< Esaias 3 >

1 For se, Herren, Israels Gud, hærskarenes Gud, tar bort fra Jerusalem og Juda støtte og stav, hver støtte av brød og hver støtte av vann,
Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
2 helt og krigsmann, dommer og profet, spåmann og eldste,
Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
3 høvedsmann over femti og hver høit aktet mann, rådsherre og håndverksmester og kyndig åndemaner.
balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
4 Og jeg vil sette barn til styrere over dem, og guttekåthet skal herske over dem.
“Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
5 Blandt folket skal den ene undertrykke den andre, hver mann sin næste; den unge skal sette sig op mot den gamle, den ringeaktede mot den høit ærede.
Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
6 Når en da tar fatt på en annen i hans fars hus og sier: Du har en kappe, du skal være vår fyrste, og denne ruin skal være under din hånd,
Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
7 så skal han samme dag svare og si: Jeg vil ikke være læge, og i mitt hus er det intet brød og ingen klær; I skal ikke sette mig til folkets fyrste.
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
8 For Jerusalem snubler, og Juda faller, fordi deres tunge og deres gjerninger er mot Herren, de trosser hans herlighets øine.
Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
9 Uttrykket i deres ansikter vidner mot dem, og om sin synd taler de åpent som folket i Sodoma, de dølger den ikke; ve deres sjeler, for de volder sig selv ulykke!
Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
10 Si om den rettferdige at det går ham godt! For han skal ete frukten av sine gjerninger.
Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
11 Ve den ugudelige! Ham går det ille; for det hans hender har gjort, skal gjøres mot ham selv.
Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
12 Mitt folks herskere er barn, og kvinner råder over det. Mitt folk! Dine førere er forførere, og den vei du skal gå, har de ødelagt.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
13 Herren treder frem for å føre sak, og han står der for å dømme folkene.
Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
14 Herren møter i retten sitt folks eldste og dets høvdinger: I har avgnaget vingården! I har rov fra de fattige i husene hos eder!
Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
15 Hvorledes kan I tråkke mitt folk ned og knuse de fattige? sier Herren, Israels Gud, hærskarenes Gud.
Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 Og Herren sa: Fordi Sions døtre er overmodige og går med kneisende nakke og lar øinene løpe om, går og tripper og klirrer med sine fotringer,
Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
17 skal Herren gjøre Sions døtres isse skurvet, og Herren skal avdekke deres blusel.
Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
18 På den dag skal Herren ta bort de prektige fotringer og soler og halvmåner,
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
19 øredobbene og kjedene og slørene,
gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
20 hodeprydelsene og fotkjedene og beltene og lukteflaskene og tryllesmykkene,
gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
21 signetringene og neseringene,
òrùka ọwọ́ àti ti imú,
22 høitidsklærne og kåpene og de store tørklær og pungene,
àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
23 speilene og de fine linneter og huene og florslørene.
dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
24 Og det skal skje: I stedet for balsam skal det være stank, og for belte rep, og for kunstig krusede krøller skallet hode, og for vid kappe trang sekk, brennemerke for skjønnhet.
Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
25 Dine menn skal falle for sverdet, og dine helter i krigen.
Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
26 Og hennes porter klager og sørger, og utplyndret sitter hun på jorden.
Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.

< Esaias 3 >