< Dommernes 8 >

1 Og Efra'ims menn sa til ham: Hvad har du gjort imot oss! Hvorfor sendte du ikke bud efter oss da du drog i strid mot midianittene? Og de gikk sterkt i rette med ham.
Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
2 Men han sa til dem: Hvad har jeg gjort her som kan lignes med det I har gjort? Er ikke Efra'ims efterhøst bedre enn Abiesers vinhøst?
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
3 I eders hånd gav Gud midianittenes fyrster, Oreb og Se'eb, og hvad har jeg maktet å gjøre som kan lignes med det I har gjort? Da han talte således, la deres vrede sig, og de lot ham være i fred.
Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
4 Gideon kom til Jordan og gikk over, han og de tre hundre mann som var med ham, trette som de var blitt ved å forfølge fienden.
Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
5 Da sa han til mennene i Sukkot: Kjære, gi de folk som følger mig, nogen brød! De er trette, og jeg holder på å forfølge Sebah og Salmunna, midianittenes konger.
Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
6 Men høvdingene i Sukkot sa: Har du da alt Sebahs og Salmunnas hender i din hånd, så vi skulde gi din hær brød?
Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
7 Da sa Gideon: Nuvel, når Herren gir Sebah og Salmunna i min hånd, da vil jeg treske eders kjøtt med ørkenens torner og med tistler.
Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
8 Og han drog derfra op til Pnuel og talte til dem på samme måte; men mennene i Pnuel svarte ham som mennene i Sukkot hadde svart.
Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
9 Da sa han til dem og: Når jeg kommer vel hjem igjen, vil jeg rive ned dette tårn.
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
10 Men Sebah og Salmunna lå i Karkor med sine hærer, omkring femten tusen mann; det var alt som var igjen av hele østerlendingenes hær; men de falne var hundre og tyve tusen mann som kunde dra sverd.
Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
11 Og Gideon drog op ad teltboernes vei østenfor Nobah og Jogbea; og han slo hæren mens den var trygg.
Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
12 Sebah og Salmunna flyktet, og han forfulgte dem; og han tok begge midianittenes konger, Sebah og Salmunna, til fange og skremte fra hverandre hele hæren.
Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
13 Og Gideon, Joas' sønn, vendte tilbake fra striden, fra Heres-skaret.
Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
14 Og han fikk fatt på en ung mann som hørte hjemme i Sukkot, og spurte ham ut; og han skrev op for ham høvdingene og de eldste i Sukkot, syv og sytti mann.
Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
15 Og han kom til mennene Sukkot og sa: Se, her er Sebah og Salmunna, for hvis skyld I hånte mig og sa: Har du da alt Sebahs og Salmunnas hender i din hånd, så vi skulde gi dine trette menn brød?
Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
16 Og han grep byens eldste, og han tok ørkenens torner og tistler og tuktet med dem mennene i Sukkot.
Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
17 Og tårnet i Pnuel rev han ned og slo ihjel byens menn.
Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
18 Og han sa til Sebah Og Salmunna: Hvordan så de ut de menn som I slo ihjel på Tabor? Og de sa: De var som du, hver av dem som en kongesønn å se til.
Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
19 Da sa han: Det var mine brødre, min mors sønner; så sant Herren lever, dersom I hadde latt dem leve, skulde jeg ikke slått eder ihjel.
Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
20 Og han sa til Jeter, sin førstefødte sønn: Kom og slå dem ihjel! Men gutten drog ikke sitt sverd; han var redd, fordi han var ennu bare en gutt.
Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
21 Da sa Sebah og Salmunna: Kom selv og hugg oss ned! For som mannen er, så er hans styrke. Så gikk Gideon frem og slo Sebah og Salmunna ihjel, og han tok de halvmåner som deres kameler hadde om halsen.
Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
22 Da sa Israels menn til Gideon: Hersk over oss, både du og din sønn og din sønnesønn! For du har frelst oss av midianittenes hånd.
Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
23 Men Gideon sa til dem: Jeg vil ikke herske over eder, og min sønn skal ikke herske over eder; Herren skal herske over eder.
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
24 Og Gideon sa til dem: Jeg vil be eder om noget: at I alle vil gi mig de ringer I har tatt til bytte! For midianittene gikk med gullringer; de var ismaelitter.
Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
25 Og de sa: Vi vil gjerne gi dig dem. Og de bredte ut et klæde, og på det kastet hver av dem de ringer han hadde tatt til bytte.
Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
26 Og vekten av de gullringer han hadde bedt om, var et tusen og syv hundre sekel gull foruten de halvmåner og øresmykker og purpurklær som midianittenes konger hadde på sig, og foruten de kjeder som deres kameler hadde om halsen.
Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
27 Og Gideon gjorde en livkjortel av gullet og stilte den op i sin by i Ofra; og hele Israel drev der avgudsdyrkelse med den; og den blev en snare for Gideon og hans hus.
Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
28 Således blev midianittene ydmyket under Israels barn, og de løftet ikke mere sitt hode, og landet hadde ro i firti år, så lenge Gideon levde.
Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
29 Så drog Jerubba'al, Joas' sønn, hjem til sitt hus og blev boende der.
Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
30 Gideon hadde sytti sønner som var kommet av hans lend; for han hadde mange hustruer.
Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
31 Og han hadde en medhustru som bodde i Sikem; med henne fikk han også en sønn og kalte ham Abimelek.
Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
32 Og Gideon, Joas' sønn, døde i høi alder og blev begravet i sin far Joas' grav i Ofra, som tilhørte Abiesers ætt.
Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
33 Men da Gideon var død, begynte Israels barn igjen å drive avgudsdyrkelse med Ba'alene, og de tok sig Ba'al-Berit til gud.
Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
34 Israels barn kom ikke i hu Herren sin Gud, som hadde frelst dem av alle deres fienders hånd rundt omkring,
Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
35 og heller ikke viste de Jerubba'als, Gideons, hus nogen kjærlighet til gjengjeld for alt det gode han hadde gjort mot Israel.
Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.

< Dommernes 8 >