< اول یوحنا 3 >

ملاحظه کنید چه نوع محبت پدر به ما داده است تا فرزندان خدا خوانده شویم؛ وچنین هستیم و از این جهت دنیا ما را نمی شناسدزیرا که او را نشناخت. ۱ 1
Ẹ wo irú ìfẹ́ tí Baba fi fẹ́ wa, tí a fi ń pè wá ní ọmọ Ọlọ́run; bẹ́ẹ̀ ni a sá à jẹ́. Nítorí èyí ni ayé kò ṣe mọ̀ wá, nítorí tí kò mọ̀ ọ́n.
‌ای حبیبان، الان فرزندان خدا هستیم و هنوز ظاهر نشده است آنچه خواهیم بود؛ لکن می‌دانیم که چون او ظاهر شود، مانند او خواهیم بود زیرا او را چنانکه هست خواهیم دید. ۲ 2
Olùfẹ́, ọmọ Ọlọ́run ni àwa ń ṣe nísinsin yìí, a kò ì tí i fihàn bí àwa ó ti rí: àwa mọ̀ pé, nígbà tí òun ba farahàn, àwa yóò dàbí rẹ̀; nítorí àwa yóò rí i, àní bí òun tí rí.
و هرکس که این امید را بر وی دارد، خود را پاک می‌سازد چنانکه او پاک است. ۳ 3
Olúkúlùkù ẹni tí ó ba sì ní ìrètí yìí nínú rẹ̀, ń wẹ ara rẹ̀ mọ́, àní bí òun ti mọ́.
و هرکه گناه را بعمل می‌آورد، برخلاف شریعت عمل می‌کند زیرا گناه مخالف شریعت است. ۴ 4
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ó ń rú òfin pẹ̀lú, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ni rírú òfin.
و می‌دانید که او ظاهر شد تا گناهان رابردارد و در وی هیچ گناه نیست. ۵ 5
Ẹ̀yin sì mọ̀ pé, òun farahàn láti mu ẹ̀ṣẹ̀ kúrò; ẹ̀ṣẹ̀ kò sì ṣí nínú rẹ̀.
هرکه در وی ثابت است گناه نمی کند و هرکه گناه می‌کند او راندیده است و نمی شناسد. ۶ 6
Ẹnikẹ́ni tí ó ba ń gbé inú rẹ̀ kì í dẹ́ṣẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì ń dẹ́ṣẹ̀ kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni kò mọ̀ ọ́n.
‌ای فرزندان، کسی شما را گمراه نکند؛ کسی‌که عدالت را به‌جا می‌آورد، عادل است چنانکه اوعادل است. ۷ 7
Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín, ẹni tí ó bá ń ṣe òdodo, ó jásí olódodo, gẹ́gẹ́ bí òun tí jẹ olódodo.
و کسی‌که گناه می‌کند از ابلیس است زیرا که ابلیس از ابتدا گناهکار بوده است. واز این جهت پسر خدا ظاهر شد تا اعمال ابلیس راباطل سازد. ۸ 8
Ẹni tí ó ba ń dẹ́ṣẹ̀ tí èṣù ni; nítorí láti àtètèkọ́ṣe ni èṣù ti ń dẹ́ṣẹ̀. Nítorí èyí ni Ọmọ Ọlọ́run ṣe farahàn, kí ó lè pa iṣẹ́ èṣù run.
هر‌که از خدا مولود شده است، گناه نمی کند زیرا تخم او در وی می‌ماند و اونمی تواند گناهکار بوده باشد زیرا که از خدا تولدیافته است. ۹ 9
Ẹnikẹ́ni tí a ti ipa Ọlọ́run bí, kì í dẹ́ṣẹ̀; nítorí tí irú rẹ̀ ń gbé inú rẹ̀, kò sì lè dẹ́ṣẹ̀ nítorí pé a ti ti ipa Ọlọ́run bí i.
فرزندان خدا و فرزندان ابلیس ازاین ظاهر می‌گردند. هر‌که عدالت را به‌جانمی آورد از خدا نیست و همچنین هر‌که برادرخود را محبت نمی نماید. ۱۰ 10
Nínú èyí ni àwọn ọmọ Ọlọ́run ń farahàn, àti àwọn ọmọ èṣù; ẹnikẹ́ni tí kò ba ń ṣe òdodo, àti ẹni tí kò fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀ kì í ṣe ti Ọlọ́run.
زیرا همین است آن پیغامی که از اول شنیدید که یکدیگر را محبت نماییم. ۱۱ 11
Nítorí èyí ni iṣẹ́ tí ẹ̀yin tí gbọ́ ni àtètèkọ́ṣe, pé ki àwa fẹ́ràn ara wa.
نه مثل قائن که از آن شریر بود و برادر خود را کشت؛ و ازچه سبب او را کشت؟ از این سبب که اعمال خودش قبیح بود و اعمال برادرش نیکو. ۱۲ 12
Kì í ṣe bí Kaini, tí í ṣe ẹni búburú, tí o sì pa arákùnrin rẹ̀. Nítorí kín ni ó sì ṣe pa á? Nítorí tí iṣẹ́ tirẹ̀ jẹ́ búburú ṣùgbọ́n tí arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ òdodo.
