Nígbà tí ó sì gbàdúrà sí i, inú Olúwa dùn sí àdúrà rẹ̀, ó sì tẹ́tí sí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni ó mú un padà wá sí Jerusalẹmu àti sí ìjọba rẹ̀. Nígbà náà Manase mọ̀ wí pé Olúwa ni Ọlọ́run.
و بعد از این حصار بیرونی شهر داود را به طرف غربی جیحون در وادی تا دهنه دروازه ماهی بنا نمود و دیواری گرداگرد عوفل کشیده، آن را بسیار بلند ساخت و سرداران جنگی بر همه شهرهای حصاردار یهودا قرار داد. ۱۴ 14
Ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí, ó mọ odi kan lẹ́yìn ìlú Dafidi, ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Gihoni, ní àfonífojì, àní ní àtiwọ ẹnu ibodè ẹja, ó sì yí orí òkè Ofeli ká; ó sì mọ ọ́n ga sókè gidigidi, ó sì fi balógun sínú gbogbo ìlú olódi Juda wọ̀n-ọn-nì.
و خدایان بیگانه و بت را از خانه خداوند و تمامی مذبحها راکه در کوه خانه خداوند و در اورشلیم ساخته بودبرداشته، آنها را از شهر بیرون ریخت. ۱۵ 15
Ó pa gbogbo àwọn Ọlọ́run àjèjì run. Ó sì hú gbogbo àwọn ère kúrò nínú ilé Olúwa, pẹ̀lú gbogbo àwọn pẹpẹ tí ó ti kọ́ ní òkè ilé Olúwa àti ní Jerusalẹmu; ó sì kó wọn jáde kúrò nínú ìlú.
و مذبح خداوند را تعمیر نموده، ذبایح سلامتی و تشکربر آن گذرانیدند و یهودا را امر فرمود که یهوه خدای اسرائیل را عبادت نمایند. ۱۶ 16
Nígbà náà ni ó mú àwọn pẹpẹ padà bọ̀ sípò. Ó sì rú ọrẹ ìdàpọ̀ àti ọrẹ-ọpẹ́ lórí rẹ̀. Ó sì sọ fún Juda láti sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
اما قوم هنوزدر مکانهای بلند قربانی می‌گذرانیدند لیکن فقطبرای یهوه خدای خود. ۱۷ 17
Àwọn ènìyàn, ko tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ ní àwọn ibi gíga. Ṣùgbọ́n sí Olúwa Ọlọ́run wọn nìkan.
و بقیه وقایع منسی و دعایی که نزد خدای خود کرد و سخنان رائیانی که به اسم یهوه خدای اسرائیل به او گفتند، اینک در تواریخ پادشاهان اسرائیل مکتوب است. ۱۸ 18
Àwọn iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Manase pẹ̀lú àdúrà rẹ̀ sí Ọlọ́run rẹ̀ àti àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn aríran sọ sí i ní orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wà nínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
و دعای او ومستجاب شدنش و تمامی گناه و خیانتش وجایهایی که مکانهای بلند در آنها ساخت واشیره‌ها و بتهایی که قبل از متواضع شدنش برپانمود، اینک در اخبار حوزای مکتوب است. ۱۹ 19
Àdúrà rẹ̀ àti bí inú Ọlọ́run ṣe dùn sí àdúrà rẹ̀ àti gbogbo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ àti àìṣòótọ́, àti àwọn òpó níbi tí ó kọ́ àwọn ibi gíga sí, ó sì gbé àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà kí ó tó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, gbogbo rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìrántí àwọn aríran.
پس منسی با پدران خود خوابید و او را در خانه خودش دفن کردند و پسرش آمون در جایش پادشاه شد. ۲۰ 20
Manase sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín sínú ààfin rẹ̀. Amoni ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
آمون بیست و دو ساله بود که پادشاه شد ودو سال در اورشلیم پادشاهی کرد. ۲۱ 21
Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
و آنچه درنظر خداوند ناپسند بود، موافق آنچه پدرش منسی کرده بود، به عمل آورد و آمون برای جمیع بتهایی که پدرش منسی ساخته بود، قربانی گذرانیده، آنها را پرستش کرد. ۲۲ 22
Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe. Amoni rú ẹbọ sí gbogbo àwọn òrìṣà tí Manase baba rẹ̀ ti ṣe, ó sì sìn wọ́n.
و به حضورخداوند تواضع ننمود، چنانکه پدرش منسی تواضع نموده بود بلکه این آمون زیاده و زیاده عصیان ورزید. ۲۳ 23
Ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i baba rẹ̀ Manase. Kò rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Olúwa: ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ Amoni sì ń pọ̀ sì í.
پس خادمانش بر او شوریده، او را در خانه خودش کشتند. ۲۴ 24
Àwọn oníṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ sí i. Wọ́n sì pa á ní ààfin rẹ̀.
و اهل زمین همه کسانی را که بر آمون پادشاه شوریده بودند، به قتل رسانیدند و اهل زمین پسرش یوشیا را در جایش به پادشاهی نصب کردند. ۲۵ 25
Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì mú Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< دوم تواریخ 33 >