< Jeremias 5 >

1 Gå omkring i gatene i Jerusalem og se efter og gi akt, søk på torvene om I finner nogen, om det er nogen som gjør rett, som streber efter redelighet! Så vil jeg tilgi byen.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 Og om de enn sier: Så sant Herren lever, så sverger de allikevel falsk.
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 Herre! Ser ikke dine øine efter redelighet? Du slo dem, men de kjente ingen smerte; du gjorde ende på dem, de vilde ikke ta imot tukt, de gjorde sitt ansikt hårdere enn sten, de vilde ikke vende om.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Da sa jeg: Det er bare småfolk; de er uforstandige, for de kjenner ikke Herrens vei, sin Guds rett;
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 jeg vil nu gå til storfolk og tale med dem; for de kjenner Herrens vei, sin Guds rett. Men nettop de har alle sammen brutt åket og sprengt båndene.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 Derfor skal løven fra skogen slå dem, ulven fra villmarkene ødelegge dem; leoparden lurer utenfor deres byer, hver den som går ut av dem, skal bli revet i stykker; for mange er deres overtredelser, tallrike deres frafall.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 Hvorfor skulde jeg tilgi dig? Dine barn har forlatt mig og svoret ved guder som ikke er guder; og jeg mettet dem, men de drev hor og flokket sig i skjøgens hus.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 Som velnærte hester er de tidlig på ferde; de vrinsker, hver efter sin næstes hustru.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Skulde jeg ikke straffe slikt, sier Herren, eller skulde min sjel ikke hevne sig på et folk som dette?
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 Stig op på dets murer og ødelegg, men gjør ikke helt ende på det! Ta bort dets kvister, de hører ikke Herren til!
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 For Israels hus og Judas hus har båret sig troløst at imot mig, sier Herren.
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 De har fornektet Herren og sagt: Han er ikke til, og det skal ikke komme nogen ulykke over oss, og sverd og hunger skal vi ikke se,
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 og profetene skal bli til vind; for det er ingen som taler i dem. Således skal det gå dem selv.
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 Derfor sier Herren, hærskarenes Gud, så: Fordi I taler slike ord, se, så gjør jeg mine ord i din munn til en ild og dette folk til ved, og ilden skal fortære dem.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Se, jeg lar et folk fra det fjerne komme over eder, Israels hus, sier Herren; et kraftig folk er det, et folk fra eldgammel tid, et folk hvis tungemål du ikke kjenner, og hvis tale du ikke skjønner.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Deres kogger er som en åpen grav, de er alle sammen kjemper.
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 Og de skal fortære din høst og ditt brød, de skal fortære dine sønner og dine døtre, de skal fortære ditt småfe og storfe, de skal fortære ditt vintre og fikentre; dine faste byer som du setter din lit til, skal de bryte ned med sverd.
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 Men selv i de dager, sier Herren, vil jeg ikke gjøre helt ende på eder.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 Og når I da sier: Hvorfor har Herren vår Gud gjort alt dette mot oss? - da skal du si til dem: Likesom I forlot mig og tjente fremmede guder i eders land, således skal I også tjene fremmede herrer i et land som ikke er eders.
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 Forkynn dette i Jakobs hus og kunngjør det i Juda og si:
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 Hør dette, du uvettige og uforstandige folk, som har øine, men ikke ser, som har ører, men ikke hører!
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Vil I ikke frykte mig, sier Herren, vil I ikke beve for mitt åsyn? Jeg som har satt sanden til grense for havet, til en evig demning som det ikke kan komme over, så om bølgene raser, makter de intet, og om de bruser, kan de ikke komme over den.
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 Men dette folk har et trossig og gjenstridig hjerte; de har veket fra ham og er gått bort.
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 Og de har ikke sagt i sitt hjerte: La oss frykte Herren vår Gud, som gir regn i rett tid, både høstregn og vårregn, han som holder ved lag for oss den ordning han har fastsatt for høstens uker!
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Eders misgjerninger har gjort at alt dette er kommet i ulag for eder, og eders synder har holdt det gode borte fra eder.
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 For det finnes ugudelige blandt mitt folk; de legger sig på lur, likesom fuglefangere dukker sig ned; de setter ut snarer og fanger mennesker.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Som et bur er fullt av fugler, således er deres hus fulle av svik; derfor er de blitt store og rike.
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 De er blitt fete, de glinser, de strømmer over av ondt, de dømmer ikke rett i nogen sak, ikke i den farløses sak, så de fremmer den, og fattigfolk hjelper de ikke til deres rett.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Skulde jeg ikke straffe slikt, sier Herren, skulde min sjel ikke hevne sig på et folk som dette?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 Forferdelige og gruelige ting skjer i landet;
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 profetene profeterer løgn, og prestene styrer efter deres råd, og mitt folk vil gjerne ha det således. Men hvad vil I gjøre når enden på dette kommer?
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

< Jeremias 5 >