< Salmenes 69 >

1 Til sangmesteren; efter "Liljer"; av David. Frels mig, Gud, for vannene er kommet inntil sjelen.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 Jeg er sunket ned i bunnløst dynd, hvor der intet fotfeste er; jeg er kommet i dype vann, og strømmen slår over mig.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 Jeg har ropt mig trett, min strupe brenner; mine øine er borttæret idet jeg venter på min Gud.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 Flere enn hårene på mitt hode er de som hater mig uten årsak; tallrike er de som vil forderve mig, mine fiender uten grunn; det jeg ikke har røvet, skal jeg nu gi tilbake.
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 Gud, du kjenner min dårskap, og all min syndeskyld er ikke skjult for dig.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 La dem ikke bli til skamme ved mig, de som bier efter dig, Herre, Herre, hærskarenes Gud! La dem ikke bli til spott ved mig, de som søker dig, Israels Gud!
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 For for din skyld bærer jeg vanære, dekker skam mitt åsyn.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 Jeg er blitt fremmed for mine brødre og en utlending for min mors barn.
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 For nidkjærhet for ditt hus har fortært mig, og deres hån som håner dig, er falt på mig.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Og min sjel gråt mens jeg fastet, og det blev mig til spott.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Og jeg gjorde sekk til mitt klædebon, og jeg blev dem til et ordsprog.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 De som sitter i porten, snakker om mig, og de som drikker sterk drikk, synger om mig.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 Men jeg kommer med min bønn til dig, Herre, i nådens tid, Gud, for din megen miskunnhet; svar mig med din frelsende trofasthet!
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Redd mig ut av dyndet og la mig ikke synke! La mig bli reddet fra dem som hater mig, og fra de dype vann!
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 La ikke vannstrømmen slå over mig og ikke dypet sluke mig, og la ikke brønnen lukke sitt gap over mig!
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Svar mig, Herre, for din miskunnhet er god; vend dig til mig efter din store barmhjertighet!
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 Og skjul ikke ditt åsyn for din tjener, for jeg er i nød; skynd dig å svare mig!
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Kom nær til min sjel, forløs den, frels mig for mine fienders skyld!
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Du kjenner min spott og min skam og min vanære; alle mine motstandere er for ditt åsyn.
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Spott har brutt mitt hjerte, så jeg er syk, og jeg ventet på medynk, men der var ingen, på trøstere, men jeg fant ikke nogen.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 De gav mig galle å ete, og for min tørst gav de mig eddik å drikke.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 La deres bord bli til en strikke for deres åsyn og til en snare for dem når de er trygge!
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 La deres øine formørkes, så de ikke ser, og la deres lender alltid vakle!
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Utøs din harme over dem, og la din brennende vrede nå dem!
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Deres bolig bli øde, ei være der nogen som bor i deres telt!
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 For den du har slått, forfølger de, og de forteller om deres smerte som du har stunget.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 La dem legge skyld til sin skyld, og la dem ikke komme til din rettferdighet!
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 La dem bli utslettet av de levendes bok, og la dem ikke bli innskrevet med de rettferdige!
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Men jeg er elendig og full av pine; la din frelse, Gud, føre mig i sikkerhet!
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 Jeg vil love Guds navn med sang og ophøie ham med lovprisning,
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 og det skal behage Herren bedre enn en ung okse med horn og klover.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 Når saktmodige ser det, skal de glede sig; I som søker Gud, eders hjerte leve!
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 For Herren hører på de fattige, og sine fanger forakter han ikke.
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Himmel og jord skal love ham, havet og alt det som rører sig i det.
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 For Gud skal frelse Sion og bygge byene i Juda, og de skal bo der og eie dem,
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 og hans tjeneres avkom skal arve dem, og de som elsker hans navn, skal bo i dem.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

< Salmenes 69 >