< Jeremias 49 >

1 Om Ammons barn. Så sier Herren: Har Israel ingen barn, eller har han ingen arving? Hvorfor har deres konge tatt Gad til eie, og hans folk bosatt sig i dets byer?
Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Se, derfor skal dager komme, sier Herren, da jeg lar krigsskrik høre mot Rabba i Ammons land, og det skal bli til en øde grusdynge, og dets døtre skal brennes op med ild, og Israel skal ta sine eiere til eie, sier Herren.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
3 Hyl, Hesbon! For Ai er ødelagt. Skrik, I Rabbas døtre, omgjord eder med sekk, jamre eder og løp omkring ved kveene! For deres konge går i fangenskap, hans prester og høvdinger alle sammen.
“Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Hvorfor roser du dig av dine daler, av din dals overflod, du frafalne datter, som setter din lit til dine skatter og sier: Hvem kan gjøre mig noget?
Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
5 Se, jeg lar frykt komme over dig, sier Herren, Israels Gud, hærskarenes Gud, fra alle dem som bor rundt omkring dig, og I skal bli drevet bort, hver til sin kant, uten at nogen samler de flyktende.
Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 Men derefter vil jeg gjøre ende på Ammons barns fangenskap, sier Herren.
“Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
7 Om Edom. Så sier Herren, hærskarenes Gud: Er det ikke mere nogen visdom i Teman? Finnes ikke lenger råd hos de forstandige? Er deres visdom uttømt?
Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8 Fly, vend eder, skjul eder dypt nede, I Dedans innbyggere! For jeg lar Esaus ulykke komme over ham, den tid da jeg hjemsøker ham.
Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9 Om vinhøstere kommer over dig, så vil de ikke levne nogen efterhøst, om tyver kommer om natten, så vil de ødelegge til de har nok.
Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 For jeg klær Esau naken, jeg avdekker hans skjulesteder, og vil han skjule sig, så kan han det ikke; hans barn og hans brødre og hans naboer blir ødelagt, og han er ikke mere.
Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Forlat dine farløse! Jeg vil holde dem i live, og dine enker kan stole på mig.
Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12 For så sier Herren: Se, de som det ikke tilkom å drikke begeret, de skal drikke, og så skulde du bli ustraffet? Nei, du skal ikke bli ustraffet, drikke skal du.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
13 For jeg har svoret ved mig selv, sier Herren, at Bosra skal bli til en forferdelse, til spott, til en ørken og til en forbannelse, og alle dets byer skal bli til evige grusdynger.
Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
14 En tidende har jeg hørt fra Herren, og et bud er sendt ut iblandt folkene: Samle eder og dra imot det, stå op til krig!
Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
15 For se, jeg gjør dig liten blandt folkene, foraktet blandt menneskene.
“Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Redsel over dig! Ditt hjertes overmot har dåret dig, du som bor i fjellkløfter, du som holder til oppe på høidene. Om du bygger ditt rede høit som ørnen, så vil jeg styrte dig ned derfra, sier Herren.
Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
17 Og Edom skal bli til en forferdelse; hver den som går forbi det, skal forferdes og spotte over alle dets plager.
“Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
18 Som da Sodoma og Gomorra og dets nabobyer blev lagt i grus, sier Herren, skal ingen mann bo der, og intet menneskebarn opholde sig der.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
19 Se, han stiger op som en løve fra Jordans prakt til de alltid grønne enger; for i et øieblikk vil jeg jage Edoms folk bort derfra, og den som er utvalgt, ham vil jeg sette over det; for hvem er som jeg, og hvem vil stevne mig, og hvem er den hyrde som kan stå for mitt åsyn?
“Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
20 Hør derfor det råd som Herren har lagt mot Edom, og de tanker som han har tenkt mot Temans innbyggere: Visselig, de skal bli slept bort de små lam; visselig, deres beitemark skal forferdes over dem.
Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Ved braket av deres fall bever jorden; det lyder skrik som høres like til det Røde Hav.
Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
22 Se, som en ørn farer han op og flyver og breder sine vinger ut over Bosra, og Edoms kjemper blir på den dag til mote som en kvinne i barnsnød.
Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
23 Om Damaskus. Hamat og Arpad er blitt til skamme, for de har hørt en ond tidende, de forgår av angst; i havet er det uro, det kan ikke være stille.
Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Damaskus er motløst, det vender sig til flukt, forferdelse har grepet det; angst og veer har grepet det som den fødende kvinne.
Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Hvor den er forlatt, den lovpriste stad, min gledes by!
Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
26 Derfor skal dens unge menn falle på dens gater, og alle krigsmennene skal tilintetgjøres på den dag, sier Herren, hærskarenes Gud.
Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 Jeg vil sette ild på Damaskus' mur, og den skal fortære Benhadads palasser.
“Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
28 Om Kedar og om Hasors riker, som Babels konge Nebukadnesar slo. Så sier Herren: Stå op, dra op mot Kedar og ødelegg Østens barn!
Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
29 Deres telt og deres småfe skal de ta; deres telttepper og alle deres redskaper og deres kameler skal de føre bort med sig, og de skal rope til dem: Redsel rundt omkring!
Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
30 Fly, flykt alt det I kan, skjul eder dypt nede, I Hasors innbyggere, sier Herren; for Babels konge Nebukadnesar har lagt råd imot eder og tenkt ut ondt imot eder.
“Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
31 Stå op, dra op mot et rolig folk, som bor trygt, sier Herren; de har hverken port eller bom, de bor for sig selv.
“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
32 Deres kameler skal bli til rov, og deres store buskap skal bli til hærfang, og jeg vil sprede dem for alle vinder, dem med rundklippet hår, og fra alle kanter vil jeg la ulykke komme over dem, sier Herren.
Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
33 Og Hasor skal bli til bolig for sjakaler, en ørken til evig tid; ingen mann skal bo der, og intet menneskebarn opholde sig der.
“Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
34 Dette er Herrens ord som kom til profeten Jeremias om Elam i begynnelsen av Judas konge Sedekias' regjering:
Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
35 Så sier Herren, hærskarenes Gud: Se, jeg knekker Elams bue, deres beste våben.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36 Og jeg vil la fire vinder fra himmelens fire hjørner komme over Elam og sprede dem for alle disse vinder, og det skal ikke være noget folk som de bortdrevne fra Elam ikke kommer til.
Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
37 Og jeg vil gjøre Elam redd for sine fiender og for dem som står dem efter livet, og jeg vil la ulykke komme over dem, min brennende vrede, sier Herren, og jeg vil sende sverd efter dem, inntil jeg får gjort ende på dem.
Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
38 Og jeg vil sette min trone i Elam, og jeg vil utrydde konge og høvdinger der, sier Herren.
Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
39 Men det skal skje i de siste dager, da vil jeg gjøre ende på Elams fangenskap, sier Herren.
“Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.

< Jeremias 49 >