‌ای برادران من، تعجب مکنید اگر دنیا از شما نفرت گیرد. ۱۳ 13
Kì ẹnu má ṣe yà yín, ẹ̀yin ará mi, bí ayé bá kórìíra yín.
ما می‌دانیم که از موت گذشته، داخل حیات گشته‌ایم از اینکه برادران را محبت می نماییم. هرکه برادر خود را محبت نمی نمایددر موت ساکن است. ۱۴ 14
Àwa mọ̀ pé àwa tí rékọjá láti inú ikú sínú ìyè, nítorí tí àwa fẹ́ràn àwọn ará. Ẹni tí kò ba ni ìfẹ́, ó ń gbé inú ikú.
هر‌که از برادر خود نفرت نماید، قاتل است و می‌دانید که هیچ قاتل حیات جاودانی در خود ثابت ندارد. (aiōnios g166) ۱۵ 15
Ẹnikẹ́ni tí ó ba kórìíra arákùnrin rẹ̀ apànìyàn ni, ẹ̀yin sì mọ́ pé kò sí apànìyàn tí ó ni ìyè àìnípẹ̀kun láti máa gbé inú rẹ̀. (aiōnios g166)
از این امر محبت را دانسته‌ایم که او جان خود را در راه ما نهاد و ما باید جان خود را در راه برادران بنهیم. ۱۶ 16
Nípa èyí ni àwa mọ ìfẹ́ nítorí tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ fún wa, ó sì yẹ kí àwa fi ẹ̀mí wa lélẹ̀ fún àwọn ará.
لکن کسی‌که معیشت دنیوی دارد و برادر خود را محتاج بیند و رحمت خود رااز او باز‌دارد، چگونه محبت خدا در او ساکن است؟ ۱۷ 17
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ni ohun ìní ayé, tí ó sì ri arákùnrin rẹ̀ tí ó ṣe aláìní, tí ó sì sé ìlẹ̀kùn ìyọ́nú rẹ̀ mọ́ ọn, báwo ni ìfẹ́ Ọlọ́run ṣe ń gbé inú rẹ̀?
‌ای فرزندان، محبت را به‌جا آریم نه درکلام و زبان بلکه در عمل و راستی. ۱۸ 18
Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ má ṣe jẹ́ kí a fi ọ̀rọ̀ tàbí ahọ́n fẹ́ràn, bí kò ṣe ni ìṣe àti ní òtítọ́.
و از این خواهیم دانست که از حق هستیم و دلهای خود رادر حضور او مطمئن خواهیم ساخت، ۱۹ 19
Àti nípa èyí ni àwa ó mọ̀ pé àwa jẹ́ ti òtítọ́, àti pé àwa ó sì fi ọkàn ara wa balẹ̀ níwájú rẹ̀.
یعنی درهرچه دل ما، ما را مذمت می‌کند، زیرا خدا از دل ما بزرگتر است و هرچیز را می‌داند. ۲۰ 20
Nínú ohunkóhun tí ọkàn wa bá ń dá wa lẹ́bi; nítorí pé Ọlọ́run tóbi ju ọkàn wa lọ, ó sì mọ ohun gbogbo.
‌ای حبیبان، هرگاه دل ما ما را مذمت نکند، در حضور خدا اعتماد داریم. ۲۱ 21
Olùfẹ́, bí ọkàn wa kò bá dá wa lẹ́bi, ǹjẹ́ àwa ni ìgboyà níwájú Ọlọ́run?
و هرچه سوآل کنیم، از او می‌پاییم، از آنجهت که احکام او رانگاه می‌داریم و به آنچه پسندیده اوست، عمل می‌نماییم. و این است حکم او که به اسم پسر اوعیسی مسیح ایمان آوریم و یکدیگر را محبت نماییم، چنانکه به ما امر فرمود. ۲۲ 22
Àti ohunkóhun tí àwa bá béèrè, ni àwa ń rí gbà lọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí tí àwa ń pa òfin rẹ̀ mọ́, àwa sì ń ṣe àwọn nǹkan tí ó dára lójú rẹ̀.
۲۳ 23
Èyí sì ni òfin rẹ̀, pé kí àwa gba orúkọ Jesu Kristi Ọmọ rẹ̀ gbọ́, kí a sì fẹ́ràn ara wá gẹ́gẹ́ bí ó tí fi òfin fún wa.
و هرکه احکام او را نگاه دارد، در او ساکن است و او در وی؛ و ازاین می‌شناسیم که در ما ساکن است، یعنی از آن روح که به ما داده است. ۲۴ 24
Ẹni tí ó bá sì pa òfin rẹ̀ mọ́ ń gbé inú rẹ̀, àti òun nínú rẹ̀. Àti nípa èyí ni àwa mọ̀ pé ó ń gbé inú wa, nípa Ẹ̀mí tí ó fi fún wa.

< اول یوحنا 3 >